< Haggai 2 >

1 Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé,
Siódmego miesiąca, dwudziestego i pierwszego dnia tegoż miesiąca stało się słowo Pańskie przez Aggieusza proroka, mówiąc:
2 “Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
Mów teraz do Zorobabela, syna Salatyjelowego, książęcia Judzkiego, i do Jesuego, syna Jozedekowego, kapłana najwyższego, i do ostatku ludu, mówiąc:
3 ‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
Któż między wami pozostał, co widział ten dom w sławie pierwszej jego? I jaki wy teraz widzicie? Izali nie jest przeciwko onemu jako nic w oczach waszych?
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà,’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Jednak teraz zmocnij się Zorobabelu! mówi Pan; zmocnij się, Jesue, synu Jozedekowy, kapłanie najwyższy! zmocnij się też wszystek ludu tej ziemi, mówi Pan, a róbcie; bom Ja z wami, mówi Pan zastępów,
5 ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
Według słowa, któremem przymierze uczynił z wami, gdyście wychodzili z Egiptu; duch także mój stanie w pośrodku was, nie bójcież się.
6 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
Bo tak mówi Pan zastępów: Oto Ja jeszcze raz, a to po małym czasie, poruszę niebem i ziemią, i morzem i suchą;
7 Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Poruszę, mówię, wszystkie narody, i przyjdą do Pożądanego od wszystkich narodów; i napełnię ten dom chwałą, mówi Pan zastępów.
8 ‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Mojeć jest srebro, i moje złoto, mówi Pan zastępów.
9 ‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Większa będzie sława domu tego pośledniego, niż onego pierwszego, mówi Pan zastępów; bo na tem miejscu dam pokój, mówi Pan zastępów.
10 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé,
Dwudziestego i czwartego dnia, dziewiątego miesiąca, roku wtórego Daryjusza, stało się słowo Pańskie przez Aggieusza proroka, mówiąc:
11 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé:
Tak mówi Pan zastępów: Pytaj się teraz kapłanów o zakon, mówiąc:
12 Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
Gdyby kto niósł mięso poświęcone w podołku sukni swej, alboby się dotknął podołkiem swoim chleba, albo potrawy, albo wina, albo oliwy, albo wszelkiego pokarmu, izali się poświęci? I odpowiedzieli kapłani a rzekli: Nie.
13 Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”
Tedy rzekł Aggieusz: Jeźli kto będąc nieczysty od trupa, dotknąłby się czego z tych rzeczy, będzieli nieczyste? I odpowiedzieli kapłani i rzekli: Będzie nieczyste.
14 Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.
Tedy odpowiadając Aggieusz rzekł: Takci lud ten, tak i naród ten przed obliczem mojem, mówi Pan, tak i wszystka sprawa rąk ich, i cokolwiek tam ofiarowali, nieczyste było.
15 “‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa.
A tak uważajcież, proszę, jako się wam powodziło od tego dnia aż do onego, kiedy przestano kłaść kamienia na kamieniu w kościele Pańskim;
16 Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òsùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀.
Od tego czasu, gdy kto przyszedł do gromady zboża, od dwudziestu korcy znalazł dziesięć; gdy przyszedł do prasy, aby naczerpał pięćdziesiąt wiader wina, znalazł tylko dwadzieścia;
17 Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Karałem was zarazą zbóż i rdzą, i gradem wszystkie prace rąk waszych; wszakże żaden z was nie wrócił się do mnie, mówi Pan.
18 ‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára.
Uważajcież teraz ode dnia tego aż do onego, ode dnia dwudziestego i czwartego miesiąca dziewiątego aż do dnia, którego był założony kościół Pański, uważajcie, mówię:
19 Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan. “‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’”
Izali jeszcze jest nasienie w szpichlerzu? I owszem, ani macica winna, ani figowe ani granatowe ani oliwne drzewo nie wydały owocu; lecz ode dnia tego będę błogosławił.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé,
Potem stało się słowo Pańskie powtóre do Aggieusza dnia dwudziestego i czwartego tegoż miesiąca, mówiąc:
21 “Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.
Mów do Zorobabela, książęcia Judzkiego, a rzecz: Ja poruszę niebiosa i ziemię;
22 Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run, Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”
I podwrócę stolice królestw, i zepsuję moc królestw pogańskich; podwrócę, mówię, wóz, i tych, którzy na nim jeżdżą, i upadną konie i jeżdżący na nich, każdy od miecza brata swego.
23 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
W on dzień, mówi Pan zastępów, wezmę cię, Zorobabelu, synu Salatyjelowy, sługo mój! mówi Pan, i uczynię cię jako sygnet; albowiem wybrałem cię, mówi Pan zastępów.

< Haggai 2 >