< Haggai 2 >

1 Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé,
In the seuenthe monethe, in the oon and twentith dai of the monethe, the word of the Lord was maad in the hond of Aggei, the profete, and seide,
2 “Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
Speke thou to Sorobabel, the sone of Salatiel, the duyk of Juda, and to Jhesu, the gret preest, the sone of Josedech, and to othere of the puple, and seie thou,
3 ‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
Who in you is left, that sai this hous in his firste glorie? and what seen ye this now? whether it is not thus, as if it be not bifore youre iyen?
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà,’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
And now, Sorobabel, be thou coumfortid, seith the Lord, and Jhesu, greet preest, sone of Josedech, be thou coumfortid, and al the puple of the lond, be thou coumfortid, seith the Lord of oostis; and do ye, for Y am with you, seith the Lord of oostis.
5 ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
The word that Y couenauntide with you, whanne ye wenten out of the lond of Egipt, and my Spirit schal be in the myddil of you.
6 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
Nyle ye drede, for the Lord of oostis seith these thingis, Yit o litil thing is, and Y schal moue heuene, and erthe, and see, and drie lond;
7 Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
and Y schal moue alle folkis, and the desirid to alle folkis schal come; and Y schal fille this hous with glorie, seith the Lord of oostis.
8 ‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Myn is siluer, and myn is gold, seith the Lord of oostes.
9 ‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
The glorie of this laste hous schal be greet, more than the firste, seith the Lord of oostis. And in this place Y schal yyue pees, seith the Lord of oostis.
10 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé,
In the foure and twentithe dai of the nynthe monethe, in the secounde yeer of kyng Daryus, the word of the Lord was maad to Aggei, the profete, and seide, The Lord God of oostis seith these thingis,
11 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé:
Axe thou preestis the lawe, and seie thou,
12 Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
If a man takith halewyd fleisch in the hem of his clothing, and touchith of the hiynesse therof breed, ether potage, ether wyn, ether oile, ether ony mete, whether it schal be halewid? Sotheli preestis answeriden, and seiden, Nai.
13 Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”
And Aggei seide, If a man defoulid in soule touchith of alle these thingis, whether it schal be defoulid? And prestis answeriden, and seiden, It schal be defoulid.
14 Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.
And Aggei answeride, and seide, So is this puple, and so is this folc bifor my face, seith the Lord, and so is al werk of her hondis; and alle thingis whiche thei offren there, schulen be defoulid.
15 “‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa.
And nowe putte ye youre hertis, fro this dai and aboue, bifor that a stoon on a stoon was put in temple of the Lord,
16 Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òsùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀.
whanne ye wenten to an heep of twenti buischels, and there weren maad ten; ye entriden to the pressour, that ye schulden presse out fifti galouns, and there weren maad twenti.
17 Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Y smoot you with brennynge wynd; and with myldew, and hail, alle the werkis of youre hondis; and ther was noon in you that turnede ayen to me, seith the Lord.
18 ‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára.
Putte ye youre hertis fro this dai, and in to comynge, fro the foure and twentithe dai of the nynthe monethe, fro the dai in whiche foundementis of the temple of the Lord ben castun, putte ye on youre herte.
19 Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan. “‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’”
Whether now seed is in buriownyng? and yit vineyerd, and fige tre, and pomgarnade, and the tre of olyue flouride not.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé,
Fro this dai Y schal blesse. And the word of the Lord was maad the secounde tyme to Aggei, in the foure and twentithe dai of the monethe,
21 “Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.
and seide, Spek thou to Sorobabel, duik of Juda, and seie thou, Y shal moue heuene and erthe togidere, and Y schal distrie the seet of rewmes,
22 Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run, Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”
and Y schal al to-breke the strengthe of rewme of hethene men, and schal distrie a foure horsid carte, and the stiere therof; and horsis schulen go doun, and stieris of hem, a man bi swerd of his brother.
23 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
In that dai, seith the Lord of oostis, thou Sorobabel, sone of Salatiel, my seruaunt, Y schal take thee, seith the Lord; and Y schal putte thee as a signet, for Y chees thee, seith the Lord of oostis.

< Haggai 2 >