< Haggai 2 >

1 Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé,
På den een og tyvende Dag i den syvende Måned kom HERRENs Ord ved Profeten Haggaj således:
2 “Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
Sig til Judas Statholder Zerubbabel, Sjaltiels Søn, til Ypperstepræsten Josua, Jozadaks Søn, og til Resten af Folket således:
3 ‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
Er der nogen tilbage iblandt eder af dem, der har set dette Hus i dets fordums Herlighed? Hvorledes tykkes det eder da nu? Er det ikke som intet i eders Øjne?
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà,’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Dog vær kun trøstig, Zerubbabel, lyder det fra HERREN, vær kun trøstig, du Ypperstepræst Josua, Jozadaks Søn, vær kun trøstigt, alt Folket i Landet, lyder det fra HERREN. Arbejd kun, thi jeg er med eder, lyder det fra Hærskarers HERRE,
5 ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
og min Ånd bliver iblandt eder med den Pagt, jeg sluttede med eder, da I drog bort fra Ægypten; frygt ikke!
6 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
Thi så sigerHærskarers HERRE: Endnu en Gang om en liden Stund vil jeg ryste Himmel og Jord, Hav og tørt Land,
7 Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
og jeg vil ryste alle Folkene, og da skal alle Folkenes Skatte komme hid, og jeg fylder dette Hus med Herlighed, siger Hærskarers HERRE.
8 ‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Mit er Sølvet, og mit er Guldet, lyder det fra Hærskarers HERRE.
9 ‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Dette Hus's kommende Herlighed bliver større end den tidligere, siger Hærskarers HERRE, og på dette Sted vil jeg give Fred, lyder det fra Hærskarers HERRE.
10 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé,
På den fire og tyvende Dag i den niende Måned i Darius's andet Regeringsår kom HERRENs Ord ved Profeten Haggaj således:
11 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé:
Så siger Hærskarers HERRE: Bed Præsterne om Svar på følgende Spørgsmål:
12 Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
"Dersom en Mand bærer helligt Kød i sin kappeflig og med Fligen rører ved Brød eller noget, som er kogt, eller ved Vin eller Olie eller nogen Slags Mad, bliver disse Ting så hellige?" Præsterne svarede nej.
13 Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”
Haggaj spurgte da: "Hvis en, som er blevet uren ved Lig, rører ved nogen af disse Ting, bliver den så uren?" Præsterne svarede ja.
14 Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.
Så tog Haggaj til Orde og sagde: Således er det i mine Øjne med disse Mennesker, således med dette Folk, lyder det fra HERREN, og således med alt deres Hænders Værk og med, hvad de ofrer der: det er urent.
15 “‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa.
Men læg nu Mærke til, hvorledes det går fra i Dag! Før Sten lagdes på Sten i HERRENs Hus,
16 Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òsùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀.
hvorledes gik det eder da? Når man kom til en Dynge Korn på tyve Mål, var der ti; og kom man til en Vinperse for at øse halvtresindstyve Mål af Kummen, var der tyve.
17 Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Jeg slog eder med Kornbrand, Rust og Hagl ved alt eders Arbejde, men I omvendte eder ikke til mig, lyder det fra HERREN.
18 ‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára.
Læg Mærke til, hvorledes det går fra i Dag, fra den fire og tyvende Dag i den niende Måned, fra den Dag Grunden lagdes til HERRENs Hus, læg Mærke dertil!
19 Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan. “‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’”
Er Sæden endnu i Laderne, står Vinstokken, Figentræet, Granatæbletræet og Oliventræet endnu uden Frugt? Fra i Dag velsigner jeg.
20 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé,
Og HERRENs Ord kom for anden Gang til Haggaj på den fire og tyvende bag i Måneden således:
21 “Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.
Sig til Judas Statholder Zerubbabel: Jeg ryster Himmelen og Jorden
22 Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run, Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”
og omstyrter Kongernes Troner, tilintetgør Hedningerigernes Styrke og vælter Stridsvognene med deres Førere, og Heste og Ryttere skal styrte, og den ene skal falde for den andens Sværd.
23 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
På hin Dag, lyder det fra Hærskarers HERRE, tager jeg dig, min Tjener Zerubbabel, Sjealtiels Søn. lyder det fra HERREN, og gør dig til en Seglring; thi dig har jeg udvalgt, lyder det fra Hærskarers HERRE.

< Haggai 2 >