< Haggai 1 >

1 Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
I konung Darejaves' andra regeringsår, i sjätte månaden, på första dagen i månaden, kom HERRENS ord genom profeten Haggai Serubbabel, Sealtiels son, Juda ståthållare, och till översteprästen Josua, Josadaks son; han sade:
2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
Så säger HERREN Sebaot: Detta folk säger: "Ännu är icke tiden kommen att gå till verket, tiden att HERRENS hus bygges upp."
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
Men HERRENS ord kom genom profeten Haggai; han sade:
4 “Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
Är då tiden kommen för eder att själva bo i panelade hus, medan detta hus ligger öde?
5 Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
Därför säger nu HERREN Sebaot så: Given akt på huru det går eder.
6 Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
I sån mycket, men inbärgen litet; I äten, men fån icke nog för att bliva mätta; I dricken, men fån icke nog för att bliva glada; I tagen på eder kläder, men haven icke nog för att bliva varma. Och den som får någon inkomst, han far den allenast för att lägga den i en söndrig pung.
7 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
Ja, så säger HERREN Sebaot: Given akt på huru det går eder.
8 Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
Men dragen nu upp till bergen, hämten trävirke och byggen upp mitt hus, så vill jag hava behag därtill och bevisa mig härlig, säger HERREN.
9 “Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
I väntaden på mycket, men se, det blev litet, och när I förden det hem, då blåste jag på det. Varför gick det så? säger HERREN Sebaot. Jo, därför att mitt hus får ligga öde, under det att envar av eder hastar med sitt eget hus.
10 Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
Fördenskull har himmelen ovan eder förhållit eder sin dagg och jorden förhållit sin gröda.
11 Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
Och jag har bjudit torka komma över land och berg, och över säd, vin och olja och alla andra jordens alster, och över människor och djur, och över all frukt av edra händers arbete.
12 Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
Och Serubbabel, Sealtiels son, och översteprästen Josua, Josadaks son med hela kvarlevan av folket lyssnade till HERRENS, sin Guds, röst och till profeten Haggais ord, eftersom HERREN, deras Gud, hade sänt honom; och folket fruktade för HERREN.
13 Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
Då sade Haggai, HERRENS sändebud, efter HERRENS uppdrag, till folket så: "Jag är med eder, säger HERREN."
14 Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
Och HERREN uppväckte Serubbabels, Sealtiels sons, Juda ståthållares, ande och översteprästen Josuas, Josadaks sons, ande och allt det kvarblivna folkets ande, så att de gingo till verket och arbetade på HERREN Sebaots; sin Guds, hus.
15 ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.
Detta skedde på tjugufjärde dagen i sjätte månaden av konung Darejaves' andra regeringsår.

< Haggai 1 >