< Haggai 1 >

1 Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
In the secounde yeer of Darius, kyng of Persis, in the sixte monethe, in the firste dai of the monethe, the word of the Lord was maad in the hond of Aggey, profete, to Sorobabel, sone of Salatiel, duyk of Juda, and to Jhesu, the greet preest, sone of Josedech,
2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
and seide, The Lord of oostis seith these thingis, and spekith, This puple seith, Yit cometh not the tyme of the hous of the Lord to be bildid.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
And the word of the Lord was maad in the hond of Aggei,
4 “Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
profete, and seide, Whether it is tyme to you, that ye dwelle in housis couplid with tymbir, and this hous be forsakun?
5 Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
And now the Lord of oostis seith these thingis, Putte ye youre hertis on youre weies.
6 Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
Ye han sowe myche, and brouyte in litil; ye han etun, and ben not fillid; ye han drunke, and ye ben not ful of drynk; ye hiliden you, and ye ben not maad hoote; and he that gaderide hiris, sente tho in to a sak holid, ether brokun.
7 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
The Lord of oostis seith these thingis, Putte ye youre hertis on youre weies.
8 Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
Stie ye vp in to the munteyn, bere ye trees, and bilde ye an hous; and it schal be acceptable to me, and Y schal be glorified, seith the Lord.
9 “Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
Ye bihelden to more, and lo! it is maad lesse; and ye brouyten in to the hous, and Y blew it out. For what cause, seith the Lord of oostis? for myn hous is desert, and ye hasten ech man in to his hous.
10 Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
For this thing heuenes ben forbedun, that thei schulden not yyue dew on you; and the erthe is forbodun, that it schulde not yyue his buriownyng.
11 Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
And Y clepide drynesse on erthe, and on mounteyns, and on wheete, and on wyn, and on oile, and what euer thingis the erthe bryngith forth; and on men, and on beestis, and on al labour of hondis.
12 Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
And Sorobabel, the sone of Salatiel, and Jhesus, the greet preest, the sone of Josedech, and alle relifs of the puple, herden the vois of her God, and the wordis of Aggei, the profete, as the Lord God of hem sente him to hem; and al the puple dredde of the face of the Lord.
13 Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
And Aggei, a messanger of the Lord, of the messangeris of the Lord, seide to the puple, and spak, Y am with you, seith the Lord.
14 Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
And the Lord reiside the spirit of Sorobabel, the sone of Salatiel, duik of Juda, and the spirit of Jhesu, the greet preest, the sone of Josedech, and the spirit of the relifs of al puple; and thei entriden, and maden werk in the hous of the Lord of oostis, her God.
15 ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.
In the foure and twentithe dai of the monethe, in the sixte monethe, in the secunde yeer of kyng Darius.

< Haggai 1 >