< Haggai 1 >

1 Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
In year two of Darius the king in the month sixth on day one of the month it came [the] word of Yahweh by [the] hand of Haggai the prophet to Zerubbabel [the] son of Shealtiel [the] governor of Judah and to Joshua [the] son of Jehozadak the priest great saying.
2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
Thus he says Yahweh of hosts saying the people this they have said not a time to come [the] time of [the] house of Yahweh to be rebuilt.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
And it came [the] word of Yahweh by [the] hand of Haggai the prophet saying.
4 “Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
¿ [does] a time [belong] to You you to dwell in houses your covered and the house this [is] desolate.
5 Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
And therefore thus he says Yahweh of hosts set heart your on ways your.
6 Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
You have sown much and you have brought little you have eaten and not to satiety you have drunk and not to become drunk you have dressed and not to be warm to him and the [one who] earns wages [is] earning wages to a bag pierced.
7 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
Thus he says Yahweh of hosts set heart your on ways your.
8 Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
Go up the hill country and you will bring wood and rebuild the house so I may take pleasure in it (so let me be honored *Q(K)*) he says Yahweh.
9 “Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
You turned to look to much and there! little and you brought [it] the house and I blew on it because of what? [the] utterance of Yahweh of hosts because of house my which it [is] desolate and you [are] running each to own house his.
10 Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
There-fore on you they have withheld ([the] heavens *L(abh)*) from dew and the land it has withheld produce its.
11 Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
And I have summoned a drought on the land and on the mountains and on the grain and on the new wine and on the fresh oil and on [that] which it will bring forth the ground and on humankind and on the livestock and on all [the] toil of hands.
12 Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
And he listened Zerubbabel - [the] son of Shealtiel and Joshua [the] son of Jehozadak the priest great and all - [the] remnant of the people to [the] voice of Yahweh God their and to [the] words of Haggai the prophet just as he had sent him Yahweh God their and they were afraid the people of Yahweh.
13 Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
And he said Haggai [the] messenger of Yahweh by [the] message of Yahweh to the people saying I [am] with you [the] utterance of Yahweh.
14 Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
And he stirred up Yahweh [the] spirit of Zerubbabel [the] son of Shealtiel [the] governor of Judah and [the] spirit of Joshua [the] son of Jehozadak the priest great and [the] spirit of all [the] remnant of the people and they came and they did work in [the] house of Yahweh of hosts God their.
15 ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.
On day twenty and four of the month in the sixth [month] in year two of Darius the king.

< Haggai 1 >