< Habakkuk 1 >

1 Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.
Brzemię, które widział prorok Habakuk.
2 Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi? Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!” Ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
PANIE, jak długo będę wołać, a nie będziesz wysłuchiwał? [Jak długo] będę krzyczeć do ciebie [o] krzywdzie, a nie będziesz wybawiał?
3 Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé? Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà? Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi; ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
Czemu dopuszczasz, abym patrzył na nieprawość i widział bezprawie? Zguba i przemoc są przede mną i znajduje się ten, który roznieca spory i niezgodę.
4 Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí, ìdájọ́ òdodo kò sì borí. Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká, nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.
Dlatego prawo jest naruszone, a nie ma już sprawiedliwości. Niegodziwy bowiem osacza sprawiedliwego, dlatego wydawane są błędne wyroki.
5 “Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye, kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi. Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
Spójrzcie na narody, zobaczcie i zdumiejcie się bardzo, gdyż dokonuję dzieła za waszych dni, w które nie uwierzycie, gdy wam o nim opowiedzą.
6 Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde, àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
Oto bowiem wzbudzę Chaldejczyków, naród srogi i gwałtowny; przejdą przez szerokość ziemi, aby posiąść cudze miejsca zamieszkania.
7 Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà, ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn, yóò máa ti inú wọn jáde.
Straszni [są] i groźni. Sami ustalają swój sąd i swoją wielkość.
8 Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ, wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká; wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré, wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun,
Ich konie są szybsze niż lamparty, dziksze niż wilki o zmierzchu. Ich jeźdźcy rozciągną się szeroko, ich jeźdźcy przybędą z daleka, przylecą jak orzeł spieszący się na żer.
9 gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú; wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
Każdy z nich przybędzie dla łupu. Ich twarze będą zwrócone na wschód i zgromadzą jeńców jak piasek.
10 Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé. Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín; nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á.
Będą szydzić z królów, a książęta [będą] u nich przedmiotem pogardy. Z każdej twierdzy będą się naśmiewać, usypią wały i zdobędą ją.
11 Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà, yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”
Wtedy [jego] duch się odmieni, a wystąpi i zawini, [myśląc], że jego moc [pochodzi] od jego boga.
12 Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà? Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́; Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí.
Czy ty nie jesteś od wieków, PANIE, mój Boże, mój Święty? [My] nie umrzemy. PANIE, postawiłeś ich na sąd. Ty, [nasza] Skało, przeznaczyłeś ich na karanie.
13 Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi; ìwọ kò le gbà ìwà ìkà nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè? Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
Twoje oczy są tak czyste, że nie możesz patrzeć na zło ani widzieć bezprawia. Czemu patrzysz na czyniących przewrotność? [Czemu milczysz], gdy niegodziwy pożera sprawiedliwszego niż on sam?
14 Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun, bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso.
[Czemu] czynisz ludzi jak ryby morskie, jak zwierzęta pełzające, które nie mają pana?
15 Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀; nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
Wyciąga wszystkie wędką, zagarnia je swoim niewodem i gromadzi je w swojej sieci. Dlatego cieszy się i raduje.
16 Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀, ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀ nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
Dlatego składa ofiarę swemu niewodowi i pali kadzidło swojej sieci. Przez nie bowiem jego dział jest obfity i jego pożywienie bogatsze.
17 Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí, tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?
Czy dlatego będzie zarzucać swoją sieć, by nieustannie zabijać narody bez litości?

< Habakkuk 1 >