< Habakkuk 3 >

1 Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.
The prayer of Habakkuk the prophet, in the form of an ode.
2 Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ; ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa, ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀; ni ìbínú, rántí àánú.
O Jehovah, I have heard thy words, and tremble. O Jehovah, revive thy work in the midst of the years, In the midst of the years make it known, In wrath remember mercy!
3 Ọlọ́run yóò wa láti Temani, ibi mímọ́ jùlọ láti òkè Parani ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run, ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ.
God cometh from Teman, And the Holy One from mount Paran; His glory covereth the heavens, And the earth is full of his praise.
4 Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ, níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.
His brightness is as the light; Rays stream forth from his hand, And there is the hiding-place of his power.
5 Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ; ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.
Before him goeth the pestilence, And the plague followeth his steps.
6 Ó dúró, ó sì mi ayé; ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká, àwọn òkè kéékèèké ayérayé sì tẹríba: ọ̀nà rẹ ayérayé ni.
He standeth, and measureth the earth; He beholdeth, and maketh the nations tremble; The everlasting mountains are broken asunder; The eternal hills sink down; The eternal paths are trodden by him.
7 Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.
I see the tents of Cushan in affliction, And the canopies of the land of Midian tremble.
8 Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn odò nì, Olúwa? Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí? Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun tí ìwọ fi ń gun ẹṣin, àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?
Is the anger of Jehovah kindled against the rivers, Is thy wrath against the rivers, Is thy indignation against the floods, That thou ridest on with thy horses, Upon thy chariots of victory?
9 A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ, ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.
Thy bow is made bare; Curses are the arrows of thy word; Thou causest rivers to break forth from the earth.
10 Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ; ibú ń ké ramúramù ó sì gbé irú omi sókè.
The mountains see thee and tremble; The flood of waters overflows; The deep uttereth his voice, And lifteth up his hands on high.
11 Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn, pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ, àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.
The sun and the moon remain in their habitation, At the light of thine arrows which fly, At the brightness of the lightning of thy spear.
12 Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já, ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.
Thou marchest through the land in indignation; Thou thrashest the nations in anger;
13 Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, àti láti gba ẹni àmì òróró rẹ là, Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀.
Thou goest forth for the deliverance of thy people, For the deliverance of thine anointed. Thou smitest the head of the house of the wicked; Thou destroyest the foundation even to the neck.
14 Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde láti tú wá ká, ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.
Thou piercest with his own spears the chief of his captains, Who rushed like a whirlwind to scatter us; Who exulted, as if they should devour the distressed in a hiding-place.
15 Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já, ó sì da àwọn omi ńlá ru.
Thou ridest through the sea with thy horses, Through the raging of mighty waters.
16 Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì, ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà; ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ, ẹsẹ̀ mi sì wárìrì, mo dúró ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún ọjọ́ ìdààmú láti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.
I have heard, and my heart trembleth; My lips quiver at the voice; Rottenness entereth into my bones, and my knees tremble, That I must wait in silence for the day of trouble, When the invader shall come up against my people!
17 Bí igi ọ̀pọ̀tọ́ ko tilẹ̀ tanná, tí èso kò sí nínú àjàrà; tí igi olifi ko le so, àwọn oko ko sì mú oúnjẹ wá; tí a sì ké agbo ẹran kúrò nínú agbo, tí kò sì sí ọwọ́ ẹran ni ibùso mọ́,
For the fig-tree shall not blossom, And there shall be no fruit upon the vine; The produce of the olive shall fail, And the fields shall yield no food. The flocks shall he cut off from the folds, And there shall be no herd in the stalls.
18 síbẹ̀, èmi ó láyọ̀ nínú Olúwa, èmi yóò sí máa yọ nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.
Yet will I rejoice in Jehovah, I will exult in God, my helper.
19 Olúwa Olódùmarè ni agbára mi, òun yóò sí ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín, yóò sí mú mi rìn lórí ibi gíga. Sí olórí akọrin lórí ohun èlò orin olókùn mi.
The Lord Jehovah is my strength; He will make my feet like the hind's, And cause me to walk upon my high places. “To the leader of the music on my stringed instruments.”

< Habakkuk 3 >