< Habakkuk 2 >

1 Èmi yóò dúró lórí ibusọ́ mi láti máa wòye, èmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóre, èmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún mi àti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí.
Na swej warcie będę stać, stanę na baszcie i będę się wpatrywać, aby zobaczyć, co [Bóg] będzie mówił i co mam odpowiedzieć, gdy zostanę upomniany.
2 Nígbà náà ni Olúwa dáhùn pé, “Kọ ìṣípayá náà sílẹ̀ kí o sì fi hàn ketekete lórí wàláà kí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.
Wtedy PAN mi odpowiedział: Zapisz to widzenie, [zapisz je] wyraźnie na tablicach, aby czytający mógł je szybko przeczytać.
3 Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè; yóò máa yára sí ìgbẹ̀yìn kí yóò sìsọ èké. Bí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é; nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́.”
[To] widzenie bowiem [dotyczy] oznaczonego czasu, [a] na końcu oznajmi, a nie skłamie; [a] choćby się odwlekało, oczekuj go, bo z pewnością przyjdzie, nie spóźni się.
4 “Kíyèsi, ọkàn rẹ tí ó gbéga, ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n olódodo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.
Oto dusza tego, który się wywyższa, nie jest w nim prawa. Ale sprawiedliwy będzie żył ze swojej wiary.
5 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí wáìnì ni ẹ̀tàn, agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmi ẹni tí ó sọ ìwọra rẹ di gbígbòòrò bí isà òkú, ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn, ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀ ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. (Sheol h7585)
Owszem, ponieważ upija się, jest on hardym człowiekiem i nie pozostaje w [swoim] domu; pomnaża swoją żądzę jak piekło i jak śmierć nie może się nasycić, choć zgromadził u siebie wszystkie narody i zebrał u siebie wszystkich ludzi. (Sheol h7585)
6 “Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé, “‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i! Tí ó sì sọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípasẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́gbà! Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’
Czy ci wszyscy nie ułożą o nim przypowieści i szyderczego przysłowia, mówiąc: Biada temu, który gromadzi nie swoje rzeczy (jak długo?) i obciąża się gęstym błotem!
7 Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde ní òjijì? Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò jí, kí wọn ó sì dẹ́rùbà ọ́? Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.
Czy nie powstaną nagle [ci], którzy będą cię kąsać, i nie obudzą się [ci], którzy będą cię szarpać? A staniesz się dla nich łupem.
8 Nítorí ìwọ ti kó Orílẹ̀-èdè púpọ̀, àwọn ènìyàn tókù yóò sì kó ọ nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; nítorí ẹ̀jẹ̀, ìwọ tí pa ilẹ̀ àti ìlú ńlá run àti gbogbo ènìyàn to ń gbé inú rẹ̀.
Ponieważ złupiłeś wiele narodów, złupią cię też wszystkie pozostałe narody z powodu krwi ludzkiej i przemocy [dokonanej w] ziemi, miastu i wszystkim jego mieszkańcom.
9 “Ègbé ni fún ẹni tí ń jẹ èrè ìjẹkújẹ sí ilé rẹ̀, tí o sí gbé ìtẹ́ rẹ̀ lórí ibi gíga, kí a ba le gbà á sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ibi!
Biada temu, który chciwie pragnie niegodziwego zysku dla swego domu, aby wystawił wysoko swoje gniazdo i tak uszedł mocy zła!
10 Ìwọ ti gbìmọ̀ ìtìjú sí ilé rẹ nípa kíké ènìyàn púpọ̀ kúrò; ìwọ sì ti pàdánù ẹ̀mí rẹ.
Postanowiłeś wytracić wiele narodów na hańbę swemu domowi, a grzeszyłeś przeciwko własnej duszy.
11 Nítorí tí òkúta yóò kígbe jáde láti inú ògiri wá, àti ìtí igi láti inú igi rírẹ́ wá yóò sì dá a lóhùn.
Kamień bowiem będzie wołać z muru i sęk z drewna da [o tym] świadectwo.
12 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ kọ́ ìlú, tí o sì fi àìṣedéédéé tẹ ìlú ńlá dó?
Biada [temu], który krwią buduje miasto i utwierdza miasto nieprawością!
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun kò ha ti ṣètò rẹ̀ pé làálàá àwọn ènìyàn jẹ́ epo fún iná kí àwọn orílẹ̀-èdè náà sì máa ṣe wàhálà fún asán?
Czyż to nie [pochodzi] od PANA zastępów, że ludy będą się trudzić przy ogniu, a narody będą się męczyć daremnie?
14 Nítorí tí ayé yóò kún fún ìmọ̀ ògo Olúwa, bí omi ti bo Òkun.
Ziemia bowiem będzie napełniona poznaniem chwały PANA, jak wody napełniają morze.
15 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ohun mímu fún aládùúgbò rẹ̀, tí ó sì fi ọtí-lílé rẹ̀ fún un, tí o sì jẹ́ kó mu àmupara, kí ìwọ kí ó ba lè wo ìhòhò wọn.”
Biada temu, który poi swego bliźniego, przystawiając mu swe naczynie, aż go upoi, by patrzeć na jego nagość!
16 Ìtìjú yóò bò ọ́ dípò ògo, ìwọ náà mu pẹ̀lú kí ìhòhò rẹ kí ó lè hàn, ago ọwọ́ ọ̀tún Olúwa, yóò yípadà sí ọ, ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ.
Nasyciłeś się hańbą zamiast sławą; upij się sam i będziesz obnażony. Kielich prawicy PANA zwróci się przeciw tobie i sromotne wymioty [pokryją] twoją sławę.
17 Nítorí ìwà ipá tí ó tí hù sí Lebanoni yóò bò ọ́, àti ìparun àwọn ẹranko yóò dẹ́rùbà ọ́ mọ́lẹ̀. Nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; ìwọ tí pa ilẹ̀ náà àti ìlú ńlá run àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Okryje cię bowiem bezprawie Libanu i spustoszenie bestii, które ich straszyły, z powodu krwi ludzkiej i przemocy [dokonanej w] ziemi miastu i wszystkim jego mieszkańcom.
18 “Èrè kí ni òrìṣà ni, tí oníṣọ̀nà rẹ̀ fi gbẹ́ ẹ, ère dídá ti ń kọ ni èké? Nítorí ti ẹni ti ó dá a gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé ohun tí ó fúnra rẹ̀ dá; ó sì mọ ère tí kò le fọhùn.
Cóż pomoże rzeźbiony posąg, który wykonał jego rzemieślnik, [albo] odlany [obraz] i nauczyciel kłamstwa, aby rzemieślnik pokładał w nim ufność, czyniąc nieme bożki?
19 Ègbé ni fún ẹni ti ń sọ fún igi pé, ‘Di alààyè?’ Fún òkúta tí kò lè fọhùn pé, ‘Dìde.’ Ǹjẹ́ òun lè tọ́ ni sí ọ̀nà? Wúrà àti fàdákà ni a fi bò ó yíká; kò sì sí èémí kan nínú rẹ.”
Biada [temu], który mówi do drewna: Przebudź się, a do niemego kamienia: Obudź się! Czyż on może nauczać? Spójrz na niego, jest powleczony złotem i srebrem, ale nie ma w nim żadnego ducha.
20 Ṣùgbọ́n Olúwa wà nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; ẹ jẹ́ kí gbogbo ayé parọ́rọ́ níwájú rẹ.
PAN jest w swoim świętym przybytku. Niech cała ziemia zamilknie przed nim.

< Habakkuk 2 >