< Habakkuk 2 >

1 Èmi yóò dúró lórí ibusọ́ mi láti máa wòye, èmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóre, èmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún mi àti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí.
Őrhelyemre állok, és megállok a bástyán, és vigyázok, hogy lássam, mit szól hozzám, és mit feleljek én panaszom dolgában.
2 Nígbà náà ni Olúwa dáhùn pé, “Kọ ìṣípayá náà sílẹ̀ kí o sì fi hàn ketekete lórí wàláà kí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.
És felele nékem az Úr, és mondá: Írd fel e látomást, és vésd táblákra, hogy könnyen olvasható legyen.
3 Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè; yóò máa yára sí ìgbẹ̀yìn kí yóò sìsọ èké. Bí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é; nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́.”
Mert e látomás bizonyos időre szól, de vége felé siet és meg nem csal; ha késik is, bízzál benne; mert eljön, el fog jőni, nem marad el!
4 “Kíyèsi, ọkàn rẹ tí ó gbéga, ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n olódodo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.
Ímé, felfuvalkodott, nem igaz ő benne az ő lelke; az igaz pedig az ő hite által él.
5 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí wáìnì ni ẹ̀tàn, agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmi ẹni tí ó sọ ìwọra rẹ di gbígbòòrò bí isà òkú, ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn, ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀ ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. (Sheol h7585)
És bizony, a bor is megcsal: felgerjed a férfiú és nincsen nyugalma; ő, a ki tátja száját, mint a Seol, és olyan ő, mint a halál: telhetetlen, és magához ragad minden népet és magához csatol minden nemzetet. (Sheol h7585)
6 “Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé, “‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i! Tí ó sì sọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípasẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́gbà! Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’
Avagy nem költenek-é ezek mindnyájan példabeszédet róla, és találós mesét reá, mondván: Jaj annak, a ki rakásra gyűjti, a mi nem övé! De meddig? És a ki adóssággal terheli magát!
7 Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde ní òjijì? Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò jí, kí wọn ó sì dẹ́rùbà ọ́? Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.
Avagy nem támadnak-é hirtelen, a kik téged mardossanak, és nem serkennek-é fel, a kik háborgassanak téged? És zsákmányul esel nékik.
8 Nítorí ìwọ ti kó Orílẹ̀-èdè púpọ̀, àwọn ènìyàn tókù yóò sì kó ọ nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; nítorí ẹ̀jẹ̀, ìwọ tí pa ilẹ̀ àti ìlú ńlá run àti gbogbo ènìyàn to ń gbé inú rẹ̀.
Mivelhogy kifosztogattál sok nemzetet, kifosztanak téged mind a többi népek az emberek véréért, és az országok, városok és minden bennök lakozók ellen való erőszaktételért.
9 “Ègbé ni fún ẹni tí ń jẹ èrè ìjẹkújẹ sí ilé rẹ̀, tí o sí gbé ìtẹ́ rẹ̀ lórí ibi gíga, kí a ba le gbà á sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ibi!
Jaj annak, a ki bűnös szerzeményt szerez házának, hogy magasra rakhassa fészkét, hogy megszabadulhasson a gonosz hatalma elől.
10 Ìwọ ti gbìmọ̀ ìtìjú sí ilé rẹ nípa kíké ènìyàn púpọ̀ kúrò; ìwọ sì ti pàdánù ẹ̀mí rẹ.
Házadnak gyalázatára tervezted a sok nép kiirtását, és bűnössé tetted lelkedet.
11 Nítorí tí òkúta yóò kígbe jáde láti inú ògiri wá, àti ìtí igi láti inú igi rírẹ́ wá yóò sì dá a lóhùn.
Mert a kő is ellened kiált a falból, és a gerenda a fa-alkotmányból visszhangoz néki.
12 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ kọ́ ìlú, tí o sì fi àìṣedéédéé tẹ ìlú ńlá dó?
Jaj annak, a ki várost épít vérengzéssel, és a ki várat emel álnoksággal.
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun kò ha ti ṣètò rẹ̀ pé làálàá àwọn ènìyàn jẹ́ epo fún iná kí àwọn orílẹ̀-èdè náà sì máa ṣe wàhálà fún asán?
Avagy ímé, nem a Seregek Urától van-é ez, hogy a népek tűznek építenek, és a nemzetek a hiábavalóságnak fáradoznak?
14 Nítorí tí ayé yóò kún fún ìmọ̀ ògo Olúwa, bí omi ti bo Òkun.
Mert az Úr dicsőségének ismeretével betelik a föld, a miképen a folyamok megtöltik a tengert.
15 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ohun mímu fún aládùúgbò rẹ̀, tí ó sì fi ọtí-lílé rẹ̀ fún un, tí o sì jẹ́ kó mu àmupara, kí ìwọ kí ó ba lè wo ìhòhò wọn.”
Jaj annak, a ki megitatja felebarátját, epédet keverve belé, hogy megrészegítsed őt, hogy láthassad az ő szemérmöket!
16 Ìtìjú yóò bò ọ́ dípò ògo, ìwọ náà mu pẹ̀lú kí ìhòhò rẹ kí ó lè hàn, ago ọwọ́ ọ̀tún Olúwa, yóò yípadà sí ọ, ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ.
Gyalázattal telsz meg dicsőség helyett; igyál te is és láttassék szemérmed; reád fordul az Úr jobbjának pohara, és gyalázat borítja el dicsőségedet.
17 Nítorí ìwà ipá tí ó tí hù sí Lebanoni yóò bò ọ́, àti ìparun àwọn ẹranko yóò dẹ́rùbà ọ́ mọ́lẹ̀. Nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; ìwọ tí pa ilẹ̀ náà àti ìlú ńlá run àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Bizony, a libanoni erőszakoskodás gyászba borít téged, és a vadak pusztítása, a mely rettegteté őket, az emberek véréért és az országon, a városon és annak minden lakosán űzött erőszakosságért.
18 “Èrè kí ni òrìṣà ni, tí oníṣọ̀nà rẹ̀ fi gbẹ́ ẹ, ère dídá ti ń kọ ni èké? Nítorí ti ẹni ti ó dá a gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé ohun tí ó fúnra rẹ̀ dá; ó sì mọ ère tí kò le fọhùn.
Mit használ a faragott kép, hogy a faragója kifaragta azt? vagy az öntött kép és a mely hazugságot tanít, hogy a képnek faragója bízik abban, csinálván néma bálványokat?
19 Ègbé ni fún ẹni ti ń sọ fún igi pé, ‘Di alààyè?’ Fún òkúta tí kò lè fọhùn pé, ‘Dìde.’ Ǹjẹ́ òun lè tọ́ ni sí ọ̀nà? Wúrà àti fàdákà ni a fi bò ó yíká; kò sì sí èémí kan nínú rẹ.”
Jaj annak, aki fának mondja: Serkenj fel! néma kőnek: Ébredj fel! Taníthat-é ez? Ímé, borítva van aranynyal és ezüsttel, lélek pedig nincs benne semmi!
20 Ṣùgbọ́n Olúwa wà nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; ẹ jẹ́ kí gbogbo ayé parọ́rọ́ níwájú rẹ.
Ellenkezőleg az Úr az ő szent templomában, hallgasson előtte az egész föld!

< Habakkuk 2 >