< Habakkuk 2 >
1 Èmi yóò dúró lórí ibusọ́ mi láti máa wòye, èmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóre, èmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún mi àti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí.
Őrhelyemen hadd álljak és megálljak a sánczon: és kitekintek, hogy lássam mit beszél velem és mi választ nyerek szemrehányásomra.
2 Nígbà náà ni Olúwa dáhùn pé, “Kọ ìṣípayá náà sílẹ̀ kí o sì fi hàn ketekete lórí wàláà kí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.
És felelt nekem az Örökkévaló és mondta: Írd föl a látomást, és pedig világosan táblákra, azért hogy végig fusson rajta, a ki olvassa.
3 Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè; yóò máa yára sí ìgbẹ̀yìn kí yóò sìsọ èké. Bí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é; nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́.”
Mert még csak időre szól a látomás és a vég felé siet és nem hazudik; ha késedelmezik, várj reá, mert jőni, jőni fog, nem késik el.
4 “Kíyèsi, ọkàn rẹ tí ó gbéga, ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n olódodo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.
Íme felfuvalkodott, nem volt egyenes ő benne a lelke; de az igaz hűsége által él.
5 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí wáìnì ni ẹ̀tàn, agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmi ẹni tí ó sọ ìwọra rẹ di gbígbòòrò bí isà òkú, ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn, ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀ ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. (Sheol )
Hát még midőn a bor hűtelen, a fennhéjázó férfi nem tud nyugodni, a ki kitágította mint az alvilág a lelkét, s ő maga olyan, mint a halál és nem lakik jól; egybeszedte magának mind a nemzeteket, s egybe gyűjtötte magának mind a népeket. (Sheol )
6 “Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé, “‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i! Tí ó sì sọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípasẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́gbà! Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’
Nemde ezek mindannyian ő róla példázatot hangoztatnak, ékes beszédet, rejtvényeket ő reá; mondják ugyanis Oh az, ki abból gyarapít, mi nem az övé – meddig még? – és megterheli magát sarczczal.
7 Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde ní òjijì? Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò jí, kí wọn ó sì dẹ́rùbà ọ́? Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.
Nemde hirtelen támadnak kínzóid és ébrednek zaklatóid, hogy prédául légy nekik!
8 Nítorí ìwọ ti kó Orílẹ̀-èdè púpọ̀, àwọn ènìyàn tókù yóò sì kó ọ nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; nítorí ẹ̀jẹ̀, ìwọ tí pa ilẹ̀ àti ìlú ńlá run àti gbogbo ènìyàn to ń gbé inú rẹ̀.
Mert te kifosztottál sok nemzetet, kifosztanak majd téged mind a megmaradt népek, emberek elontott vére miatt; meg az erőszak miatt, országon, városon és mind a benne lakókon.
9 “Ègbé ni fún ẹni tí ń jẹ èrè ìjẹkújẹ sí ilé rẹ̀, tí o sí gbé ìtẹ́ rẹ̀ lórí ibi gíga, kí a ba le gbà á sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ibi!
Oh a ki nyerészkedik gonosz nyerészkedéssel a háza számára, hogy a magasban rakja meg fészkét, hogy megmeneküljön a veszedelem markából.
10 Ìwọ ti gbìmọ̀ ìtìjú sí ilé rẹ nípa kíké ènìyàn púpọ̀ kúrò; ìwọ sì ti pàdánù ẹ̀mí rẹ.
Szégyent tanácsoltál házadnak, kivágván sok népet, vétkeztél tenmagad ellen.
11 Nítorí tí òkúta yóò kígbe jáde láti inú ògiri wá, àti ìtí igi láti inú igi rírẹ́ wá yóò sì dá a lóhùn.
Mert kő a falból fog kiáltani és lécz a fa gerendázatból felel majd neki.
12 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ kọ́ ìlú, tí o sì fi àìṣedéédéé tẹ ìlú ńlá dó?
Oh a ki várost épít vérontással és várat megszilárdít jogtalansággal.
13 Olúwa àwọn ọmọ-ogun kò ha ti ṣètò rẹ̀ pé làálàá àwọn ènìyàn jẹ́ epo fún iná kí àwọn orílẹ̀-èdè náà sì máa ṣe wàhálà fún asán?
Nemde, íme, az Örökkévalótól, a seregek Urától van! Fáradnak tehát népek tűzért és nemzetek a semmiért bágyadnak el.
14 Nítorí tí ayé yóò kún fún ìmọ̀ ògo Olúwa, bí omi ti bo Òkun.
Mert megtelik majd a föld az Örökkévaló dicsőségének megismerésével, mint vizekkel, melyek a tengert borítják.
15 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ohun mímu fún aládùúgbò rẹ̀, tí ó sì fi ọtí-lílé rẹ̀ fún un, tí o sì jẹ́ kó mu àmupara, kí ìwọ kí ó ba lè wo ìhòhò wọn.”
Oh aki megitatja felebarátját, ki hozzáöntöd mérgedet, meg is részegítve őt, azért hogy oda tekints meztelenségükre.
16 Ìtìjú yóò bò ọ́ dípò ògo, ìwọ náà mu pẹ̀lú kí ìhòhò rẹ kí ó lè hàn, ago ọwọ́ ọ̀tún Olúwa, yóò yípadà sí ọ, ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ.
Jóllaktál gyalázattal inkább mint dicsőséggel; igyál te is, és meztelenedjél meg, kerüljön át te hozzád az Örökkévaló jobbjának serlege: csúfos gyalázat a te dicsőségedre!
17 Nítorí ìwà ipá tí ó tí hù sí Lebanoni yóò bò ọ́, àti ìparun àwọn ẹranko yóò dẹ́rùbà ọ́ mọ́lẹ̀. Nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; ìwọ tí pa ilẹ̀ náà àti ìlú ńlá run àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Mert elborít téged a Libánonon tett erőszak és a vadakon elkövetett pusztítás, mely rettenti őket, emberek elontott vére miatt, meg az erőszak miatt országon, városon és mind a benne lakókon.
18 “Èrè kí ni òrìṣà ni, tí oníṣọ̀nà rẹ̀ fi gbẹ́ ẹ, ère dídá ti ń kọ ni èké? Nítorí ti ẹni ti ó dá a gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé ohun tí ó fúnra rẹ̀ dá; ó sì mọ ère tí kò le fọhùn.
Mit használt a faragott kép, hogy faragta az alakítója, az öntött kép s a hazugságot tanító, hogy bízott az alakító az ő alkotásában, készítvén néma bálványokat?
19 Ègbé ni fún ẹni ti ń sọ fún igi pé, ‘Di alààyè?’ Fún òkúta tí kò lè fọhùn pé, ‘Dìde.’ Ǹjẹ́ òun lè tọ́ ni sí ọ̀nà? Wúrà àti fàdákà ni a fi bò ó yíká; kò sì sí èémí kan nínú rẹ.”
Oh s ki a fának mondja: ébredj – serkenj föl! a merev kőnek! Az tanítson? Íme foglalva van aranyba, ezüstbe és semmi szellem nincsen benne.
20 Ṣùgbọ́n Olúwa wà nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; ẹ jẹ́ kí gbogbo ayé parọ́rọ́ níwájú rẹ.
De az Örökkévaló az ő szent templomában – csitt előtte az egész föld!