< Habakkuk 1 >

1 Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.
A revelação que Habakkuk, o profeta, viu.
2 Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi? Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!” Ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
Yahweh, quanto tempo vou chorar, e você não vai ouvir? Eu clamo a você “Violência!” e você não vai salvar?
3 Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé? Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà? Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi; ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
Por que você me mostra iniquidade, e olha a perversidade? Pois a destruição e a violência estão diante de mim. Há contendas, e a contenda se levanta.
4 Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí, ìdájọ́ òdodo kò sì borí. Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká, nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.
Portanto a lei está paralisada, e a justiça nunca prevalece; pois os ímpios rodeiam os justos; portanto, a justiça sai pervertida.
5 “Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye, kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi. Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
“Olhe entre as nações, observe e maravilhe-se maravilhosamente, pois estou trabalhando em seus dias um trabalho que você não vai acreditar, embora lhe seja dito.
6 Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde, àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
Pois eis que estou levantando os caldeus, essa nação amarga e apressada que marcham pela largura da terra, para possuir moradas que não são deles.
7 Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà, ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn, yóò máa ti inú wọn jáde.
Eles são temidos e temidos. Seu julgamento e sua dignidade procedem de si mesmos.
8 Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ, wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká; wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré, wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun,
Seus cavalos também são mais rápidos que os leopardos, e são mais ferozes que os lobos da noite. Seus cavaleiros se orgulham de sua força. Sim, seus cavaleiros vêm de longe. Eles voam como uma águia que se apressa a devorar.
9 gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú; wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
Todos eles vêm em busca de violência. Suas hordas estão viradas para a frente. Eles reúnem os prisioneiros como areia.
10 Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé. Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín; nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á.
Yes, eles zombam dos reis, e os príncipes são um escárnio para eles. Eles riem de cada fortaleza, pois constroem uma rampa de terra e a tomam.
11 Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà, yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”
então eles varrem como o vento e seguem em frente. Eles são de fato culpados, cuja força é seu deus”.
12 Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà? Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́; Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí.
Aren você não é do eterno, Yahweh meu Deus, meu Santo? Nós não vamos morrer. Yahweh, você os nomeou para julgamento. Você, Rock, o estabeleceu para puni-lo.
13 Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi; ìwọ kò le gbà ìwà ìkà nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè? Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
Tu que tens olhos mais puros do que para ver o mal, e que não podes ver a perversidade, por que toleras aqueles que lidam traiçoeiramente e se calam quando o ímpio engole o homem que é mais justo do que ele,
14 Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun, bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso.
e faz os homens como os peixes do mar, como as coisas rastejantes que não têm nenhum governante sobre eles?
15 Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀; nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
Ele os toma a todos com o anzol. Ele os captura em sua rede e os reúne em sua rede de arrastão. Portanto, ele se regozija e se alegra.
16 Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀, ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀ nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
Por isso ele se sacrifica à sua rede e queima incenso ao seu arrastão, porque por eles sua vida é luxuosa e sua comida é boa.
17 Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí, tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?
Será que ele esvaziará continuamente sua rede e matará as nações sem piedade?

< Habakkuk 1 >