< Habakkuk 1 >

1 Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.
[I am] Habakkuk, a prophet. This is the [message that Yahweh] gave to me in a vision.
2 Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi? Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!” Ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
[I said, ] “Yahweh, how long must I continue to call [to you] for help before you respond? I cry out to you [for help], saying that [people are acting] violently [everywhere], but you do not rescue us!
3 Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé? Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà? Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi; ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
(Must I/I do not want to) continue seeing people doing what is unjust [RHQ]. Why do you not punish people who are doing what is wrong [RHQ]? I see people destroying things and [acting] violently. There is fighting and quarreling [everywhere].
4 Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí, ìdájọ́ òdodo kò sì borí. Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká, nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.
No one obeys laws [PRS], and judges [PRS] never do what is fair/just. Wicked people always defeat righteous people [in the courts], with the result that matters are never decided fairly/justly.”
5 “Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye, kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi. Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
[Yahweh replied to me, ] “[I know that what you say is true, but] look around at [what is happening in] the other nations; [if you look, ] you will be amazed, because I am doing something during this time that you would not believe [would happen], even if someone told you about it.
6 Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde, àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
The soldiers of Babylonia are fierce/cruel and swift. And now I am causing them [to become very powerful]; they will march across the world and conquer [many] other countries.
7 Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà, ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn, yóò máa ti inú wọn jáde.
They are people whom [others] fear very much [DOU], and they do whatever they want to, paying no attention to the laws of other countries.
8 Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ, wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká; wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré, wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun,
The horses [that pull their chariots] go faster than leopards, and they are fiercer than wolves are in the evening. The horses on which the soldiers ride gallop swiftly; the soldiers riding them come from distant places. They are like [SIM] eagles that swoop down to [snatch and] kill small animals.
9 gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú; wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
As they ride along, [they are] determined to act violently. They advance like [SIM] a wind from the desert, gathering prisoners that are as [numerous as grains of] sand.
10 Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé. Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín; nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á.
They make fun of kings and princes [of other countries], and they ridicule all the cities that have high walls around them. They pile dirt [outside those walls] [in order to climb up] and capture those cities.
11 Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà, yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”
They rush past like the wind, and then they go [to attack other cities]. But they are very guilty, because [they think that] their own power is their god.”
12 Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà? Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́; Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí.
[Then I said, ] “Yahweh, you have certainly [RHQ] always/forever been God. You are my Holy One; you will not die. So [why] have you appointed those men [from Babylonia] to judge and get rid of [us]? You are like [MET] a huge rock [under which we are protected/safe], so why have you sent them to punish us?
13 Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi; ìwọ kò le gbà ìwà ìkà nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè? Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
You [SYN] are pure, and you cannot endure looking at what is evil, [so why] are you ignoring men who are treacherous? Why do you do nothing [to punish] those wicked men [from Babylonia] who destroy people who are more righteous than they [are]?
14 Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun, bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso.
[Do you consider that] we are like fish in the sea, or like other creatures in the sea, that have no ruler?
15 Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀; nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
[The soldiers of Babylonia think that we are fish] [RHQ] for them to pull out of the sea with hooks or to catch in their nets, while they rejoice and celebrate.
16 Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀, ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀ nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
If they catch us, they will [worship] their weapons [MET] with which they captured us, and offer sacrifices to them and burn incense in front of them! [They will say] ‘Those weapons have enabled us to become rich and be able to eat expensive food.’
17 Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí, tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?
[Will you allow] them to continue [to conquer people] [MET] forever? [Will you allow] them to destroy people of other nations without their being merciful [to anyone]?”

< Habakkuk 1 >