+ Genesis 1 >

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ohun gbogbo Ọlọ́run dá àwọn ọ̀run àti ayé.
Kezdetben teremtette Isten az eget és a földet.
2 Ayé sì wà ní rúdurùdu, ó sì ṣófo, òkùnkùn sì wà lójú ibú omi, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì ń rábàbà lójú omi.
És a föld puszta és kietlen volt és sötétség volt a mélység színe fölött; Isten szelleme pedig lebegett a vizek színe fölött.
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà,” ìmọ́lẹ̀ sì wà.
És mondta Isten: Legyen világosság! És lett világosság.
4 Ọlọ́run rí i pé ìmọ́lẹ̀ náà dára, ó sì ya ìmọ́lẹ̀ náà sọ́tọ̀ kúrò lára òkùnkùn.
És látta Isten a világosságot, hogy jó és elválasztotta Isten a világosságot a sötétségtől.
5 Ọlọ́run sì pe ìmọ́lẹ̀ náà ní “ọ̀sán,” àti òkùnkùn ní “òru.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní.
És elnevezte Isten a világosságot nappalnak, a sötétséget pedig elnevezte éjjelnek. És lett este és lett reggel: egy nap.
6 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí òfúrufú kí ó wà ní àárín àwọn omi, láti pààlà sí àárín àwọn omi.”
És mondta Isten: Legyen boltozat a vizek közepében, hogy legyen elválasztó víz és víz között.
7 Ọlọ́run sì dá òfúrufú láti ya omi tí ó wà ní òkè òfúrufú kúrò lára omi tí ó wà ní orí ilẹ̀. Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
És alkotta Isten a boltozatot és elválasztotta a vizeket, melyek a boltozat alatt vannak, a vizektől, melyek a boltozat fölött vannak. És úgy lett.
8 Ọlọ́run sì pe òfúrufú ní “ọ̀run.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kejì.
És elnevezte Isten a boltozatot égnek. És lett este és lett reggel: második nap.
9 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi abẹ́ ọ̀run wọ́ papọ̀ sí ojú kan, kí ilẹ̀ gbígbẹ sì farahàn.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
És mondta Isten: Gyűljenek össze a vizek az ég alatt egy helyre, hogy meglássák a száraz! És úgy lett
10 Ọlọ́run sì pe ilẹ̀ gbígbẹ náà ní “ilẹ̀,” àti àpapọ̀ omi ní “òkun.” Ọlọ́run sì rí i wí pé ó dára.
És elnevezte Isten a szárazat földnek, a vizek gyüleményét meg elnevezte tengereknek: És látta Isten, hogy jó.
11 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó hu ọ̀gbìn: ewéko ti yóò máa mú èso wá àti igi tí yóò máa so èso ní irú tirẹ̀, tí ó ní irúgbìn nínú.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
Akkor mondta Isten: Sarjasszon a föld sarjadékot, füvet, mely magot hoz, gyümölcsfát, gyümölcstermőt a maga neme szerint, amelynek magva benne van a földön! És úgy lett.
12 Ilẹ̀ sì hù ọ̀gbìn: ewéko tí ó ń so èso ní irú tirẹ̀, àti igi tí ń so èso, tí ó ní irúgbìn nínú ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì ri pé ó dára.
És előhozott a föld sarjadékot, füvet, mely magot hoz, a maga neme szerint és fát, gyümölcstermőt, melynek magva benne van, a maga neme szerint. És látta Isten, hogy jó.
13 Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹta.
És lett este és lett reggel: harmadik nap.
14 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà ní ojú ọ̀run, láti pààlà sí àárín ọ̀sán àti òru, kí wọn ó sì máa wà fún àmì láti mọ àwọn àsìkò, àti àwọn ọjọ́ àti àwọn ọdún.
És mondta Isten: Legyenek világítók az ég boltozatán, hogy elválasszák a nappalt az éjjeltől és legyenek jelekül ünnepek, napok és évek számára;
15 Kí wọn ó jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ní ojú ọ̀run láti tan ìmọ́lẹ̀ sí orí ilẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
és legyenek világítókul az ég boltozatán, hogy világítsanak a földre! És úgy lett.
16 Ọlọ́run dá ìmọ́lẹ̀ ńlá ńlá méjì, ìmọ́lẹ̀ tí ó tóbi láti ṣe àkóso ọ̀sán àti ìmọ́lẹ̀ tí ó kéré láti ṣe àkóso òru. Ó sì dá àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú.
És alkotta Isten a két nagy világítót; a nagyobbik világítót nappali uralomra és a kisebbik világítót éjjeli uralomra, meg a csillagokat.
17 Ọlọ́run sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ sí ojú ọ̀run láti máa tan ìmọ́lẹ̀ si orí ilẹ̀,
És tette azokat Isten az ég boltozatára, hogy világítsanak a földre,
18 láti ṣàkóso ọ̀sán àti òru àti láti pààlà sí àárín ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
és hogy uralkodjanak nappal és éjjel, és hogy elválasszák a világosságot a sötétségtől. És látta Isten, hogy jó.
19 Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹrin.
És lett este és lett reggel: negyedik nap.
20 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi kí ó kún fún àwọn ohun alààyè, kí àwọn ẹyẹ kí ó sì máa fò ní òfúrufú.”
És mondta Isten: Nyüzsögjenek a vizek élőlények nyüzsgésétől, a madár pedig röpdössön a föld fölött, az ég boltozatának színén!
21 Nítorí náà Ọlọ́run dá àwọn ẹ̀dá alààyè ńlá ńlá sí inú òkun, àwọn ohun ẹlẹ́mìí àti àwọn ohun tí ń rìn ní onírúurú tiwọn, àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́ ní onírúurú tiwọn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
És teremtette Isten a nagy tengeri szörnyeket és mind az élőlényt, mely mozog; amelyektől nyüzsögtek a vizek, a maguk neme szerint, és mind a szárnyas madarat, a maga neme szerint. És látta Isten, hogy jó.
22 Ọlọ́run súre fún wọn, ó sì wí pé, “Ẹ máa bí sí i, ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ kún inú omi òkun, kí àwọn ẹyẹ náà sì máa pọ̀ sí i ní orí ilẹ̀.”
És megáldotta azokat Isten, mondván: Szaporodjatok, sokasodjatok és töltsétek be a vizet a tengerekben, és a madár sokasodjék a földön.
23 Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ karùn-ún.
És lett este és lett reggel: ötödik nap.
24 Ọlọ́run sì wí pé, “Kí ilẹ̀ kí ó mú ohun alààyè jáde ní onírúurú wọn: ẹran ọ̀sìn, àwọn ohun afàyàfà àti àwọn ẹran inú igbó, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní irú tirẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
És mondta Isten: Hozzon elő a föld élőlényt a maga neme szerint, barmot és csúszó-mászót, meg földi vadat a maga neme szerint! És úgy lett.
25 Ọlọ́run sì dá ẹranko inú igbó àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ní irú tirẹ̀ àti gbogbo ohun alààyè tí ń rìn ní ilẹ̀ ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
És alkotta Isten a föld vadját a maga neme szerint, a barmot a maga neme szerint és a föld minden csúszó-mászóját a maga neme szerint. És látta Isten, hogy jó.
26 Lẹ́yìn náà ni Ọlọ́run wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a dá ènìyàn ní àwòrán ara wa, gẹ́gẹ́ bí àwa ti rí, kí wọn kí ó jẹ ọba lórí ẹja òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run, ẹran ọ̀sìn, gbogbo ilẹ̀ àti lórí ohun gbogbo tí ń rìn lórí ilẹ̀.”
És mondta Isten: Alkossunk embert képmásunkra, hasonlatosságunk szerint, hogy uralkodjék a tenger halán, az ég madarán és a barmon, meg az egész földön és minden csúszó-mászón, mely mozog a földön.
27 Nítorí náà, Ọlọ́run dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀, ní àwòrán Ọlọ́run ni ó dá a, akọ àti abo ni ó dá wọn.
És teremtette Isten az embert az ő képmására, Isten képmására teremtette őt; férfinak és nőnek teremtette őket.
28 Ọlọ́run sì súre fún wọn, Ọlọ́run sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ ṣe ìkápá ayé. Ẹ ṣe àkóso àwọn ẹja inú òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó ń rìn ní orí ilẹ̀.”
Megáldotta őket Isten és mondta nekik Isten: Szaporodjatok, sokasodjatok, töltsétek be a földet és hódísátok meg; és uralkodjatok a tenger halán, az ég madarán és minden élőn, mely mozog a földön.
29 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo fi gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ń so èso fún un yín bí oúnjẹ àti àwọn igi eléso pẹ̀lú. Gbogbo rẹ̀ yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín.
És mondta Isten: Íme, adtam nektek minden füvet, mely magot hoz, amely az egész föld színén van és minden fát, melyen rajta van a fa gyümölcse, mely magot hoz; tiétek legyen eledelül.
30 Àti fún àwọn ẹranko inú igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ohun afàyàfà, gbogbo ohun tó ní èémí ìyè nínú ni mo fi ewéko fún bí oúnjẹ.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
A föld minden vadjának pedig, meg az ég minden madarának és mindennek, ami mozog a földön, amiben élő lélek van, minden zöld füvet (adtam) eledelül. És úgy lett.
31 Ọlọ́run sì rí àwọn ohun gbogbo tí ó dá, ó dára gidigidi. Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹfà.
És látta Isten mindazt, amit alkotott, hogy íme igen jó. És lett este és lett reggel: a hatodik nap.

+ Genesis 1 >