< Genesis 9 >

1 Ọlọ́run sì súre fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ wí pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì pọ̀ ní iye, kí ẹ sì kún ayé.
Bog je blagoslovil Noeta in njegove sinove ter jim rekel: »Bodite rodovitni in se množite ter na novo napolnite zemljo.
2 Ẹ̀rù yín yóò mú ojo wà lára gbogbo ẹranko àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀; àti gbogbo ẹja òkun; a fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
Strah pred vami in groza pred vami bo na vsaki zemeljski živali in na vsaki zračni perjadi, na vsem, kar se giba na zemlji in na vseh ribah morja; izročene so v vašo roko.
3 Gbogbo ohun tó wà láààyè tí ó sì ń rìn, ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín, bí mo ṣe fi ewéko fún un yín náà ni mo fi ohun gbogbo fún un yín.
Vsaka gibajoča stvar, ki živi, naj bo hrana za vas; celó kakor zelena zelišča, sem vam izročil vse stvari.
4 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Toda mesa z njegovim življenjem, ki je njegova kri, ne boste jedli.
5 Nítòótọ́ ẹ̀jẹ̀ yín, àní ẹ̀mí yín, ni èmi yóò sì béèrè; lọ́wọ́ gbogbo ẹranko ni èmí yóò béèrè rẹ̀, àti lọ́wọ́ ènìyàn, lọ́wọ́ arákùnrin olúkúlùkù ènìyàn ni èmi yóò béèrè ẹ̀mí ènìyàn.
Zagotovo bom terjal vašo kri vaših življenj. Terjal jo bom iz roke vsake živali in iz človeške roke. Iz roke vsakega človekovega brata bom terjal človeško življenje.
6 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀, láti ọwọ́ ènìyàn ni a ó gbà ta ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀. Nítorí ní àwòrán Ọlọ́run ni Ọlọ́run dá ènìyàn.
Kdorkoli prelije človeško kri, bo po človeku prelita njegova kri, kajti človeka je naredil po Božji podobi.
7 Ṣùgbọ́n ní tiyín, ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ máa gbá yìn lórí ilẹ̀, kí ẹ sì pọ̀ sí i lórí rẹ̀.”
Vi pa bodite rodovitni in se množite, na zemlji obilno obrodite in se množite na njej.«
8 Ọlọ́run sì wí fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé,
Bog je spregovoril Noetu ter z njim njegovim sinovom, rekoč:
9 “Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín àti pẹ̀lú àwọn ìran yín tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
»Jaz, glejte, jaz vzpostavljam svojo zavezo z vami in z vašim zarodom za vami
10 Àti pẹ̀lú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, ìbá à ṣe ẹyẹ, ẹja, ẹran ọ̀sìn, ẹranko igbó, gbogbo ohun tí ó jáde kúrò nínú ọkọ̀ pẹ̀lú yín, àní gbogbo ẹ̀dá alààyè ní ayé.
in z vsakim živim ustvarjenim bitjem, ki je z vami, od perjadi, od živine in od vsake zemeljske živali z vami; od vsega, kar prihaja iz ladje, do vsake zemeljske živali.
11 Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín láéláé, Èmi kì yóò fi ìkún omi pa ayé run kúrò mọ láéláé, a kì yóò fi omi pa ayé run.”
In z vami bom vzpostavil svojo zavezo; niti vse meso ne bo več iztrebljeno s poplavnimi vodami niti ne bo več poplave, da uniči zemljo.«
12 Ọlọ́run sì wí pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ń dá yìí láàrín èmi àti ẹ̀yin àti ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, májẹ̀mú àtìrandíran tó ń bọ̀:
Bog je rekel: »To je simbol zaveze, ki jo sklepam med seboj in vami in vsakim živim ustvarjenim bitjem, ki je z vami, za neprestane rodove.
13 Mo ti fi òṣùmàrè sí àwọsánmọ̀, yóò sì jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín èmi àti ayé.
Svojo mavrico postavim v oblak in ta bo za simbol zaveze med menoj in zemljo.
14 Nígbàkígbà tí mo bá mú kí òjò ṣú, tí òṣùmàrè bá farahàn ní àwọsánmọ̀.
In zgodilo se bo, ko nad zemljo privedem oblak, da bo mavrica vidna v oblaku
15 Èmi yóò rántí májẹ̀mú mi, tí ó wà láàrín èmi àti ẹ̀yin àti gbogbo ẹ̀dá alààyè, kì yóò sì tún sí ìkún omi mọ́ láti pa gbogbo ẹ̀dá run.
in spomnil se bom svoje zaveze, ki je med menoj in vami in vsakim živim ustvarjenim bitjem od vsega mesa in vode ne bodo več postale poplava, da uničijo vse meso.
16 Nígbàkígbà tí òṣùmàrè bá yọ ní àwọsánmọ̀, èmi yóò rí i, èmi yóò sì rántí májẹ̀mú ayérayé tí ń bẹ láàrín Ọlọ́run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń bẹ ní ayé.”
In v oblaku bo mavrica in pogledal bom nanjo, da se bom lahko spomnil večne zaveze med Bogom in vsakim živim ustvarjenim bitjem od vsega mesa, ki je na zemlji.«
17 Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ láàrín èmi àti gbogbo alààyè ní ayé.”
Bog je rekel Noetu: »To je simbol zaveze, ki sem jo utrdil med seboj in vsem mesom, ki je na zemlji.«
18 Àwọn ọmọ Noa tí ó jáde nínú ọkọ̀ ni Ṣemu, Hamu àti Jafeti. (Hamu ni baba Kenaani.)
Noetovi sinovi, ki so se izkrcali iz ladje, so bili Sem, Ham in Jafet. Ham pa je Kánaanov oče.
19 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Noa mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ni gbogbo ènìyàn ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ ayé.
To so trije Noetovi sinovi, in od njih je bila prekrita vsa zemlja.
20 Noa bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ àgbẹ̀, ó sì gbin ọgbà àjàrà.
In Noe je začel biti poljedelec ter zasadil vinograd
21 Ó mu àmupara nínú ọtí wáìnì àjàrà rẹ̀, ó sì tú ara rẹ̀ sí ìhòhò, ó sì sùn nínú àgọ́ rẹ̀.
in pil od vina in se napil in bil je nag v svojem šotoru.
22 Hamu tí í ṣe baba Kenaani sì rí baba rẹ̀ ní ìhòhò bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ méjèèjì ní ìta.
Ham, Kánaanov oče, pa je videl nagoto svojega očeta in zunaj povedal svojima dvema bratoma.
23 Ṣùgbọ́n Ṣemu àti Jafeti mú aṣọ lé èjìká wọn, wọ́n sì fi ẹ̀yìn rìn, wọ́n sì bo ìhòhò baba wọn. Wọ́n kọjú sẹ́yìn kí wọn kí ó má ba à rí ìhòhò baba wọn.
Sem in Jafet sta vzela obleko in si jo položila na obe njuni rami in šla, obrnjena nazaj in pokrila nagoto njunega očeta. In njuna obraza sta bila obrnjena nazaj in nista videla očetove nagote.
24 Nígbà tí Noa kúrò ní ojú ọtí, tí ó sì mọ ohun tí ọmọ rẹ̀ kékeré ṣe sí i.
Noe se je prebudil iz svojega vina ter spoznal, kaj mu je storil njegov mlajši sin.
25 Ó wí pé, “Ègún ni fún Kenaani. Ìránṣẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ni yóò máa ṣe fún àwọn arákùnrin rẹ̀.”
Rekel je: »Preklet bodi, Kánaan. Svojim bratom bo služabnik služabnikov.«
26 Ó sì tún wí pé, “Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ṣemu Kenaani yóò máa ṣe ẹrú fún Ṣemu.
Rekel je: »Blagoslovljen bodi Semov Gospod Bog, Kánaan pa bo njegov služabnik.
27 Ọlọ́run yóò mú Jafeti gbilẹ̀, Jafeti yóò máa gbé ní àgọ́ Ṣemu Kenaani yóò sì jẹ́ ẹrú fún un.”
Bog bo povečal Jafeta in prebival bo v Semovih šotorih, Kánaan pa bo njegov služabnik.«
28 Noa wà láààyè fún irinwó ọdún dín àádọ́ta lẹ́yìn ìkún omi.
Noe je po poplavi živel tristo petdeset let.
29 Àpapọ̀ ọjọ́ ayé Noa jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún dín làádọ́ta, ó sì kú.
Vseh Noetovih dni je bilo devetsto petdeset let, in je umrl.

< Genesis 9 >