< Genesis 9 >

1 Ọlọ́run sì súre fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ wí pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì pọ̀ ní iye, kí ẹ sì kún ayé.
Şi Dumnezeu a binecuvântat pe Noe şi pe fiii lui şi le-a spus: Fiţi roditori şi înmulţiţi-vă şi umpleţi pământul.
2 Ẹ̀rù yín yóò mú ojo wà lára gbogbo ẹranko àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀; àti gbogbo ẹja òkun; a fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
Şi teama de voi şi groaza de voi va fi peste fiecare fiară a pământului şi peste fiecare pasăre a cerului, peste tot ce se mişcă pe pământ şi peste toţi peştii mării; în mâna voastră sunt ele predate.
3 Gbogbo ohun tó wà láààyè tí ó sì ń rìn, ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín, bí mo ṣe fi ewéko fún un yín náà ni mo fi ohun gbogbo fún un yín.
Tot ce se mişcă şi trăieşte va fi mâncare pentru voi; precum planta verde, v-am dat toate lucrurile.
4 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Dar carne cu viaţa ei, ceea ce este sângele ei, să nu mâncaţi.
5 Nítòótọ́ ẹ̀jẹ̀ yín, àní ẹ̀mí yín, ni èmi yóò sì béèrè; lọ́wọ́ gbogbo ẹranko ni èmí yóò béèrè rẹ̀, àti lọ́wọ́ ènìyàn, lọ́wọ́ arákùnrin olúkúlùkù ènìyàn ni èmi yóò béèrè ẹ̀mí ènìyàn.
Şi cu adevărat sângele vostru, al vieţilor voastre, îl voi cere, din mâna fiecărei fiare îl voi cere şi din mâna omului, din mâna fiecărui frate al omului voi cere viaţa omului.
6 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀, láti ọwọ́ ènìyàn ni a ó gbà ta ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀. Nítorí ní àwòrán Ọlọ́run ni Ọlọ́run dá ènìyàn.
Oricine varsă sângele omului, prin om să fie vărsat sângele lui, pentru că după chipul lui Dumnezeu l-a făcut pe om.
7 Ṣùgbọ́n ní tiyín, ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ máa gbá yìn lórí ilẹ̀, kí ẹ sì pọ̀ sí i lórí rẹ̀.”
Şi voi fiţi roditori şi înmulţiţi-vă, naşteţi abundent pe pământ şi înmulţiţi-vă pe acesta.
8 Ọlọ́run sì wí fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé,
Şi Dumnezeu i-a vorbit lui Noe şi fiilor lui cu el, spunând:
9 “Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín àti pẹ̀lú àwọn ìran yín tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
Şi eu, iată, întemeiez legământul meu cu voi şi cu sămânţa voastră după voi;
10 Àti pẹ̀lú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, ìbá à ṣe ẹyẹ, ẹja, ẹran ọ̀sìn, ẹranko igbó, gbogbo ohun tí ó jáde kúrò nínú ọkọ̀ pẹ̀lú yín, àní gbogbo ẹ̀dá alààyè ní ayé.
Şi cu fiecare creatură vie care este cu voi, dintre păsări, dintre vite şi dintre fiecare fiară a pământului cu voi, de la tot ceea ce iese afară din arcă, până la fiecare fiară a pământului.
11 Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín láéláé, Èmi kì yóò fi ìkún omi pa ayé run kúrò mọ láéláé, a kì yóò fi omi pa ayé run.”
Şi voi întemeia legământul meu cu voi şi nici nu va mai fi toată făptura stârpită vreodată prin apele unui potop, nici nu va mai fi vreodată un potop să distrugă pământul.
12 Ọlọ́run sì wí pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ń dá yìí láàrín èmi àti ẹ̀yin àti ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, májẹ̀mú àtìrandíran tó ń bọ̀:
Şi Dumnezeu a spus: Acesta este semnul legământului pe care îl fac între mine şi voi şi fiecare creatură vie care este cu voi, pentru generaţii pentru totdeauna:
13 Mo ti fi òṣùmàrè sí àwọsánmọ̀, yóò sì jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín èmi àti ayé.
Eu aşez curcubeul meu în nor şi acesta va fi ca semn al unui legământ între mine şi pământ.
14 Nígbàkígbà tí mo bá mú kí òjò ṣú, tí òṣùmàrè bá farahàn ní àwọsánmọ̀.
Şi se va întâmpla, când aduc un nor peste pământ, că se va vedea curcubeul în nor:
15 Èmi yóò rántí májẹ̀mú mi, tí ó wà láàrín èmi àti ẹ̀yin àti gbogbo ẹ̀dá alààyè, kì yóò sì tún sí ìkún omi mọ́ láti pa gbogbo ẹ̀dá run.
Şi îmi voi aminti de legământul meu, care este între mine şi voi şi fiecare creatură vie a toată făptura; şi apele nu vor mai deveni un potop ca să nimicească toată făptura.
16 Nígbàkígbà tí òṣùmàrè bá yọ ní àwọsánmọ̀, èmi yóò rí i, èmi yóò sì rántí májẹ̀mú ayérayé tí ń bẹ láàrín Ọlọ́run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń bẹ ní ayé.”
Şi curcubeul va fi în nor şi îl voi privi, ca să îmi amintesc de legământul veşnic dintre Dumnezeu şi fiecare creatură vie, a toată făptura, care este pe pământ.
17 Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ láàrín èmi àti gbogbo alààyè ní ayé.”
Şi Dumnezeu i-a spus lui Noe: Acesta este semnul legământului, pe care l-am întemeiat între mine şi toată făptura care este pe pământ.
18 Àwọn ọmọ Noa tí ó jáde nínú ọkọ̀ ni Ṣemu, Hamu àti Jafeti. (Hamu ni baba Kenaani.)
Şi fiii lui Noe, care au ieşit din arcă, au fost Sem şi Ham şi Iafet; şi Ham este tatăl lui Canaan.
19 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Noa mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ni gbogbo ènìyàn ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ ayé.
Aceştia sunt cei trei fii ai lui Noe şi din ei a fost acoperit întregul pământ.
20 Noa bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ àgbẹ̀, ó sì gbin ọgbà àjàrà.
Şi Noe a început a fi agricultor şi a sădit o vie;
21 Ó mu àmupara nínú ọtí wáìnì àjàrà rẹ̀, ó sì tú ara rẹ̀ sí ìhòhò, ó sì sùn nínú àgọ́ rẹ̀.
Şi a băut din vin şi s-a îmbătat şi s-a dezgolit înăuntrul cortului său.
22 Hamu tí í ṣe baba Kenaani sì rí baba rẹ̀ ní ìhòhò bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ méjèèjì ní ìta.
Şi Ham, tatăl lui Canaan, a văzut goliciunea tatălui său şi a spus celor doi fraţi ai săi de afară.
23 Ṣùgbọ́n Ṣemu àti Jafeti mú aṣọ lé èjìká wọn, wọ́n sì fi ẹ̀yìn rìn, wọ́n sì bo ìhòhò baba wọn. Wọ́n kọjú sẹ́yìn kí wọn kí ó má ba à rí ìhòhò baba wọn.
Şi Sem şi Iafet au luat o haină şi au pus-o peste amândoi umerii lor şi au mers cu spatele şi au acoperit goliciunea tatălui lor şi feţele lor erau întoarse şi nu au văzut goliciunea tatălui lor.
24 Nígbà tí Noa kúrò ní ojú ọtí, tí ó sì mọ ohun tí ọmọ rẹ̀ kékeré ṣe sí i.
Şi Noe s-a trezit din beţia vinului său şi a cunoscut ceea ce fiul său mai tânăr i-a făcut.
25 Ó wí pé, “Ègún ni fún Kenaani. Ìránṣẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ni yóò máa ṣe fún àwọn arákùnrin rẹ̀.”
Şi a spus: Blestemat fie Canaan, un servitor al servitorilor va fi el fraţilor săi.
26 Ó sì tún wí pé, “Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ṣemu Kenaani yóò máa ṣe ẹrú fún Ṣemu.
Şi a spus: Binecuvântat fie DOMNUL Dumnezeul lui Sem; şi Canaan va fi servitorul lui.
27 Ọlọ́run yóò mú Jafeti gbilẹ̀, Jafeti yóò máa gbé ní àgọ́ Ṣemu Kenaani yóò sì jẹ́ ẹrú fún un.”
Dumnezeu va lărgi pe Iafet şi va locui în corturile lui Sem şi Canaan va fi servitorul lui.
28 Noa wà láààyè fún irinwó ọdún dín àádọ́ta lẹ́yìn ìkún omi.
Şi Noe a trăit după potop trei sute cincizeci de ani.
29 Àpapọ̀ ọjọ́ ayé Noa jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún dín làádọ́ta, ó sì kú.
Şi toate zilele lui Noe au fost nouă sute cincizeci de ani; şi a murit.

< Genesis 9 >