< Genesis 9 >

1 Ọlọ́run sì súre fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ wí pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì pọ̀ ní iye, kí ẹ sì kún ayé.
I błogosławił Bóg Noego, i syny jego, i rzekł im: Rozradzajcie się, i rozmnażajcie się, i napełniajcie ziemię.
2 Ẹ̀rù yín yóò mú ojo wà lára gbogbo ẹranko àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀; àti gbogbo ẹja òkun; a fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
A strach wasz i bojaźń wasza będzie nad wszelkiem zwierzęciem ziemi, i nad wszystkiem ptastwem niebieskiem, i nad wszystkiem, co się rucha na ziemi, i nad wszystkiemi rybami morskiemi: w rękę waszę podane są.
3 Gbogbo ohun tó wà láààyè tí ó sì ń rìn, ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín, bí mo ṣe fi ewéko fún un yín náà ni mo fi ohun gbogbo fún un yín.
Wszystko co się rucha, i co żyje, wam będzie na pokarm, jako jarzynę zieloną, dałem wam to wszystko.
4 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Wszakże mięsa z duszą jego, która jest krew jego, jeść nie będziecie.
5 Nítòótọ́ ẹ̀jẹ̀ yín, àní ẹ̀mí yín, ni èmi yóò sì béèrè; lọ́wọ́ gbogbo ẹranko ni èmí yóò béèrè rẹ̀, àti lọ́wọ́ ènìyàn, lọ́wọ́ arákùnrin olúkúlùkù ènìyàn ni èmi yóò béèrè ẹ̀mí ènìyàn.
A zaiste krwi waszej, dusz waszych szukać będę, z ręki każdej bestyi szukać jej będę: także z ręki człowieczej, z ręki każdego brata jego będę szukał duszy człowieczej.
6 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀, láti ọwọ́ ènìyàn ni a ó gbà ta ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀. Nítorí ní àwòrán Ọlọ́run ni Ọlọ́run dá ènìyàn.
Kto wyleje krew człowieczą, przez człowieka krew jego wylana będzie: bo na wyobrażenie Boże uczynion jest człowiek.
7 Ṣùgbọ́n ní tiyín, ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ máa gbá yìn lórí ilẹ̀, kí ẹ sì pọ̀ sí i lórí rẹ̀.”
A wy rozradzajcie się, i rozmnażajcie się, rozpładzajcie się na ziemi, i mnóżcie się na niej.
8 Ọlọ́run sì wí fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé,
Tedy rzekł Bóg do Noego, i do synów jego z nim, mówiąc:
9 “Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín àti pẹ̀lú àwọn ìran yín tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
A Ja, oto Ja stanowię przymierze moje z wami, i z nasieniem waszem po was.
10 Àti pẹ̀lú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, ìbá à ṣe ẹyẹ, ẹja, ẹran ọ̀sìn, ẹranko igbó, gbogbo ohun tí ó jáde kúrò nínú ọkọ̀ pẹ̀lú yín, àní gbogbo ẹ̀dá alààyè ní ayé.
I z każdą duszą żywiącą, która jest z wami: w ptastwie, w bydle, i w każdem zwierzęciu ziemi, które są z wami, ze wszystkich, co wyszły z korabia, aż do każdego zwierzęcia na ziemi.
11 Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín láéláé, Èmi kì yóò fi ìkún omi pa ayé run kúrò mọ láéláé, a kì yóò fi omi pa ayé run.”
I postanowię przymierze moje z wami; a nie będzie zatracone więcej wszelkie ciało wodami potopu; i nie będzie więcej potop na skażenie ziemi.
12 Ọlọ́run sì wí pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ń dá yìí láàrín èmi àti ẹ̀yin àti ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, májẹ̀mú àtìrandíran tó ń bọ̀:
Tedy rzekł Bóg: To jest znak przymierza, który Ja dawam między mną i między wami, i między każdą duszą żywiącą, która jest z wami, w rodzaje wieczne.
13 Mo ti fi òṣùmàrè sí àwọsánmọ̀, yóò sì jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín èmi àti ayé.
Łuk mój położyłem na obłoku, który będzie na znak przymierza między mną, i między ziemią.
14 Nígbàkígbà tí mo bá mú kí òjò ṣú, tí òṣùmàrè bá farahàn ní àwọsánmọ̀.
I stanie się, gdy wzbudzę ciemny obłok nad ziemią, a ukaże się łuk na obłoku:
15 Èmi yóò rántí májẹ̀mú mi, tí ó wà láàrín èmi àti ẹ̀yin àti gbogbo ẹ̀dá alààyè, kì yóò sì tún sí ìkún omi mọ́ láti pa gbogbo ẹ̀dá run.
Że wspomnę na przymierze moje, które jest między mną i między wami, i między każdą duszą żywiącą w każdem ciele; i nie będą więcej wody na potop, ku wytraceniu wszelkiego ciała.
16 Nígbàkígbà tí òṣùmàrè bá yọ ní àwọsánmọ̀, èmi yóò rí i, èmi yóò sì rántí májẹ̀mú ayérayé tí ń bẹ láàrín Ọlọ́run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń bẹ ní ayé.”
Będzie tedy łuk on na obłoku, i wejrzę nań, abym wspomniał na przymierze wieczne, między Bogiem i między wszelką duszą żywiącą w każdem ciele, które jest na ziemi.
17 Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ láàrín èmi àti gbogbo alààyè ní ayé.”
Zatem rzekł Bóg do Noego: Tenci jest znak przymierza, którem postanowił między mną, i między wszelkiem ciałem, które jest na ziemi.
18 Àwọn ọmọ Noa tí ó jáde nínú ọkọ̀ ni Ṣemu, Hamu àti Jafeti. (Hamu ni baba Kenaani.)
A byli synowie Noego, którzy wyszli z korabia, Sem, i Cham, i Jafet; a Cham jest ojcem Chanaan.
19 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Noa mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ni gbogbo ènìyàn ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ ayé.
Ci trzej synowie Noego, przez które się napełniła ludem wszystka ziemia.
20 Noa bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ àgbẹ̀, ó sì gbin ọgbà àjàrà.
Tedy Noe począł uprawiać ziemię, i nasadził winnicę.
21 Ó mu àmupara nínú ọtí wáìnì àjàrà rẹ̀, ó sì tú ara rẹ̀ sí ìhòhò, ó sì sùn nínú àgọ́ rẹ̀.
Potem pił wino; a upiwszy się, odkrył się w namiocie swoim.
22 Hamu tí í ṣe baba Kenaani sì rí baba rẹ̀ ní ìhòhò bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ méjèèjì ní ìta.
A ujrzawszy Cham, ojciec Chanaanów, nagość ojca swego, oznajmił to dwom braciom swoim na dworze.
23 Ṣùgbọ́n Ṣemu àti Jafeti mú aṣọ lé èjìká wọn, wọ́n sì fi ẹ̀yìn rìn, wọ́n sì bo ìhòhò baba wọn. Wọ́n kọjú sẹ́yìn kí wọn kí ó má ba à rí ìhòhò baba wọn.
Tedy wziąwszy Sem i Jafet szatę, a włożywszy ją oba na ramiona swe, szli wspak, i zakryli nagość ojca swego; a oblicza ich odwrócone były, że nagości ojca swego nie widzieli.
24 Nígbà tí Noa kúrò ní ojú ọtí, tí ó sì mọ ohun tí ọmọ rẹ̀ kékeré ṣe sí i.
A ocuciwszy się Noe z wina swego, gdy się dowiedział, co mu uczynił syn jego młodszy, rzekł:
25 Ó wí pé, “Ègún ni fún Kenaani. Ìránṣẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ni yóò máa ṣe fún àwọn arákùnrin rẹ̀.”
Przeklęty Chanaan, sługą sług braci swojej będzie.
26 Ó sì tún wí pé, “Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ṣemu Kenaani yóò máa ṣe ẹrú fún Ṣemu.
Rzekł też: Błogosławiony Pan Bóg Semów, a niech będzie Chanaan sługą ich.
27 Ọlọ́run yóò mú Jafeti gbilẹ̀, Jafeti yóò máa gbé ní àgọ́ Ṣemu Kenaani yóò sì jẹ́ ẹrú fún un.”
Niech rozszerzy Bóg Jafeta, i niech mieszka w namieciech Semowych a niech Chanaan sługą ich.
28 Noa wà láààyè fún irinwó ọdún dín àádọ́ta lẹ́yìn ìkún omi.
I żył Noe po potopie trzy sta lat, i pięćdziesiąt lat.
29 Àpapọ̀ ọjọ́ ayé Noa jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún dín làádọ́ta, ó sì kú.
I było wszystkich dni Noego, dziewięć set lat, i pięćdziesiąt lat, i umarł.

< Genesis 9 >