< Genesis 9 >

1 Ọlọ́run sì súre fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ wí pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì pọ̀ ní iye, kí ẹ sì kún ayé.
Azután megáldá Isten Noét és az ő fiait, és azt mondá nékik: Szaporodjatok és sokasodjatok, és töltsétek be a földet.
2 Ẹ̀rù yín yóò mú ojo wà lára gbogbo ẹranko àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀; àti gbogbo ẹja òkun; a fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
És féljen és rettegjen tőletek a földnek minden állatja az égnek minden madara: minden a mi nyüzsög a földön, és a tengernek minden hala kezetekbe adatott;
3 Gbogbo ohun tó wà láààyè tí ó sì ń rìn, ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín, bí mo ṣe fi ewéko fún un yín náà ni mo fi ohun gbogbo fún un yín.
Minden mozgó állat, a mely él legyen nektek eledelűl; a mint a zöld fűvet, nektek adtam mindazokat.
4 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
Csak a húst az őt elevenítő vérrel meg ne egyétek.
5 Nítòótọ́ ẹ̀jẹ̀ yín, àní ẹ̀mí yín, ni èmi yóò sì béèrè; lọ́wọ́ gbogbo ẹranko ni èmí yóò béèrè rẹ̀, àti lọ́wọ́ ènìyàn, lọ́wọ́ arákùnrin olúkúlùkù ènìyàn ni èmi yóò béèrè ẹ̀mí ènìyàn.
De a ti véreteket, a melyben van a ti éltetek, számon kérem; számon kérem minden állattól, azonképen az embertől, kinek-kinek atyjafiától számon kérem az ember életét.
6 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀, láti ọwọ́ ènìyàn ni a ó gbà ta ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀. Nítorí ní àwòrán Ọlọ́run ni Ọlọ́run dá ènìyàn.
A ki ember-vért ont, annak vére ember által ontassék ki; mert Isten a maga képére teremté az embert.
7 Ṣùgbọ́n ní tiyín, ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ máa gbá yìn lórí ilẹ̀, kí ẹ sì pọ̀ sí i lórí rẹ̀.”
Ti pedig szaporodjatok és sokasodjatok, nyüzsögjetek a földön és sokasodjatok azon.
8 Ọlọ́run sì wí fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé,
És szóla az Isten Noénak és vele az ő fiainak, mondván:
9 “Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín àti pẹ̀lú àwọn ìran yín tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
Én pedig ímé szövetséget szerzek ti veletek és a ti magvatokkal ti utánnatok.
10 Àti pẹ̀lú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, ìbá à ṣe ẹyẹ, ẹja, ẹran ọ̀sìn, ẹranko igbó, gbogbo ohun tí ó jáde kúrò nínú ọkọ̀ pẹ̀lú yín, àní gbogbo ẹ̀dá alààyè ní ayé.
És minden élő állattal, mely veletek van: madárral, barommal, minden mezei vaddal, mely veletek van; mindattól kezdve a mi a bárkából kijött, a földnek minden vadjáig.
11 Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín láéláé, Èmi kì yóò fi ìkún omi pa ayé run kúrò mọ láéláé, a kì yóò fi omi pa ayé run.”
Szövetséget kötök ti veletek, hogy soha ezután el nem vész özönvíz miatt minden test; és soha sem lesz többé özönvíz a földnek elvesztésére.
12 Ọlọ́run sì wí pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ń dá yìí láàrín èmi àti ẹ̀yin àti ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, májẹ̀mú àtìrandíran tó ń bọ̀:
És monda az Isten: Ez a jele a szövetségnek, melyet én örök időkre szerzek közöttem és ti köztetek, és minden élő állat között, mely ti veletek van:
13 Mo ti fi òṣùmàrè sí àwọsánmọ̀, yóò sì jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín èmi àti ayé.
Az én ívemet helyeztetem a felhőkbe, s ez lesz jele a szövetségnek közöttem és a föld között.
14 Nígbàkígbà tí mo bá mú kí òjò ṣú, tí òṣùmàrè bá farahàn ní àwọsánmọ̀.
És lészen, hogy mikor felhővel borítom be a földet, meglátszik az ív a felhőben.
15 Èmi yóò rántí májẹ̀mú mi, tí ó wà láàrín èmi àti ẹ̀yin àti gbogbo ẹ̀dá alààyè, kì yóò sì tún sí ìkún omi mọ́ láti pa gbogbo ẹ̀dá run.
És megemlékezem az én szövetségemről, mely van én közöttem és ti közöttetek, és minden testből való élő állat között; és nem lesz többé a víz özönné minden testnek elvesztésére.
16 Nígbàkígbà tí òṣùmàrè bá yọ ní àwọsánmọ̀, èmi yóò rí i, èmi yóò sì rántí májẹ̀mú ayérayé tí ń bẹ láàrín Ọlọ́run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń bẹ ní ayé.”
Azért legyen tehát az ív a felhőben, hogy lássam azt és megemlékezzem az örökkévaló szövetségről Isten között és minden testből való élő állat között, mely a földön van.
17 Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ láàrín èmi àti gbogbo alààyè ní ayé.”
És monda Isten Noénak: Ez ama szövetségnek jele, melyet szerzettem én közöttem és minden test között, mely a földön van.
18 Àwọn ọmọ Noa tí ó jáde nínú ọkọ̀ ni Ṣemu, Hamu àti Jafeti. (Hamu ni baba Kenaani.)
Valának pedig Noé fiai, kik a bárkából kijöttek vala: Sém és Khám és Jáfet. Khám pedig Kanaánnak atyja.
19 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Noa mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ni gbogbo ènìyàn ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ ayé.
Ezek hárman a Noé fiai s ezektől népesedék meg az egész föld.
20 Noa bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ àgbẹ̀, ó sì gbin ọgbà àjàrà.
Noé pedig földmívelő kezde lenni, és szőlőt ültete.
21 Ó mu àmupara nínú ọtí wáìnì àjàrà rẹ̀, ó sì tú ara rẹ̀ sí ìhòhò, ó sì sùn nínú àgọ́ rẹ̀.
És ivék a borból, s megrészegedék, és meztelenen vala sátra közepén.
22 Hamu tí í ṣe baba Kenaani sì rí baba rẹ̀ ní ìhòhò bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ méjèèjì ní ìta.
Khám pedig, Kanaánnak atyja, meglátá az ő atyjának mezítelenségét, és hírűl adá künnlevő két testvérének.
23 Ṣùgbọ́n Ṣemu àti Jafeti mú aṣọ lé èjìká wọn, wọ́n sì fi ẹ̀yìn rìn, wọ́n sì bo ìhòhò baba wọn. Wọ́n kọjú sẹ́yìn kí wọn kí ó má ba à rí ìhòhò baba wọn.
Akkor Sém és Jáfet ruhát ragadván, azt mindketten vállokra veték, és háttal menve takarák be atyjok mezítelenségét; s arczczal hátra meg sem láták atyjok mezítelenségét.
24 Nígbà tí Noa kúrò ní ojú ọtí, tí ó sì mọ ohun tí ọmọ rẹ̀ kékeré ṣe sí i.
Hogy felserkene Noé mámorából, és megtudá a mit vele az ő kisebbik fia cselekedett vala:
25 Ó wí pé, “Ègún ni fún Kenaani. Ìránṣẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ni yóò máa ṣe fún àwọn arákùnrin rẹ̀.”
Monda: Átkozott Kanaán! Szolgák szolgája legyen atyjafiai közt.
26 Ó sì tún wí pé, “Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ṣemu Kenaani yóò máa ṣe ẹrú fún Ṣemu.
Azután monda: Áldott az Úr, Sémnek Istene, néki légyen szolgája Kanaán!
27 Ọlọ́run yóò mú Jafeti gbilẹ̀, Jafeti yóò máa gbé ní àgọ́ Ṣemu Kenaani yóò sì jẹ́ ẹrú fún un.”
Terjeszsze ki Isten Jáfetet, lakozzék Sémnek sátraiban; légyen néki szolgája a Kanaán!
28 Noa wà láààyè fún irinwó ọdún dín àádọ́ta lẹ́yìn ìkún omi.
Éle pedig Noé az özönvíz után háromszáz ötven esztendeig.
29 Àpapọ̀ ọjọ́ ayé Noa jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún dín làádọ́ta, ó sì kú.
És vala Noé egész életének ideje kilenczszáz ötven esztendő; és meghala.

< Genesis 9 >