< Genesis 8 >

1 Ọlọ́run sì rántí Noa àti ohun alààyè gbogbo tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, bí àwọn ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn, ó sì mú kí afẹ́fẹ́ fẹ́ sórí ilẹ̀, omi náà sì fà.
No rĩrĩ, Ngai nĩaririkanire Nuhu o hamwe na nyamũ ciothe cia gĩthaka o na mahiũ marĩa mothe aarĩ namo thĩinĩ wa thabina, na agĩtũma rũhuho rũhurutane gũkũ thĩ, namo maaĩ makĩambĩrĩria kũhũa.
2 Gbogbo ìsun ibú àti fèrèsé ìṣàn ọ̀run tì, òjò pẹ̀lú sì dáwọ́ rírọ̀ dúró.
Nacio ithima cia kũrĩa kũriku na ihingo cia mũiyũro wa igũrũ ikĩhingwo, nayo mbura ĩgĩtiga kuura.
3 Omi sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gbẹ kúrò lórí ilẹ̀, lẹ́yìn àádọ́jọ ọjọ́, ó sì ti ń fà.
Namo maaĩ magĩthiĩ makĩhũũaga, magĩthiraga thĩ. Thuutha wa matukũ igana na mĩrongo ĩtano-rĩ, maaĩ magĩkorwo manyihanyiihĩte,
4 Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì ni ọkọ̀ náà gúnlẹ̀ sórí òkè Ararati.
naguo mũthenya wa ikũmi na mũgwanja wa mweri wa mũgwanja, thabina ĩkĩrũgama irĩma-inĩ cia Ararati.
5 Omi náà sì ń gbẹ si títí di oṣù kẹwàá. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, orí àwọn òkè sì farahàn.
Maaĩ macio magĩthiĩ na mbere na kũhũa o nginya mweri wa ikũmi, na mũthenya wa mbere wa mweri wa ikũmi-rĩ, tũcũmbĩrĩ twa irĩma tũkĩambĩrĩria kuoneka.
6 Lẹ́yìn ogójì ọjọ́, Noa sí fèrèsé tí ó ṣe sára ọkọ̀.
Na thuutha wa matukũ mĩrongo ĩna, Nuhu akĩhingũra ndirica ĩrĩa aakĩte thabina-inĩ,
7 Ó sì rán ẹyẹ ìwò kan jáde, tí ó ń fò káàkiri síwá àti sẹ́yìn títí omi fi gbẹ kúrò ní orí ilẹ̀.
na akĩrekereria ihuru na nja, narĩo rĩgĩtũũra rĩũmbũkaga kũndũ na kũndũ o nginya rĩrĩa maaĩ maahũire thĩ.
8 Ó sì rán àdàbà kan jáde láti wò ó bóyá omi ti gbẹ kúrò lórí ilẹ̀.
Ningĩ akĩrekereria ndutura ĩthiĩ ĩkarore kana maaĩ nĩmahũĩte gũkũ thĩ.
9 Ṣùgbọ́n àdàbà náà kò rí ìyàngbẹ ilẹ̀ bà lé nítorí omi kò tí ì tan lórí ilẹ̀, ó sì padà sọ́dọ̀ Noa. Noa na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú ẹyẹ náà wọlé sọ́dọ̀ ara rẹ̀ nínú ọkọ̀.
No ndutura ĩyo ndĩonire handũ ha kũũmba tondũ thĩ yothe yaiyũrĩtwo nĩ maaĩ; nĩ ũndũ ũcio ĩgĩcooka thabina-inĩ kũrĩ Nuhu. Nake agĩtambũrũkia guoko akĩmĩoya, akĩmĩtoonyia thabina thĩinĩ kũu we aarĩ.
10 Ó sì dúró fún ọjọ́ méje sí i; ó sì tún rán àdàbà náà jáde láti inú ọkọ̀.
Ningĩ agĩeterera matukũ mangĩ mũgwanja, na maathira akĩrekereria ndutura rĩngĩ yume nja ya thabina.
11 Nígbà tí àdàbà náà padà sọ́dọ̀ rẹ̀ ní àṣálẹ́, ó já ewé igi olifi tútù há ẹnu! Nígbà náà ni Noa mọ̀ pé omi ti ń gbẹ kúrò lórí ilẹ̀.
Rĩrĩa ndutura ĩyo yamũcookereire hwaĩ-inĩ-rĩ, yakuuĩte ithangũ rĩa mũtamaiyũ na mũkanye wayo, rĩatuĩtwo o hĩndĩ ĩyo! Nuhu agĩkĩmenya atĩ maaĩ nĩmahũĩte thĩ.
12 Noa tún mú sùúrù fún ọjọ́ méje, ó sì tún rán àdàbà náà jáde, ṣùgbọ́n àdàbà náà kò padà sọ́dọ̀ rẹ̀ mọ́.
Nuhu agĩeterera matukũ mangĩ mũgwanja, agĩcooka akĩrekereria ndutura ĩyo yume nja rĩngĩ, no hĩndĩ ĩno ndĩigana kũmũcookerera.
13 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ní ọdún kọ́kànlélẹ́gbẹ̀ta ni omi náà gbẹ kúrò lórí ilẹ̀; Noa sì ṣí ọkọ̀, ó sì ri pé ilẹ̀ ti gbẹ.
Na rĩrĩ, mũthenya wa mbere, mweri wa mbere wa mwaka ũrĩa Nuhu akinyirie mĩaka magana matandatũ na ũmwe-rĩ, mũthenya ũcio nĩguo maaĩ maahũire biũ gũkũ thĩ. Nake Nuhu akĩeheria kĩrĩa kĩagitĩte thabina, agĩkĩona atĩ thĩ nĩyaniarĩte.
14 Ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kejì, ilẹ̀ ti gbẹ pátápátá.
Gũgĩkinya mũthenya wa mĩrongo ĩĩrĩ na mũgwanja wa mweri wa keerĩ-rĩ, thĩ nĩyaniarĩte biũ.
15 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Noa pé.
Ningĩ Ngai akĩĩra Nuhu atĩrĩ,
16 “Jáde kúrò nínú ọkọ̀, ìwọ àti aya rẹ, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ àti àwọn aya wọn.
“Uma thabina, wee na mũtumia waku, na ariũ aku na atumia ao.
17 Kó gbogbo àwọn ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú rẹ jáde: àwọn ẹyẹ, ẹranko àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀, kí wọn lè bí sí i, kí wọn sì pọ̀ sí i, kí wọn sì máa gbá yìn lórí ilẹ̀.”
Hingũrĩra mĩthemba yothe ya ciũmbe iria irĩ muoyo icio ũrĩ nacio: irĩ nyoni, na nyamũ, na ciũmbe iria ithiiagĩra thĩ, nĩgeetha ciongerereke thĩ, na iciarane cingĩhe gũkũ thĩ.”
18 Noa, àwọn ọmọ rẹ̀, aya rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì jáde.
Nĩ ũndũ ũcio Nuhu akiuma thabina hamwe na ariũ ake, na mũtumia wake, na atumia a ariũ ake.
19 Gbogbo àwọn ẹranko àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀ àti gbogbo ẹyẹ pátápátá ni ó jáde kúrò nínú ọkọ̀, ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ní irú tiwọn.
Nyamũ ciothe na ciũmbe ciothe iria ithiiagĩra thĩ, na nyoni ciothe, na kĩndũ o gĩothe gĩthiiagĩra gũkũ thĩ, ciothe cikiuma thabina, mũthemba o mũthemba.
20 Noa sì mọ pẹpẹ fún Olúwa, ó sì mú lára àwọn ẹran tí ó mọ́ àti ẹyẹ tí ó mọ́, ó sì fi rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
Nake Nuhu agĩakĩra Jehova kĩgongona, na akĩoya nyamũ imwe cia iria ciothe itarĩ thaahu, na nyoni iria itarĩ thaahu, akĩrutĩra Ngai igongona rĩa njino ho.
21 Olúwa sì gbọ́ òórùn dídùn; ó sì wí ní ọkàn rẹ̀ pé, “Èmi kì yóò tún fi ilẹ̀ ré nítorí ènìyàn mọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo èrò inú rẹ̀ jẹ́ ibi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá, èmi kì yóò pa gbogbo ohun alààyè run mọ́ láé, bí mo ti ṣe.
Nake Jehova agĩkenio nĩ mũtararĩko ũcio, akiuga atĩrĩ na ngoro yake: “Ndirĩ hĩndĩ ngaacooka kũruma thĩ rĩngĩ nĩ ũndũ wa mũndũ, o na gũtuĩka merirĩria ma ngoro yake nĩ mooru kuuma ũnini-inĩ wake. Na ndirĩ hĩndĩ ngaacooka kũniina ciũmbe ciothe iria irĩ muoyo ta ũguo njĩkĩte.
22 “Níwọ́n ìgbà tí ayé bá sì wà, ìgbà ọ̀gbìn àti ìgbà ìkórè ìgbà òtútù àti ìgbà ooru, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òjò, ìgbà ọ̀sán àti ìgbà òru, yóò wà títí láé.”
“Mahinda mothe marĩa thĩ ĩgũtũũra-rĩ, kũrĩkoragwo na hĩndĩ ya kũhaanda na ya magetha, na hĩndĩ ya heho na ya ũrugarĩ, na hĩndĩ ya themithũ na ya gathano, na mũthenya na ũtukũ.”

< Genesis 8 >

A Dove is Sent Forth from the Ark
A Dove is Sent Forth from the Ark