< Genesis 7 >

1 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Noa pé, “Wọ inú ọkọ̀ lọ ìwọ àti gbogbo ìdílé rẹ, nítorí ìwọ nìkan ni mo rí bí olódodo nínú ìran yìí.
Yahvé dijo a Noé: “Sube con toda tu familia a la nave, porque he visto tu justicia ante mí en esta generación.
2 Mú méje méje nínú àwọn ẹran tí ó mọ́, akọ àti abo, mú méjì méjì takọ tabo nínú àwọn ẹran aláìmọ́.
Llevarás contigo siete parejas de cada animal limpio, el macho y su hembra. De los animales que no están limpios, toma dos, el macho y su hembra.
3 Sì mú méje méje pẹ̀lú nínú onírúurú ẹyẹ, takọ tabo ni kí o mú wọn, wọlé sínú ọkọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí á ba à lè pa wọ́n mọ́ láààyè ní gbogbo ayé.
También de las aves del cielo, siete y siete, macho y hembra, para mantener viva la semilla en la superficie de toda la tierra.
4 Nítorí ní ọjọ́ méje sí ìhín, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi yóò sì pa gbogbo ohun alààyè tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀.”
En siete días haré llover sobre la tierra durante cuarenta días y cuarenta noches. Destruiré todo ser viviente que he hecho de la superficie de la tierra”.
5 Noa sì ṣe ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ fún un.
Noé hizo todo lo que Yahvé le ordenó.
6 Noa jẹ́ ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún nígbà tí ìkún omi dé sórí ilẹ̀.
Noé tenía seiscientos años cuando el diluvio de aguas llegó a la tierra.
7 Noa àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì wọ inú ọkọ láti sá àsálà fún ìkún omi.
Noé subió a la nave con sus hijos, su mujer y las mujeres de sus hijos, a causa de las aguas del diluvio.
8 Méjì méjì ni àwọn ẹran tí ó mọ́ àti aláìmọ́, ti ẹyẹ àti ti gbogbo àwọn ẹ̀dá afàyàfà,
Los animales limpios, los inmundos, las aves y todo lo que se arrastra por el suelo
9 akọ àti abo ni wọ́n wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa.
entraron por parejas con Noé en la nave, machos y hembras, como Dios le había ordenado a Noé.
10 Lẹ́yìn ọjọ́ keje, ìkún omi sì dé sí ayé.
Después de los siete días, las aguas de la inundación llegaron a la tierra.
11 Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì, tí Noa pé ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún, ni gbogbo ìsun ibú ya, fèrèsé ìṣàn omi ọ̀run sì ṣí sílẹ̀.
En el año seiscientos de la vida de Noé, en el segundo mes, a los diecisiete días del mes, ese día estallaron todas las fuentes del gran abismo y se abrieron las ventanas del cielo.
12 Òjò àrọ̀ìrọ̀dá sì rọ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.
Llovió sobre la tierra durante cuarenta días y cuarenta noches.
13 Ní ọjọ́ tí ìkún omi yóò bẹ̀rẹ̀ gan an ni Noa àti Ṣemu, Hamu àti Jafeti pẹ̀lú aya Noa àti aya àwọn ọmọ rẹ̀ wọ inú ọkọ̀.
En el mismo día Noé, y Sem, Cam y Jafet — los hijos de Noé — y la esposa de Noé y las tres esposas de sus hijos con ellos, entraron en la nave —
14 Wọ́n mú ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn ní onírúurú wọn, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ẹyẹ àti àwọn ohun abìyẹ́ ni onírúurú wọn.
ellos, y todo animal según su especie, todo el ganado según su especie, todo reptil que se arrastra sobre la tierra según su especie, y toda ave según su especie, toda ave de toda clase.
15 Méjì méjì ni gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè nínú wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀.
Las parejas de toda carne con aliento de vida entraron en la nave hacia Noé.
16 Gbogbo wọ́n wọlé ní takọ tabo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa, Olúwa sì tì wọn mọ́ inú ọkọ̀.
Los que entraron, entraron macho y hembra de toda carne, como Dios le ordenó; entonces Yahvé lo encerró.
17 Òjò náà sì rọ̀ ní àrọ̀ìrọ̀dá fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ọkọ̀ náà sì ń léfòó lórí omi, kúrò lórí ilẹ̀ bí omi náà ti ń pọ̀ sí i.
El diluvio duró cuarenta días sobre la tierra. Las aguas aumentaron, y levantaron la nave, y ésta se elevó sobre la tierra.
18 Bí omi náà ti ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ni ọkọ̀ náà sì ń léfòó lójú omi.
Las aguas crecieron y aumentaron mucho sobre la tierra, y el barco flotaba sobre la superficie de las aguas.
19 Omi náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó bo gbogbo àwọn òkè gíga tí ó wà lábẹ́ ọ̀run.
Las aguas se elevaron mucho sobre la tierra. Todos los montes altos que había bajo todo el cielo quedaron cubiertos.
20 Omi náà kún bo àwọn òkè, bí ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
Las aguas subieron quince codos más, y las montañas quedaron cubiertas.
21 Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ parun: ẹyẹ, ohun ọ̀sìn, ẹranko igbó, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ènìyàn.
Murió toda la carne que se movía sobre la tierra, incluyendo las aves, el ganado, los animales, todo lo que se arrastra sobre la tierra y todo hombre.
22 Gbogbo ohun tí ó wà lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ tó ní èémí ìyè ní ihò imú wọn ni ó kú.
Murió todo lo que estaba en la tierra firme, en cuyas narices había aliento de espíritu de vida.
23 Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ni a parẹ́: ènìyàn àti ẹranko, àwọn ohun tí ń rìn nílẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run pátápátá ló ṣègbé. Noa àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ni ó ṣẹ́kù.
Fue destruido todo ser viviente que estaba sobre la superficie de la tierra, incluidos el hombre, el ganado, los reptiles y las aves del cielo. Fueron destruidos de la tierra. Sólo quedó Noé y los que estaban con él en la nave.
24 Omi náà sì bo ilẹ̀ fún àádọ́jọ ọjọ́.
Las aguas inundaron la tierra durante ciento cincuenta días.

< Genesis 7 >

The Great Flood
The Great Flood