< Genesis 7 >

1 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Noa pé, “Wọ inú ọkọ̀ lọ ìwọ àti gbogbo ìdílé rẹ, nítorí ìwọ nìkan ni mo rí bí olódodo nínú ìran yìí.
Potem PAN powiedział do Noego: Wejdź ty wraz z całym twoim domem do arki, gdyż widziałem cię, że jesteś sprawiedliwy przede mną w tym pokoleniu.
2 Mú méje méje nínú àwọn ẹran tí ó mọ́, akọ àti abo, mú méjì méjì takọ tabo nínú àwọn ẹran aláìmọ́.
Z każdego zwierzęcia czystego weź sobie po siedem par, samca i samicę jego; ale ze zwierząt nieczystych – po [jednej] parze, samca i samicę jego.
3 Sì mú méje méje pẹ̀lú nínú onírúurú ẹyẹ, takọ tabo ni kí o mú wọn, wọlé sínú ọkọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí á ba à lè pa wọ́n mọ́ láààyè ní gbogbo ayé.
Także z ptactwa niebieskiego po siedem par, samca i samicę, aby zachować przy życiu ich potomstwo na całej powierzchni ziemi.
4 Nítorí ní ọjọ́ méje sí ìhín, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi yóò sì pa gbogbo ohun alààyè tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀.”
Pozostaje bowiem jeszcze siedem dni, a [potem] spuszczę deszcz na ziemię, na czterdzieści dni i czterdzieści nocy, i zgładzę z powierzchni ziemi wszelkie stworzenie, które uczyniłem.
5 Noa sì ṣe ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ fún un.
Noe uczynił więc wszystko, co mu PAN rozkazał.
6 Noa jẹ́ ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún nígbà tí ìkún omi dé sórí ilẹ̀.
Noe miał sześćset lat, gdy przyszedł potop wód na ziemię.
7 Noa àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì wọ inú ọkọ láti sá àsálà fún ìkún omi.
I wszedł Noe, a z nim jego synowie, jego żona i żony jego synów do arki ze względu na wody potopu.
8 Méjì méjì ni àwọn ẹran tí ó mọ́ àti aláìmọ́, ti ẹyẹ àti ti gbogbo àwọn ẹ̀dá afàyàfà,
Ze zwierząt czystych i nieczystych i z ptactwa, i ze wszystkiego, co pełza po ziemi;
9 akọ àti abo ni wọ́n wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa.
Po parze weszło do Noego do arki, samiec i samica, jak Bóg rozkazał Noemu.
10 Lẹ́yìn ọjọ́ keje, ìkún omi sì dé sí ayé.
A po siedmiu dniach wody potopu spadły na ziemię.
11 Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì, tí Noa pé ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún, ni gbogbo ìsun ibú ya, fèrèsé ìṣàn omi ọ̀run sì ṣí sílẹ̀.
W sześćsetnym roku życia Noego, w drugim miesiącu, siedemnastego dnia [tego] miesiąca, w tym właśnie dniu, przerwały się wszystkie źródła wielkiej głębi i otworzyły się okna nieba.
12 Òjò àrọ̀ìrọ̀dá sì rọ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.
I deszcz padał na ziemię czterdzieści dni i czterdzieści nocy.
13 Ní ọjọ́ tí ìkún omi yóò bẹ̀rẹ̀ gan an ni Noa àti Ṣemu, Hamu àti Jafeti pẹ̀lú aya Noa àti aya àwọn ọmọ rẹ̀ wọ inú ọkọ̀.
W tym właśnie dniu weszli do arki Noe oraz jego synowie – Sem, Cham i Jafet, a z nimi żona Noego i trzy żony jego synów.
14 Wọ́n mú ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn ní onírúurú wọn, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ẹyẹ àti àwọn ohun abìyẹ́ ni onírúurú wọn.
Oni i wszelkie zwierzęta według swego rodzaju, wszelkie bydło według swego rodzaju, wszelkie zwierzęta pełzające, które pełzają po ziemi według swego rodzaju, wszelkie ptaki według swego rodzaju [i] wszelkie stworzenia skrzydlate.
15 Méjì méjì ni gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè nínú wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀.
I tak weszły do Noego do arki, po parze z każdego ciała, w którym [było] tchnienie życia.
16 Gbogbo wọ́n wọlé ní takọ tabo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa, Olúwa sì tì wọn mọ́ inú ọkọ̀.
A te, które weszły, samiec i samica z każdego ciała weszły, jak mu Bóg rozkazał. I zamknął PAN za nim [drzwi].
17 Òjò náà sì rọ̀ ní àrọ̀ìrọ̀dá fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ọkọ̀ náà sì ń léfòó lórí omi, kúrò lórí ilẹ̀ bí omi náà ti ń pọ̀ sí i.
A potop trwał na ziemi czterdzieści dni i wody wezbrały, i podniosły arkę, i unosiła się nad ziemią.
18 Bí omi náà ti ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ni ọkọ̀ náà sì ń léfòó lójú omi.
Wody wzmogły się i wezbrały bardzo nad ziemią, i pływała arka po wodach.
19 Omi náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó bo gbogbo àwọn òkè gíga tí ó wà lábẹ́ ọ̀run.
I wody bardzo się wzmogły nad ziemią, i zakryły wszystkie wysokie góry, które [były] pod całym niebem.
20 Omi náà kún bo àwọn òkè, bí ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
Wody wezbrały na piętnaście łokci wzwyż i góry zostały zakryte.
21 Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ parun: ẹyẹ, ohun ọ̀sìn, ẹranko igbó, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ènìyàn.
Zginęło więc wszelkie ciało poruszające się na ziemi: ptactwo, bydło, zwierzęta i wszelkie zwierzęta pełzające, które pełzają po ziemi, i wszyscy ludzie.
22 Gbogbo ohun tí ó wà lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ tó ní èémí ìyè ní ihò imú wọn ni ó kú.
Wszystko, co [miało] w nozdrzach tchnienie życia, wszystko, co żyło na suchym lądzie, zginęło.
23 Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ni a parẹ́: ènìyàn àti ẹranko, àwọn ohun tí ń rìn nílẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run pátápátá ló ṣègbé. Noa àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ni ó ṣẹ́kù.
Tak zostało zgładzone wszelkie stworzenie, które [było] na powierzchni ziemi, od człowieka aż do bydła, zwierząt pełzających i ptactwa niebieskiego. Wszystko to zostało zgładzone z ziemi. Pozostał tylko Noe i ci, którzy z nim byli w arce.
24 Omi náà sì bo ilẹ̀ fún àádọ́jọ ọjọ́.
A wody wezbrały nad ziemią sto pięćdziesiąt dni.

< Genesis 7 >

The Great Flood
The Great Flood