< Genesis 7 >

1 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Noa pé, “Wọ inú ọkọ̀ lọ ìwọ àti gbogbo ìdílé rẹ, nítorí ìwọ nìkan ni mo rí bí olódodo nínú ìran yìí.
Potom řekl Hospodin k Noé: Vejdiž ty i všecka čeled tvá do korábu; nebo jsem tě viděl spravedlivého před sebou v národu tomto.
2 Mú méje méje nínú àwọn ẹran tí ó mọ́, akọ àti abo, mú méjì méjì takọ tabo nínú àwọn ẹran aláìmọ́.
Ze všech hovad čistých vezmeš sobě sedmero a sedmero, samce a samici jeho, ale z hovad nečistých dvé a dvé, samce a samici jeho.
3 Sì mú méje méje pẹ̀lú nínú onírúurú ẹyẹ, takọ tabo ni kí o mú wọn, wọlé sínú ọkọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí á ba à lè pa wọ́n mọ́ láààyè ní gbogbo ayé.
Z ptactva také nebeského sedmero a sedmero, samce a samici, aby živé zachováno bylo símě na vší zemi.
4 Nítorí ní ọjọ́ méje sí ìhín, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi yóò sì pa gbogbo ohun alààyè tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀.”
Nebo po dnech ještě sedmi já dštíti budu na zemi za čtyřidceti dnů a čtyřidceti nocí; a vyhladím se svrchku země všelikou podstatu, kterouž jsem učinil.
5 Noa sì ṣe ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ fún un.
Tedy učinil Noé všecko tak, jakž mu přikázal Hospodin.
6 Noa jẹ́ ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún nígbà tí ìkún omi dé sórí ilẹ̀.
(Byl pak Noé v šesti stech letech, když ta potopa přišla na zemi.)
7 Noa àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì wọ inú ọkọ láti sá àsálà fún ìkún omi.
A protož přišel Noé a synové jeho, i žena jeho, i ženy synů jeho s ním k korábu, pro vody potopy.
8 Méjì méjì ni àwọn ẹran tí ó mọ́ àti aláìmọ́, ti ẹyẹ àti ti gbogbo àwọn ẹ̀dá afàyàfà,
Z hovad také čistých i z hovad nečistých, i z ptactva a ze všeho, což se hýbe na zemi,
9 akọ àti abo ni wọ́n wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa.
Po dvém vešli k Noé do korábu, samec a samice, tak jakž byl rozkázal Bůh Noé.
10 Lẹ́yìn ọjọ́ keje, ìkún omi sì dé sí ayé.
Stalo se pak po sedmi dnech, že vody potopy přišly na zemi.
11 Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì, tí Noa pé ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún, ni gbogbo ìsun ibú ya, fèrèsé ìṣàn omi ọ̀run sì ṣí sílẹ̀.
Léta šestistého věku Noé, druhého měsíce, sedmnáctého dne téhož měsíce, v ten den protrženy jsou všecky studnice propasti veliké, a průduchové nebeští otevříni jsou.
12 Òjò àrọ̀ìrọ̀dá sì rọ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.
I byl příval na zemi čtyřidceti dní a čtyřidceti nocí.
13 Ní ọjọ́ tí ìkún omi yóò bẹ̀rẹ̀ gan an ni Noa àti Ṣemu, Hamu àti Jafeti pẹ̀lú aya Noa àti aya àwọn ọmọ rẹ̀ wọ inú ọkọ̀.
Toho dne všel Noé, Sem a Cham i Jáfet, synové Noé, žena Noé, a tři ženy synů jeho s ním do korábu.
14 Wọ́n mú ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn ní onírúurú wọn, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ẹyẹ àti àwọn ohun abìyẹ́ ni onírúurú wọn.
Oni i všeliký živočich podlé pokolení svého, i všeliké hovado podlé pokolení svého, a všeliký zeměplaz, kterýž se hýbe na zemi, podlé pokolení svého, i všeliké ptactvo vedlé pokolení svého, všelijací ptáci, všecko, což křídla má,
15 Méjì méjì ni gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè nínú wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀.
Vešli k Noé do korábu, po dvém ze všelikého těla, v němž byl duch života.
16 Gbogbo wọ́n wọlé ní takọ tabo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa, Olúwa sì tì wọn mọ́ inú ọkọ̀.
A což jich vešlo, samec a samice ze všelikého těla vešli, tak jakž byl přikázal jemu Bůh, a zavřel Hospodin po něm.
17 Òjò náà sì rọ̀ ní àrọ̀ìrọ̀dá fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ọkọ̀ náà sì ń léfòó lórí omi, kúrò lórí ilẹ̀ bí omi náà ti ń pọ̀ sí i.
A když byla potopa za čtyřidceti dnů na zemi, tedy rozmnoženy jsou vody, až i vyzdvihly koráb, a vznesly jej od země.
18 Bí omi náà ti ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ni ọkọ̀ náà sì ń léfòó lójú omi.
Nebo zmohly se vody a rozmnoženy jsou velmi nad zemí, i zplýval koráb na vodách.
19 Omi náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó bo gbogbo àwọn òkè gíga tí ó wà lábẹ́ ọ̀run.
A tak náramně rozmohly se vody nad zemí, že přikryty jsou všecky hory nejvyšší, kteréž byly pode vším nebem.
20 Omi náà kún bo àwọn òkè, bí ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
Patnácte loktů zvýší rozmohly se vody, když přikryty jsou hory.
21 Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ parun: ẹyẹ, ohun ọ̀sìn, ẹranko igbó, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ènìyàn.
I umřelo všeliké tělo, kteréž se hýbe na zemi, tak z ptactva, jako z hovad a živočichů, i všelikého hmyzu, kterýž se plazí po zemi, i každého člověka.
22 Gbogbo ohun tí ó wà lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ tó ní èémí ìyè ní ihò imú wọn ni ó kú.
Všecko, což mělo dýchání ducha života v chřípích svých, ze všeho, což bylo na suše, pomřelo.
23 Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ni a parẹ́: ènìyàn àti ẹranko, àwọn ohun tí ń rìn nílẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run pátápátá ló ṣègbé. Noa àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ni ó ṣẹ́kù.
A tak vyhladil Bůh všelikou podstatu, kteráž byla na tváři země, od člověka až do hovada, až do zeměplazu, a až do ptactva nebeského, vyhlazeno jest, pravím, z země; a zůstal toliko Noé, a kteříž s ním byli v korábu.
24 Omi náà sì bo ilẹ̀ fún àádọ́jọ ọjọ́.
I trvaly vody nad zemí za sto a padesáte dnů.

< Genesis 7 >

The Great Flood
The Great Flood