< Genesis 6 >

1 Nígbà tí ènìyàn bẹ̀rẹ̀ sí ní pọ̀ si ní orí ilẹ̀, wọ́n sí bí àwọn ọmọbìnrin.
Stalo se pak, když se počali množiti lidé na zemi, a dcery se jim zrodily,
2 Àwọn ọmọ Ọlọ́run rí i wí pé àwọn ọmọbìnrin ènìyàn lẹ́wà, wọ́n sì fẹ́ èyíkéyìí tí ó wù wọ́n ṣe aya.
Že vidouce synové Boží dcery lidské, any krásné jsou, brali sobě ženy ze všech, kteréž oblibovali.
3 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èémí ìyè tí mo mí sínú ènìyàn kò ní máa gbé inú ènìyàn títí láé, nítorí ẹran-ara sá à ni òun, ọgọ́fà ọdún ni ọjọ́ rẹ̀ yóò jẹ́.”
Pročež řekl Hospodin: Nebude se nesnaditi duch můj s člověkem na věky, proto že také tělo jest, a bude dnů jeho sto a dvadceti let.
4 Àwọn òmíràn wà láyé ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti lẹ́yìn ìgbà náà; nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run lọ bá àwọn ọmọbìnrin ènìyàn lòpọ̀ tí wọ́n sì bímọ fún wọn. Àwọn náà ni ó di akọni àti olókìkí ìgbà náà.
Obrové pak byli na zemi v těch dnech; ano i potom, když vcházeli synové Boží k dcerám lidským, ony rodily jim. To jsou ti mocní, kteříž zdávna byli, muži na slovo vzatí.
5 Olúwa sì rí bí ìwà búburú ènìyàn ti ń gbilẹ̀ si, àti pé gbogbo èrò inú rẹ̀ kìkì ibi ni, ní ìgbà gbogbo.
Ale když viděl Hospodin, an se rozmnožuje zlost lidská na zemi, a že by všeliké myšlení srdce jejich nebylo než zlé po všecken čas,
6 Inú Olúwa sì bàjẹ́ gidigidi nítorí pé ó dá ènìyàn sí ayé, ọkàn rẹ̀ sì gbọgbẹ́.
Litoval Hospodin, že učinil člověka na zemi, a bolest měl v srdci svém.
7 Nítorí náà, Olúwa wí pé, “Èmi yóò pa ènìyàn tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀, ènìyàn àti ẹranko, àti ohun tí ń rákò, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, nítorí inú mi bàjẹ́ pé mo ti dá wọn.”
Tedy řekl Hospodin: Vyhladím z země člověka, kteréhož jsem stvořil, od člověka až do hovada, až do zeměplazu, až i do ptactva nebeského; nebo líto mi, že jsem je učinil.
8 Ṣùgbọ́n, Noa rí ojúrere Olúwa.
Ale Noé našel milost před Hospodinem.
9 Wọ̀nyí ni ìtàn Noa. Noa nìkan ni ó jẹ́ olóòótọ́ ènìyàn àti ẹni tí ó pé ní ìgbà ayé rẹ̀, ó sì fi òtítọ́ bá Ọlọ́run rìn.
Tito jsou příběhové Noé: Noé muž spravedlivý, dokonalý byl za svého věku, s Bohem ustavičně chodil Noé.
10 Noa sì bí ọmọkùnrin mẹ́ta, Ṣemu, Hamu àti Jafeti.
(Zplodil pak Noé tři syny: Sema, Chama a Jáfeta.)
11 Ayé sì kún fún ìbàjẹ́ gidigidi ní ojú Ọlọ́run, ó sì kún fún ìwà ipá pẹ̀lú.
Ale země byla porušena před Bohem, a naplněna byla země nepravostí.
12 Ọlọ́run sì rí bí ayé ti bàjẹ́ tó, nítorí àwọn ènìyàn inú ayé ti bá ara wọn jẹ́ ní gbogbo ọ̀nà wọn.
Viděl tedy Bůh zemi, a aj, porušena byla, nebo bylo porušilo všeliké tělo cestu svou na zemi.
13 Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èmi yóò pa gbogbo ènìyàn run, nítorí ilẹ̀ ayé kún fún ìwà ipá nípasẹ̀ wọn. Èmi yóò pa wọ́n run àti ayé pẹ̀lú.
Protož řekl Bůh k Noé: Konec všelikého těla přichází přede mne, nebo naplněna jest země nepravostí od nich; z té příčiny, hle, již zkazím je s zemí.
14 Nítorí náà fi igi ọ̀mọ̀ kan ọkọ̀, kí o sì yọ yàrá sí inú rẹ̀, kí o sì fi ọ̀dà ilẹ̀ rẹ́ ẹ tinú-tẹ̀yìn.
Učiň sobě koráb z dříví gofer; příhrady zděláš v tom korábu, a oklejuješ jej vnitř i zevnitř klím.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe kan ọkọ̀ náà: Gígùn rẹ̀ ní òró yóò jẹ́ ọ̀ọ́dúnrún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ yóò jẹ́ àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́, nígbà tí gíga rẹ̀ yóò jẹ́ ọgbọ̀n ìgbọ̀nwọ́.
A na tento způsob uděláš jej: Tří set loktů bude dlouhost toho korábu, padesáti loktů širokost jeho a třidceti loktů vysokost jeho.
16 Ṣe òrùlé sí orí ọkọ̀ náà ní ìgbọ̀nwọ́ kan, sì ṣe ọkọ̀ náà ní alájà mẹ́ta, ipá kan ní ìsàlẹ̀, ọ̀kan ní àárín àti ọ̀kan tí ó kù ní òkè, ẹ̀gbẹ́ ni kí ó ṣe ẹnu-ọ̀nà ọkọ̀ náà sí.
Okno uděláš v korábu, a svrchkem na loket vysokým zavřeš jej; dvéře také korábu v boku jeho postavíš, a pokoje spodní, druhé i třetí zděláš v něm.
17 Èmi yóò mú ìkún omi wá sí ayé láti pa gbogbo ohun ẹlẹ́mìí run lábẹ́ ọ̀run. Gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè ní inú. Gbogbo ohun tí ó wà nínú ayé yóò parun.
Já pak, aj, já uvedu potopu vod na zemi, aby zkaženo bylo všeliké tělo, v němž jest duch života pod nebem. Cožkoli bude na zemi, umře.
18 Ṣùgbọ́n èmi ó dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì wọ ọkọ̀, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú aya rẹ.
S tebou však učiním smlouvu svou; a vejdeš do korábu, ty i synové tvoji, žena tvá i ženy synů tvých s tebou.
19 Ìwọ yóò mú gbogbo ohun alààyè takọ tabo wá sí inú ọkọ̀, kí wọn le wà láààyè pẹ̀lú rẹ.
A ze všech živočichů všelikého těla, po dvém z každého uvedeš do korábu, abys je živé zachoval s sebou; samec a samice budou.
20 Mú onírúurú àwọn ẹyẹ, ẹranko àti àwọn ohun tí ń rákò ní méjì méjì, kí a bá lè pa wọ́n mọ́ láààyè.
Z ptactva podlé pokolení jeho, a z hovad podlé pokolení jejich, ze všelikého také zeměplazu podlé pokolení jeho, po dvém z každého vejdou k tobě, aby živi zůstali.
21 Mú onírúurú oúnjẹ wá sínú ọkọ̀, kí o pa wọ́n mọ́ fún jíjẹ gbogbo ẹ̀yin tí ẹ wà nínú ọkọ̀ àti ènìyàn àti ẹranko.”
Ty pak nabeř s sebou všeliké potravy, kteráž se jísti může, a shromažď sobě, aby byla tobě i jim ku pokrmu.
22 Noa sì ṣe ohun gbogbo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.
I učinil Noé podlé všeho, jakž mu rozkázal Bůh, tak učinil.

< Genesis 6 >

The World is Destroyed by Water
The World is Destroyed by Water