< Genesis 50 >

1 Josẹfu sì ṣubú lé baba rẹ̀, ó sọkún, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu.
Иосиф с-а арункат пе фаца татэлуй сэу, л-а плынс ши л-а сэрутат.
2 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún àwọn oníṣègùn tí ó wà ní ìkáwọ́ rẹ̀ pé kí wọn kí ó ṣe òkú Israẹli baba rẹ̀ lọ́jọ̀, àwọn oníṣègùn náà sì ṣe bẹ́ẹ̀.
А порунчит докторилор каре ерау ын служба луй сэ ымбэлсэмезе пе татэл сэу, ши докторий ау ымбэлсэмат пе Исраел.
3 Fún ogójì ọjọ́ ni wọ́n fi ṣe èyí, nítorí èyí ni àsìkò tí a máa ń fi ṣe ẹ̀ǹbáàmù òkú. Àwọn ará Ejibiti sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀ fún àádọ́rin ọjọ́.
Патрузечь де зиле ау трекут астфел ши ау фост ынтребуинцате ку ымбэлсэмаря луй. Ши еӂиптений л-ау плынс шаптезечь де зиле.
4 Nígbà tí ọjọ́ ìṣọ̀fọ̀ náà kọjá. Josẹfu wí fún àwọn ará ilé Farao pé, “Bí mo bá bá ojúrere yín pàdé, ẹ bá mi sọ fún Farao.
Дупэ че ау трекут зилеле де жале, Иосиф а ворбит оаменилор дин каса луй Фараон ши ле-а зис: „Дакэ ам кэпэтат тречере ынаинтя воастрэ, спунець, вэ рог, луй Фараон че вэ спун еу.
5 ‘Baba mi mú mi búra ó sì wí fún mi pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú: sinmi sínú ibojì tí mo gbẹ́ fún ara mi ní ilẹ̀ Kenaani.” Nísinsin yìí, jẹ́ kí n lọ kí n sì sìnkú baba mi, lẹ́yìn náà èmi yóò padà wa.’”
‘Татэл меу м-а пус сэ жур, зикынд: «Ятэ, ын курынд еу ам сэ мор! Сэ мэ ынгропь ын мормынтул пе каре ми л-ам сэпат ын цара Канаан.» Аш вря дар сэ мэ суй аколо, ка сэ ынгроп пе татэл меу, ши дупэ ачея мэ вой ынтоарче.’”
6 Farao wí pé, “Gòkè lọ, kí o sì sin baba rẹ, bí ó tí mú ọ búra.”
Фараон а рэспунс: „Суе-те ши ынгроапэ пе татэл тэу, дупэ журэмынтул пе каре те-а пус сэ-л фачь.”
7 Báyìí ni Josẹfu gòkè lọ láti sìnkú baba rẹ̀. Gbogbo àwọn ìjòyè Farao ni ó sìn ín lọ—àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀, àti gbogbo àwọn àgbàgbà ilẹ̀ Ejibiti.
Иосиф с-а суит ка сэ ынгроапе пе татэл сэу. Ымпреунэ ку ел с-ау суит тоць служиторий луй Фараон, бэтрыний касей луй, тоць бэтрыний цэрий Еӂиптулуй,
8 Yàtọ̀ fún gbogbo àwọn ará ilé Josẹfu àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn tí ó jẹ́ ilé baba rẹ̀, àwọn ọmọ wọn nìkan àti agbo ẹran pẹ̀lú agbo màlúù ni ó sẹ́ kù ní Goṣeni.
тоатэ каса луй Иосиф, фраций сэй ши каса татэлуй сэу; н-ау лэсат ын цинутул Госен декыт прунчий, оиле ши боий.
9 Kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin pẹ̀lú gòkè lọ. Àìmoye ènìyàn ni ó lọ.
Ымпреунэ ку Иосиф май ерау каре ши кэлэрець, аша кэ алаюл ера фоарте маре.
10 Nígbà tí wọ́n dé ilẹ̀ ìpakà Atadi, ní ẹ̀bá Jordani, wọn pohùnréré ẹkún, níbẹ̀ ni Josẹfu sì tún dúró ṣọ̀fọ̀ baba rẹ̀ fún ọjọ́ méje.
Кынд ау ажунс ла ария луй Атад, каре есте динколо де Йордан, ау фэкут плынӂере маре ши жалникэ, ши Иосиф а цинут ын чинстя татэлуй сэу ун бочет де шапте зиле.
11 Nígbà tí àwọn ará Kenaani tí ń gbé níbẹ̀ rí i bí wọ́n ti ń ṣọ̀fọ̀ náà ni ilẹ̀ ìpakà Atadi, wọ́n wí pé, “Ọ̀fọ̀ ńlá ni àwọn ará Ejibiti ń ṣe yìí.” Ìdí èyí ni a fi ń pe ibẹ̀ ní Abeli-Misraimu. Kò sì jìnnà sí Jordani.
Локуиторий цэрий, канааниций, ау фост марторь ла бочетул ачеста дин ария луй Атад ши ау зис: „Ятэ ун маре бочет принтре еӂиптень!” Де ачея с-а дат ачестей арий нумеле Абел-Мицраим; еа есте динколо де Йордан.
12 Báyìí ni àwọn ọmọ Jakọbu ṣe ohun tí baba wọn pàṣẹ fún wọn.
Астфел ау ымплинит фиий луй Иаков порунчиле татэлуй лор.
13 Wọ́n gbé e lọ sí ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì sin ín sínú ihò àpáta tí ó wà ní oko Makpela, ní tòsí i Mamre tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti, pẹ̀lú ilẹ̀ náà.
Л-ау дус ын цара Канаан ши л-ау ынгропат ын пештера дин огорул Макпела, пе каре-л кумпэрасе Авраам де ла хетитул Ефрон ка мошие де ынмормынтаре ши каре есте фацэ ын фацэ ку Мамре.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú baba rẹ̀ tan, Josẹfu padà sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn mìíràn tí ó tẹ̀lé e lọ láti sin baba rẹ̀.
Иосиф, дупэ че а ынгропат пе татэл сэу, с-а ынторс ын Еӂипт ымпреунэ ку фраций сэй ши ку тоць чей че се суисерэ ку ел ка сэ ынгроапе пе татэл сэу.
15 Nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu rí i pé baba wọn kú, wọ́n wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ bí ó bá ṣe pé Josẹfu ṣì fi wá sínú ń kọ́, tí ó sì fẹ́ gbẹ̀san gbogbo aburú tí a ti ṣe sí i?”
Кынд ау вэзут фраций луй Иосиф кэ татэл лор а мурит, ау зис: „Дакэ ва принде Иосиф урэ пе ной ши не ва ынтоарче тот рэул пе каре и л-ам фэкут?”
16 Nítorí náà wọ́n ránṣẹ́ sí Josẹfu wí pé, “Baba rẹ fi àṣẹ yìí sílẹ̀ kí ó tó lọ wí pé,
Ши ау тримис сэ спунэ луй Иосиф: „Татэл тэу а дат порунка ачаста ынаинте де моарте:
17 ‘Èyí ni kí ẹ̀yin kí ó sọ fún Josẹfu, mo bẹ̀ ọ́ kí o dáríjì àwọn arákùnrin rẹ, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àti aburú tí wọ́n ṣe sí ọ, èyí tí ó mú ibi bá ọ’. Nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run baba rẹ jì wọ́n.” Nígbà tí iṣẹ́ ti wọ́n rán dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Josẹfu sọkún.
‘Аша сэ ворбиць луй Иосиф: «О, яртэ нелеӂюиря фрацилор тэй ши пэкатул лор, кэч ць-ау фэкут рэу!»’ Яртэ акум пэкатул робилор Думнезеулуй татэлуй тэу!” Иосиф а плынс кынд а аузит кувинтеле ачестя.
18 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wá, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n wí pé, “Ẹrú rẹ ni a jẹ́.”
Фраций луй ау венит ши с-ау арункат ей ыншишь ку фаца ла пэмынт ынаинтя луй ши й-ау зис: „Сунтем робий тэй.”
19 Ṣùgbọ́n Josẹfu wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí?
Иосиф ле-а зис: „Фиць фэрэ тямэ, кэч сунт еу оаре ын локул луй Думнезеу?
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbèrò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbèrò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là.
Вой, негрешит, в-аць гындит сэ-мь фачець рэу, дар Думнезеу а скимбат рэул ын бине, ка сэ ымплиняскэ чея че се веде азь, ши ануме сэ скапе вяца унуй попор ын маре нумэр.
21 Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèsè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.
Фиць дар фэрэ тямэ, кэч еу вэ вой хрэни пе вой ши пе копиий воштри.” Ши й-а мынгыят ши ле-а ымбэрбэтат инимиле.
22 Josẹfu sì ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láààyè fún àádọ́fà ọdún.
Иосиф а локуит ын Еӂипт, ел ши каса татэлуй сэу, ши а трэит о сутэ зече ань.
23 Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Efraimu-Àwọn ọmọ Makiri, ọmọkùnrin Manase ni a sì gbé le eékún Josẹfu nígbà tí ó bí wọn.
Иосиф а вэзут пе фиий луй Ефраим пынэ ла ал трейля ням; ши фиий луй Макир, фиул луй Манасе, с-ау нэскут пе ӂенункий луй.
24 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.”
Иосиф а зис фрацилор сэй: „Еу ам сэ мор! Дар Думнезеу вэ ва черчета ши вэ ва фаче сэ вэ суиць дин цара ачаста ын цара пе каре а журат кэ о ва да луй Авраам, луй Исаак ши луй Иаков.”
25 Josẹfu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra májẹ̀mú kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”
Иосиф а пус пе фиий луй Исраел сэ журе, зикынд: „Кынд вэ ва черчета Думнезеу, сэ луаць ши оаселе меле де аич.”
26 Báyìí ni Josẹfu kú nígbà tí ó pé àádọ́fà ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ṣe òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Ejibiti.
Иосиф а мурит ын вырстэ де о сутэ зече ань. Л-ау ымбэлсэмат ши л-ау пус ынтр-ун сикриу ын Еӂипт.

< Genesis 50 >