< Genesis 50 >

1 Josẹfu sì ṣubú lé baba rẹ̀, ó sọkún, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu.
Hat navah Joseph ni a na pa e mithmai a tabo sin teh ka laihoi a pahnuep.
2 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún àwọn oníṣègùn tí ó wà ní ìkáwọ́ rẹ̀ pé kí wọn kí ó ṣe òkú Israẹli baba rẹ̀ lọ́jọ̀, àwọn oníṣègùn náà sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Joseph ni tâsibawinaw hah a na pa e ro pawk hoeh nahanlah tâsi hluk hane kâ a poe. Hatdawkvah, tâsibawinaw ni Isarel e ro teh a pawk hoeh nahanlah tâsi a hluk awh.
3 Fún ogójì ọjọ́ ni wọ́n fi ṣe èyí, nítorí èyí ni àsìkò tí a máa ń fi ṣe ẹ̀ǹbáàmù òkú. Àwọn ará Ejibiti sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀ fún àádọ́rin ọjọ́.
A ro a rakuengnae dawk hnin 40 touh a ro. Bangkongtetpawiteh, ro a pawk thai hoeh nahanlah rakuengnae dawk hottelah ouk a ro. Hahoi, hnin 70 touh thung Izipnaw a khuika awh.
4 Nígbà tí ọjọ́ ìṣọ̀fọ̀ náà kọjá. Josẹfu wí fún àwọn ará ilé Farao pé, “Bí mo bá bá ojúrere yín pàdé, ẹ bá mi sọ fún Farao.
Ahni khuinae hnin a baw totouh, Joseph ni Faro imthungkhu koe a dei pouh teh, na lung ka youk pawiteh, pahren lahoi Faro hnâthai vah,
5 ‘Baba mi mú mi búra ó sì wí fún mi pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú: sinmi sínú ibojì tí mo gbẹ́ fún ara mi ní ilẹ̀ Kenaani.” Nísinsin yìí, jẹ́ kí n lọ kí n sì sìnkú baba mi, lẹ́yìn náà èmi yóò padà wa.’”
Apa ni lawk na kam sak, khenhaw! ka due han toe, Kanaan ram phuen ka ran tangcoung e dawk, haw vah na pakawm loe, telah ati. Hatdawkvah, pahren lahoi apa heh na pakawm sak ei, bout ka ban han ati, telah na dei pouh awh, telah atipouh.
6 Farao wí pé, “Gòkè lọ, kí o sì sin baba rẹ, bí ó tí mú ọ búra.”
Faro ni, thoe na bo sak e patetlah na pa teh pakawm, telah atipouh.
7 Báyìí ni Josẹfu gòkè lọ láti sìnkú baba rẹ̀. Gbogbo àwọn ìjòyè Farao ni ó sìn ín lọ—àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀, àti gbogbo àwọn àgbàgbà ilẹ̀ Ejibiti.
Hatdawkvah, Joseph teh a na pa pakawp hanelah a cei. Faro e a sannaw pueng, imthungkhu dawk e kacue naw hoi Izip ram e kacuenaw pueng,
8 Yàtọ̀ fún gbogbo àwọn ará ilé Josẹfu àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn tí ó jẹ́ ilé baba rẹ̀, àwọn ọmọ wọn nìkan àti agbo ẹran pẹ̀lú agbo màlúù ni ó sẹ́ kù ní Goṣeni.
Joseph imthungkhunaw pueng, a hmaunaw hoi a na pa imthungkhunaw pueng hai a cei awh. A ca kanawnaw hoi tuhunaw hoi maitonaw teh Goshen ram dawk a ta awh.
9 Kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin pẹ̀lú gòkè lọ. Àìmoye ènìyàn ni ó lọ.
Ahnimouh koevah, rangleng hoi marangransanaw hai a cei awh dawkvah, tamihupui lah ao.
10 Nígbà tí wọ́n dé ilẹ̀ ìpakà Atadi, ní ẹ̀bá Jordani, wọn pohùnréré ẹkún, níbẹ̀ ni Josẹfu sì tún dúró ṣọ̀fọ̀ baba rẹ̀ fún ọjọ́ méje.
Jordan namran e Atad cangkatinnae koevah a pha awh. Hote hmuen koe hnin sari touh thung a ka khai awh teh a tahungkhai awh.
11 Nígbà tí àwọn ará Kenaani tí ń gbé níbẹ̀ rí i bí wọ́n ti ń ṣọ̀fọ̀ náà ni ilẹ̀ ìpakà Atadi, wọ́n wí pé, “Ọ̀fọ̀ ńlá ni àwọn ará Ejibiti ń ṣe yìí.” Ìdí èyí ni a fi ń pe ibẹ̀ ní Abeli-Misraimu. Kò sì jìnnà sí Jordani.
Hote ram Kanaan taminaw ni Atad cangkatinnae koe vah a yu ro a tahungkhai awh e a hmu awh teh, hetheh Izipnaw e tami kadout tahungkhai e kalenpoung doeh, telah ati awh. Hatdawkvah, hote hmuen teh 'Abel-mizraim' telah ati awh. Hot teh, Jordan namran lah kaawm e doeh.
12 Báyìí ni àwọn ọmọ Jakọbu ṣe ohun tí baba wọn pàṣẹ fún wọn.
A canaw ni kâ a poe e patetlah ahnimouh hanlah a sak awh.
13 Wọ́n gbé e lọ sí ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì sin ín sínú ihò àpáta tí ó wà ní oko Makpela, ní tòsí i Mamre tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti, pẹ̀lú ilẹ̀ náà.
A canaw ni Kanaan ram a kâenkhai awh teh Abraham ni kâpakawp nahane hmuen râw lah, Hit tami Ephron koehoi law a ran e Mamre kho hmalah kaawm e Makpelah law e lungngoum thung vah a pakawp awh.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú baba rẹ̀ tan, Josẹfu padà sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn mìíràn tí ó tẹ̀lé e lọ láti sin baba rẹ̀.
A na pa a pakawp awh hnukkhu, Joseph hoi a hmaunaw hoi a na pa pakawpnae koe kacetnaw pueng hoi cungtalah Izip ram lah a ban awh.
15 Nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu rí i pé baba wọn kú, wọ́n wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ bí ó bá ṣe pé Josẹfu ṣì fi wá sínú ń kọ́, tí ó sì fẹ́ gbẹ̀san gbogbo aburú tí a ti ṣe sí i?”
Joseph e hmaunaw ni a na pa a due e hah a hmu navah, Joseph ni na hmawt ngai awh hoeh vaiteh, ahni koe sak awh e hnokahawi hoeh e naw pueng hah moi koung na pathung han vaimoe, telah a kâti awh.
16 Nítorí náà wọ́n ránṣẹ́ sí Josẹfu wí pé, “Baba rẹ fi àṣẹ yìí sílẹ̀ kí ó tó lọ wí pé,
Hatdawkvah, Joseph koe dei hanelah tami a patoun awh teh, na pa ni a due hoehnahlan vah, hettelah Joseph koe na dei pouh han.
17 ‘Èyí ni kí ẹ̀yin kí ó sọ fún Josẹfu, mo bẹ̀ ọ́ kí o dáríjì àwọn arákùnrin rẹ, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àti aburú tí wọ́n ṣe sí ọ, èyí tí ó mú ibi bá ọ’. Nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run baba rẹ jì wọ́n.” Nígbà tí iṣẹ́ ti wọ́n rán dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Josẹfu sọkún.
Nang lathueng yonnae a sak awh eiteh, pahren lahoi na hmaunaw e kâtapoenae hoi a yonnae teh ngaithoum loe, telah kâ na poe. Hatdawkvah, na pa Cathut e sannaw e kâtapoenae hah ngaithoum pouh, telah ati. Ahni koe a dei pouh navah, Joseph teh a ka.
18 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wá, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n wí pé, “Ẹrú rẹ ni a jẹ́.”
A hmaunaw ni hai a cei awh teh a hmalah tabo laihoi khenhaw! na sannaw lah ka o awh, telah atipouh awh.
19 Ṣùgbọ́n Josẹfu wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí?
Joseph ni ahnimouh koevah, taket awh hanh awh, Bangkongtetpawiteh, Cathut e yueng lah maw ka o.
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbèrò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbèrò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là.
Nangmouh ni ka lathueng vah, hawihoehnae hah sak han na kâcai awh, hateiteh, Cathut ni sahnin vah tami moikapap hringnae rungngang hanelah hawinae hah sak han noenae lah ao.
21 Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèsè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.
Hatdawkvah, taket awh hanh. Nangmouh hoi na canaw teh pou na kawk awh han, telah atipouh. Hottelah lungmawng sak teh lawk kahawi hoi a pato.
22 Josẹfu sì ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láààyè fún àádọ́fà ọdún.
Joseph teh ama hoi a na pa imthungkhunaw hoi Izip ram vah kho a sak awh. Joseph teh kum 110 touh a hring.
23 Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Efraimu-Àwọn ọmọ Makiri, ọmọkùnrin Manase ni a sì gbé le eékún Josẹfu nígbà tí ó bí wọn.
Joseph ni Ephraim e a canaw, a na mincanaw hoi se thum totouh e a hmu. Manasseh capa, Makhir canaw hai Joseph e khokpakhu dawk a khe awh.
24 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.”
Joseph ni a hmaunawnghanaw koe, ka due han toe, hateiteh, Cathut ni na khet han. Hete ram dawk hoi na tâcokhai awh vaiteh, Abraham, Isak hoi Jakop koe thoebo hoi lawkkam e ram dawk na ceikhai awh han, telah atipouh.
25 Josẹfu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra májẹ̀mú kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”
Hatdawkvah, Joseph ni Isarel catounnaw hah lawkkamnae a sak teh, Cathut ni na khet awh roeroe han. Ka hru hah hete hmuen koehoi na ceikhai awh han, telah ati.
26 Báyìí ni Josẹfu kú nígbà tí ó pé àádọ́fà ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ṣe òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Ejibiti.
Hatdawkvah, Joseph teh kum 110 touh a pha nah a due. A ro teh kapawk thai hoeh lah a sak awh teh Izip e thingkong buet touh thungvah a ta awh.

< Genesis 50 >