< Genesis 50 >
1 Josẹfu sì ṣubú lé baba rẹ̀, ó sọkún, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu.
Te vaengah Joseph loh a napa maelhmai a bakop thil tih a soah a rhah neh a mok.
2 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún àwọn oníṣègùn tí ó wà ní ìkáwọ́ rẹ̀ pé kí wọn kí ó ṣe òkú Israẹli baba rẹ̀ lọ́jọ̀, àwọn oníṣègùn náà sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Te phoeiah Joseph loh a napa te sihluk ham a sal siboei rhoek te a uen tih siboei rhoek loh Isreal te si a hlukuh.
3 Fún ogójì ọjọ́ ni wọ́n fi ṣe èyí, nítorí èyí ni àsìkò tí a máa ń fi ṣe ẹ̀ǹbáàmù òkú. Àwọn ará Ejibiti sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀ fún àádọ́rin ọjọ́.
Sihluknah khohnin te khohnin lipkip a di ham a om dongah khohnin a soep vanneh rhok te Egypt rhoek loh khohnin sawmrhih a rhah uh.
4 Nígbà tí ọjọ́ ìṣọ̀fọ̀ náà kọjá. Josẹfu wí fún àwọn ará ilé Farao pé, “Bí mo bá bá ojúrere yín pàdé, ẹ bá mi sọ fún Farao.
Rhahnah khohnin a poeng vaengah Joseph loh Pharaoh im la, “Na mikhmuh ah mikdaithen ni ka dang atah Pharaoh kah hna kaep ah bet ka thui mai eh.
5 ‘Baba mi mú mi búra ó sì wí fún mi pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú: sinmi sínú ibojì tí mo gbẹ́ fún ara mi ní ilẹ̀ Kenaani.” Nísinsin yìí, jẹ́ kí n lọ kí n sì sìnkú baba mi, lẹ́yìn náà èmi yóò padà wa.’”
A pa loh, 'Ka duek atah Kanaan kho ah kamah ham ka vueh tangtae phuel ah pahoi nan up ni, ' a ti tih kai he n'toemngam sak oeh dongah bet ka cet saeh lamtah a pa te ka up phoeiah ka bal mai eh?,” a ti nah.
6 Farao wí pé, “Gòkè lọ, kí o sì sin baba rẹ, bí ó tí mú ọ búra.”
Pharaoh long khaw, “Na toemngam vanbangla cet lamtah na pa te up dae,” a ti nah.
7 Báyìí ni Josẹfu gòkè lọ láti sìnkú baba rẹ̀. Gbogbo àwọn ìjòyè Farao ni ó sìn ín lọ—àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀, àti gbogbo àwọn àgbàgbà ilẹ̀ Ejibiti.
Te dongah Joseph te a napa up ham a caeh hatah Pharaoh kah sal boeih neh a im kah a hamca rhoek long khaw, Egypt kho kah a hamca boeih long khaw,
8 Yàtọ̀ fún gbogbo àwọn ará ilé Josẹfu àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn tí ó jẹ́ ilé baba rẹ̀, àwọn ọmọ wọn nìkan àti agbo ẹran pẹ̀lú agbo màlúù ni ó sẹ́ kù ní Goṣeni.
Joseph cako boeih neh a manuca rhoek long khaw, a napa cako long khaw a thak puei uh. Camoe neh a boiva, saelhung bueng te Goshen kho ah a caehtak uh.
9 Kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin pẹ̀lú gòkè lọ. Àìmoye ènìyàn ni ó lọ.
Te dongah anih taengah aka cet te leng khaw, marhang caem khaw lambong yet la muep om.
10 Nígbà tí wọ́n dé ilẹ̀ ìpakà Atadi, ní ẹ̀bá Jordani, wọn pohùnréré ẹkún, níbẹ̀ ni Josẹfu sì tún dúró ṣọ̀fọ̀ baba rẹ̀ fún ọjọ́ méje.
Tedae Jordan rhalvangan kah Atad te a pha uh vaengah rhaengsaelung neh bungbung mat a rhaengsae uh tih a napa ham nguekcoinah te hnin rhih a yaeh uh.
11 Nígbà tí àwọn ará Kenaani tí ń gbé níbẹ̀ rí i bí wọ́n ti ń ṣọ̀fọ̀ náà ni ilẹ̀ ìpakà Atadi, wọ́n wí pé, “Ọ̀fọ̀ ńlá ni àwọn ará Ejibiti ń ṣe yìí.” Ìdí èyí ni a fi ń pe ibẹ̀ ní Abeli-Misraimu. Kò sì jìnnà sí Jordani.
Tedae Atad ah a nguekcoinah te Kanaan kho kah khosa rhoek loh a hmuh uh vaengah, “Hekah he Egypt rhoek loh mat a nguekcoinah ni,” a ti uh dongah Jordan rhalvangan kah a ming te Abelmizaim la a khue.
12 Báyìí ni àwọn ọmọ Jakọbu ṣe ohun tí baba wọn pàṣẹ fún wọn.
Te dongah a uen vanbangla Isreal ham a ca rhoek loh a saii uh tih,
13 Wọ́n gbé e lọ sí ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì sin ín sínú ihò àpáta tí ó wà ní oko Makpela, ní tòsí i Mamre tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti, pẹ̀lú ilẹ̀ náà.
Kanaan kho la a khuen uh. Te phoeiah Abraham loh phuel khohut la Khitti Ephron kah khohmuen Mamre ah a lai Makpelah lo kah lungko ah a up uh.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú baba rẹ̀ tan, Josẹfu padà sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn mìíràn tí ó tẹ̀lé e lọ láti sin baba rẹ̀.
Joseph neh a manuca rhoek khaw, a napa up ham anih taengah aka cet boeih long khaw a napa te aup phoeiah Egypt la bal uh.
15 Nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu rí i pé baba wọn kú, wọ́n wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ bí ó bá ṣe pé Josẹfu ṣì fi wá sínú ń kọ́, tí ó sì fẹ́ gbẹ̀san gbogbo aburú tí a ti ṣe sí i?”
Tedae a napa a duek coeng dongah Joseph te a manuca rhoek loh a hmuh uh vaengah, “Joseph he mamih taengah a konaeh koinih anih taengah boethae n'saii uh boeih te n'thuung rhoe n'thuung ni,” a ti uh.
16 Nítorí náà wọ́n ránṣẹ́ sí Josẹfu wí pé, “Baba rẹ fi àṣẹ yìí sílẹ̀ kí ó tó lọ wí pé,
Te dongah Joseph taengla ol a uen uh tih, “Na pa loh a duek hlan ah,
17 ‘Èyí ni kí ẹ̀yin kí ó sọ fún Josẹfu, mo bẹ̀ ọ́ kí o dáríjì àwọn arákùnrin rẹ, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àti aburú tí wọ́n ṣe sí ọ, èyí tí ó mú ibi bá ọ’. Nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run baba rẹ jì wọ́n.” Nígbà tí iṣẹ́ ti wọ́n rán dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Josẹfu sọkún.
'Joseph te, 'Na manuca rhoek kah dumlai khaw, nang a thae la n'saii uh vaengakah tholhnah te khaw phueih mai ti nah,’ a ti tih n'uen dongah na pa Pathen sal rhoek kah boekoeknah te phuei mai,” a ti nah uh tih a thui uh vaengah Joseph rhap.
18 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wá, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n wí pé, “Ẹrú rẹ ni a jẹ́.”
Te dongah a manuca rhoek khaw cet uh tih a hmai ah bakop uh tih kaimih he nang kah sal ni he a ti uh.
19 Ṣùgbọ́n Josẹfu wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí?
Tedae Joseph loh, “kai he Pathen hnukthoi a? Rhih uh boeh saw.
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbèrò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbèrò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là.
Nangmih loh kai taengah boethae la nan taeng uh cakhaw Pathen loh tahae khohnin kah bangla pilnam muep hing sak ham te a then la a moeh coeng.
21 Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèsè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.
Te dongah rhih uh boeh. Nangmih khaw, na ca rhoek khaw kan cangbam bitni,” a ti nah tih amih lungbuei te hloep ol a thui pah.
22 Josẹfu sì ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láààyè fún àádọ́fà ọdún.
Joseph khaw Egypt ah a napa kah a cako neh kho a sak. Te vaengah Joseph te kum pasoi neh kum rha hing.
23 Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Efraimu-Àwọn ọmọ Makiri, ọmọkùnrin Manase ni a sì gbé le eékún Josẹfu nígbà tí ó bí wọn.
Te dongah Joseph loh Ephraim ca rhoek a khongthum duela a hmuh. Manasseh capa Makir ca rhoek khaw Joseph khuklu dongah a cun uh.
24 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.”
Te vaengah Joseph loh a manuca rhoek la, “Kai ka duek cakhaw Pathen loh nangmih n'hip khaw n'hip vetih nangmih te tahae kah kho lamkah Abraham, Isaak neh Jakob ham a toemngam tangtae khohmuen la khuen bitni,” a ti nah.
25 Josẹfu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra májẹ̀mú kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”
Te dongah Joseph loh Israel ca rhoek te a toemngam sak tih, “Nangmih te Pathen loh n'hip rhoe la n'hip vaengah he lamkah ka rhuh na khuen uh ni,” a ti nah.
26 Báyìí ni Josẹfu kú nígbà tí ó pé àádọ́fà ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ṣe òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Ejibiti.
Joseph he kum pasoi neh a lang a lo ca vaengah duek tih a rhok te si a hluk uh phoeiah Egypt kah thingkawng dongah a khueh uh.