< Genesis 5 >

1 Èyí ni àkọsílẹ̀ ìran Adamu. Nígbà tí Ọlọ́run dá ènìyàn, ní àwòrán Ọlọ́run ni ó dá a.
Tato jest kniha rodů Adamových. V ten den, v kterémž stvořil Bůh člověka, ku podobenství Božímu učinil ho.
2 Àti akọ àti abo ni Ó dá wọn, ó sì súre fún wọn, ó sì pe orúkọ wọ́n ní Adamu ní ọjọ́ tí ó dá wọn.
Muže a ženu stvořil je a požehnal jim, a nazval jméno jejich Adam v ten den, když stvořeni jsou.
3 Nígbà tí Adamu di ẹni àádóje ọdún, ó bí ọmọkùnrin kan tí ó jọ ọ́, tí ó jẹ́ àwòrán ara rẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Seti.
Byl pak Adam ve stu a třidcíti letech, když zplodil syna ku podobenství svému a k obrazu svému, a nazval jméno jeho Set.
4 Ọjọ́ Adamu, lẹ́yìn ìgbà tí ó bí Seti, jẹ́ ẹgbẹ̀rin ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
I bylo dnů Adamových po zplození Seta osm set let, a plodil syny a dcery.
5 Àpapọ̀ ọdún tí Adamu gbé ní orí ilẹ̀ jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún ọdún ó lé ọgbọ̀n, ó sì kú.
A tak bylo všech dnů Adamových, v kterýchž byl živ, devět set a třidceti let, i umřel.
6 Nígbà tí Seti pé àrùnlélọ́gọ́rùn-ún ọdún, ó bí Enoṣi.
Set pak byl ve stu a pěti letech, když zplodil Enosa.
7 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bí Enoṣi, Seti sì gbé fún ẹgbẹ̀rin ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn; ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
A po zplození Enosa živ byl Set osm set a sedm let, a plodil syny a dcery.
8 Àpapọ̀ ọdún Seti sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún ọdún ó lé méjìlá, ó sì kú.
I bylo všech dnů Setových devět set a dvanácte let, i umřel.
9 Nígbà tí Enoṣi di ẹni àádọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Kenani.
Byl pak Enos v devadesáti letech, když zplodil Kainana.
10 Lẹ́yìn tí ó bí Kenani, Enoṣi sì wà láààyè fún ẹgbẹ̀rin ọdún ó lé mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, ó sì bí àwọn ọkùnrin àti obìnrin.
A po zplození Kainana živ byl Enos osm set a patnácte let, a plodil syny a dcery.
11 Àpapọ̀ ọdún Enoṣi jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún ọdún ó lé márùn-ún, ó sì kú.
I bylo všech dnů Enosových devět set a pět let, i umřel.
12 Nígbà tí Kenani di àádọ́rin ọdún ni ó bí Mahalaleli.
Kainan pak byl v sedmdesáti letech, když zplodil Mahalaleele.
13 Lẹ́yìn tí ó bí Mahalaleli, Kenani wà láààyè fún òjìlélẹ́gbẹ̀rin ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
A po zplození Mahalaleele živ byl Kainan osm set a čtyřidceti let, a plodil syny a dcery.
14 Àpapọ̀ ọjọ́ Kenani jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún ọdún ó lé mẹ́wàá, ó sì kú.
I bylo všech dnů Kainanových devět set a deset let, i umřel.
15 Nígbà tí Mahalaleli pé ọmọ àrùnlélọ́gọ́ta ọdún ni ó bí Jaredi.
Mahalaleel pak byl v šedesáti a pěti letech, když zplodil Járeda.
16 Mahalaleli sì gbé fún ẹgbẹ̀rin ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn ìgbà tí ó bí Jaredi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
A po zplození Járeda živ byl Mahalaleel osm set a třidceti let, a plodil syny a dcery.
17 Àpapọ̀ iye ọdún Mahalaleli jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún ọdún ó dín márùn-ún, ó sì kú.
I bylo všech dnů Mahalaleelových osm set devadesáte a pět let, i umřel.
18 Nígbà tí Jaredi pé ọmọ ọgọ́jọ ọdún ó lé méjì ni ó bí Enoku.
Járed pak byl ve stu šedesáti a dvou letech, když zplodil Enocha.
19 Lẹ́yìn èyí, Jaredi wà láààyè fún ẹgbẹ̀rin ọdún Enoku sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
A po zplození Enocha živ byl Járed osm set let, a plodil syny a dcery.
20 Àpapọ̀ ọdún Jaredi sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún dín méjìdínlógójì, ó sì kú.
I bylo všech dnů Járedových devět set šedesáte a dvě létě, i umřel.
21 Nígbà tí Enoku pé ọmọ ọgọ́ta ọdún ó lé márùn ni ó bí Metusela.
Enoch pak byl v šedesáti a pěti letech, když zplodil Matuzaléma.
22 Lẹ́yìn tí ó bí Metusela, Enoku sì bá Ọlọ́run rìn ní ọ̀ọ́dúnrún ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
A chodil Enoch stále s Bohem po zplození Matuzaléma tři sta let, a plodil syny a dcery.
23 Àpapọ̀ ọjọ́ Enoku sì jẹ́ irinwó ọdún dín márùndínlógójì.
I bylo všech dnů Enochových tři sta šedesáte a pět let.
24 Enoku bá Ọlọ́run rìn; a kò sì rí i mọ́ nítorí Ọlọ́run mú un lọ.
A chodil Enoch stále s Bohem a nebyl více vidín; nebo vzal ho Bůh.
25 Nígbà tí Metusela pé igba ọdún dín mẹ́tàlá ní o bí Lameki.
Matuzalém pak byl ve stu osmdesáti sedmi letech, když zplodil Lámecha.
26 Lẹ́yìn èyí Metusela wà láààyè fún ẹgbẹ̀rin ọdún dín méjìdínlógún, lẹ́yìn ìgbà tí ó bí Lameki, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
A po zplození Lámecha živ byl Matuzalém sedm set osmdesáte a dvě létě, a plodil syny a dcery.
27 Àpapọ̀ ọdún Metusela jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún dín mọ́kànlélọ́gbọ̀n, ó sì kú.
I bylo všech dnů Matuzalémových devět set šedesáte a devět let, i umřel.
28 Nígbà tí Lameki pé ọdún méjìlélọ́gọ́sàn án ni ó bí ọmọkùnrin kan.
Lámech pak byl ve stu osmdesáti a dvou letech, když zplodil syna,
29 Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Noa, ó sì wí pé, “Eléyìí ni yóò tù wá nínú ni iṣẹ́ àti làálàá ọwọ́ wa, nítorí ilẹ̀ tí Olúwa ti fi gégùn ún.”
Jehož jméno nazval Noé, řka: Tento nám odpočinutí způsobí od díla našeho, od práce rukou našich, kterouž máme s zemí, jížto zlořečil Hospodin.
30 Lẹ́yìn tí ó bí Noa, Lameki gbé fún ẹgbẹ̀ta ọdún dín márùn-ún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
A živ byl Lámech potom, když zplodil Noé, pět set devadesáte a pět let, a plodil syny a dcery.
31 Àpapọ̀ ọdún Lameki sì jẹ́ ẹgbẹ̀rin ọdún dín mẹ́tàlélógún, ó sì kú.
I bylo všech dnů Lámechových sedm set sedmdesáte a sedm let, i umřel.
32 Lẹ́yìn tí Noa pé ọmọ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún ni ó bí Ṣemu, Hamu àti Jafeti.
A když byl Noé v pěti stech letech, zplodil Sema, Chama a Jáfeta.

< Genesis 5 >