< Genesis 49 >
1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
Andin Yaqup oghullirini chaqirip ulargha mundaq dédi: — [Hemminglar] jem bolunglar, men silerge kéyinki künlerde siler yoluqidighan ishlarni éytip bérey: —
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
Yighilip kélip anglanglar, i Yaqupning oghulliri; Atanglar Israilgha qulaq sélinglar.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Ey Ruben, sen méning tunji oghlumsen, Küch-qudritimsen, Küchüm bar waqtimning tunji méwisidursen, Salapet we qudrette aldi iding,
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
Lékin qaynap téship chüshken sudek, Emdi aldi bolalmassen; Chünki sen atangning körpisige chiqting, Shuning bilen sen uni bulghiding! U méning körpemning üstige chiqti!
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Shiméon bilen Lawiy qérindashlardur; Ularning qilichliri zorawanliqning qoralliridur!
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Ah jénim, ularning meslihitige kirmigin! I izzitim, ularning jamaiti bilen chétilip qalmighay! Chünki ular achchiqida ademlerni öltürüp, Öz béshimchiliq qilip buqilarning péyini kesti.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Ularning achchiqi esheddiy bolghachqa lenetke qalsun! Ghezipimu rehimsiz bolghachqa lenetke qalsun! Men ularni Yaqupning ichide tarqitiwétimen, Israilning ichide ularni chéchiwétimen.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
Ey Yehuda! Séni bolsa qérindashliring teripler, Qolung düshmenliringning gejgisini basar. Atangning oghulliri sanga bash urar,
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Yehuda yash bir shirdur; Ey oghlum, sen owni tutupla chiqting; U shirdek [owning yénida] chöküp sozulup yatsa, Yaki chishi shirdek yétiwalsa, Kimmu uni qozghashqa pétinar?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Shahane hasa Yehudadin kétip qalmaydu, Yehudaning pushtidin qanun chiqarghuchi öksümeydu, Taki shu hoquq Igisi kelgüche kütidu; Kelgende, jahan xelqliri uninggha itaet qilidu.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
U texiyini üzüm téligha, Éshek balisini sortluq üzüm téligha baghlap qoyar. U libasini sharabta yuyup, Tonini üzüm sherbitide yuyar.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Uning közliri sharabtin qizirip kéter, Chishliri süt ichkinidin ap’aq turar.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
Zebulun déngiz boyini makan qilar, Makani kémilerning panahgahi bolar, Yer-zémini Zidon’ghiche yétip barar.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
Issakar bestlik berdem bir éshektur, U ikki qotan arisida yatqandur;
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
U aramgahning yaxshi ikenlikige qarap, Zéminning ésilliqini körüp, Yük kötürüshke mürisini égip, Alwan’gha ishleydighan qul bolup qalar.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Dan Israil qebililiridin biri bolar, Öz xelqige höküm chiqirar.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Dan yol üstidiki yilan, Chighir yol üstide turghan zeherlik bir yilandur. U atning tuyiqini chéqip, At min’güchini arqigha mollaq atquzar.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
I Perwerdigar, nijatinggha telmürüp kütüp keldim!
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
Gadqa bolsa, qaraqchilar qoshuni hujum qilar; Lékin u tapinini bésip zerbe bérer.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
Ashirning tamiqida zeytun méyi mol bolar, U shahlar üchün nazu-németlerni teminler.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
Naftalidin chirayliq gepler chiqar, U erkin qoyuwétilgen maraldur.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
Yüsüp méwilik derexning shéxidur, Bulaqning yénidiki köp méwilik shaxtektur; Uning shaxchiliri tamdin halqip ketkendur.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Ya atquchilar uninggha azar qilip, Uninggha oq atti, uninggha nepretlendi.
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
Halbuki, uning oqyayi mezmut turar, Qol-bilekliri eplik turghuzular, Shu [küch] Yaquptiki qudret Igisining qolliridindur — (Israilning Qoram Téshi, yeni uning Padichisi Uningdin chiqar!)
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
[Ashu küch] atangning Tengrisidindur — (U sanga medet bérer!) [Yeni] Hemmige Qadirdindur — U séni beriketler! Yuqirida asmanning beriketliri bilen, Töwende yatqan chongqur sularning beriketliri bilen, Emchek bilen baliyatquning berikiti bilen séni beriketler!
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Séning atangning tiligen beriketliri ata-bowilirimning tiligen beriketliridin ziyade boldi, Ular menggülük tagh-édirlarning chetlirigiche yéter, Ular Yüsüpning béshigha chüsher, Yeni öz qérindashliridin ayrim turghuchining choqqisigha téger.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
Binyamin yirtquch böridektur; Etigende u owni yer. Kechqurun u oljisini teqsim qilar» — dédi.
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
Bularning hemmisi Israilning on ikki qebilisi bolup, mezkur sözler bolsa atisining ulargha tiligen bext-beriket sözliridur. U shuning bilen ularning herbirige mas kélidighan bir beriket bilen ulargha bext-beriket tilidi.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
Andin Yaqup ulargha mundaq tapilidi: — «Men emdi öz qowmimning qéshigha qoshulimen. Siler méni ata-bowilirimning yénida, hittiylardin bolghan Efronning étizliqidiki ghargha depne qilinglar;
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
u ghar bolsa Qanaan zéminida Mamrening udulida, Makpélahning étizliqida. Gharni Ibrahim göristan bolsun dep shu étizliq bilen qoshup hittiy Efrondin sétiwalghanidi.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
Shu yerde Ibrahim ayali Sarah bilen depne qilin’ghan; shu yerde Ishaq ayali Riwkah bilenmu depne qilin’ghan; shu yerde menmu Léyahni depne qildim.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Bu étizliq hem ichidiki ghar Hetning ewladliridin sétiwélin’ghanidi».
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
Yaqup oghullirigha bu wesiyetni tapilap bolup, putlirini kariwatta tüzlep, nepes toxtap öz qowmigha qoshuldi.