< Genesis 49 >

1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
Yakup oğullarını çağırarak, “Yanıma toplanın” dedi, “Gelecekte size neler olacağını anlatayım.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
“Yakupoğulları, toplanın ve dinleyin, Babanız İsrail'e kulak verin.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
“Ruben, sen benim ilk oğlum, gücümsün, Kudretimin ilk ürünüsün, Saygı ve güç bakımından en üstünsün.
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
Ama su gibi oynaksın, Üstün olmayacaksın artık. Çünkü babanın yatağına girip Onu kirlettin. Döşeğimi rezil ettin.
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
“Şimon'la Levi kardeştir, Kılıçları şiddet kusar.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Gizli tasarılarına ortak olmam, Toplantılarına katılmam. Çünkü öfkelenince adam öldürdüler, Canları istedikçe sığırları sakatladılar.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Lanet olsun öfkelerine, Çünkü şiddetlidir. Lanet olsun gazaplarına, Çünkü zalimcedir. Onları Yakup'ta bölecek Ve İsrail'de dağıtacağım.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
“Yahuda, kardeşlerin seni övecek, Düşmanlarının ensesinde olacak elin. Kardeşlerin önünde eğilecek.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Yahuda bir aslan yavrusudur. Oğlum benim! Avından dönüp yere çömelir, Aslan gibi, dişi bir aslan gibi yatarsın. Kim onu uyandırmaya cesaret edebilir?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Sahibi gelene kadar Krallık asası Yahuda'nın elinden çıkmayacak, Yönetim hep onun soyunda kalacak, Uluslar onun sözünü dinleyecek.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
Eşeğini bir asmaya, Sıpasını seçme bir dala bağlayacak; Giysilerini şarapta, Kaftanını üzümün kızıl kanında yıkayacak.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Gözleri şaraptan kızıl, Dişleri sütten beyaz olacak.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
“Zevulun deniz kıyısında yaşayacak, Liman olacak gemilere, Sınırı Sayda'ya dek uzanacak.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
“İssakar semerler arasında yatan güçlü eşek gibidir;
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
Ne zaman dinlenecek iyi bir yer, Hoşuna giden bir ülke görse, Yüklenmek için sırtını eğer, Angaryaya katlanır.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
“Dan kendi halkını yönetecek, Bir İsrail oymağı gibi.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Yol kenarında bir yılan, Toprak yolda bir engerek olacak; Atın topuklarını ısırıp Atlıyı sırtüstü düşüren bir engerek.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
“Ben senin kurtarışını bekliyorum, ya RAB.
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
“Gad akıncıların saldırısına uğrayacak, Ama onların topuklarına saldıracak.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
“Zengin yemekler olacak Aşer'de, Krallara yaraşır lezzetli yiyecekler yetiştirecek Aşer.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
“Naftali salıverilmiş geyiğe benzer, Sevimli yavrular doğurur.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
“Yusuf meyveli bir dal gibidir, Kaynak kıyısında verimli bir dal gibi, Filizleri duvarların üzerinden aşar.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Okçular acımadan saldırdı ona. Düşmanca savurdular oklarını üzerine.
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
Ama onun yayı sağlam, Kolları esnek çıktı; Yakup'un güçlü Tanrısı, İsrail'in Kayası, Çobanı olan Tanrı sayesinde.
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
Sana yardım eden babanın Tanrısı'dır, Her Şeye Gücü Yeten Tanrı'dır seni kutsayan. Yukarıdaki göklerin Ve aşağıdaki denizlerin bereketiyle, Memelerin, rahimlerin bereketiyle O'dur seni kutsayan.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Babanın kutsamaları ebedi dağların nimetlerinden, Ebedi tepelerin bolluğundan daha yücedir; Yusuf'un başı üzerinde, Kardeşleri arasında önder olanın üstünde olacak.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
“Benyamin aç kurda benzer; Sabah avını yer, Akşam ganimeti paylaşır.”
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
İsrail'in on iki oymağı bunlardır. Babaları onları kutsarken bunları söyledi. Her birini uygun biçimde kutsadı.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
Sonra Yakup oğullarına şu buyrukları verdi: “Ben ölmek, halkıma kavuşmak üzereyim. Beni Kenan ülkesinde atalarımın yanına, Mamre yakınlarında Hititli Efron'un tarlasındaki mağaraya, Makpela Tarlası'ndaki mağaraya gömün. İbrahim o mağarayı mezar yapmak üzere Hititli Efron'dan tarlasıyla birlikte satın almıştı.
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
İbrahim'le karısı Sara, İshak'la karısı Rebeka oraya gömüldüler. Lea'yı da ben oraya gömdüm.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Tarla ile içindeki mağara Hititler'den satın alındı.”
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
Yakup oğullarına verdiği buyrukları bitirince, ayaklarını yatağın içine çekti, son soluğunu vererek halkına kavuştu.

< Genesis 49 >