< Genesis 49 >

1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
Yaaq'ubee dixbı qopt'ul eyhen: – Yizde k'anyaqa savaale, vuşde vuk'lelqa qalesınbı zı yuşan ha'as.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
Yaaq'ubun dixbı, sabı zal k'ırı alixhxhe, Vuşde dekkıl İzrailir k'ırı gyaqqe.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Ruven, ğu yizda ts'erriyna dix, ğu yizda guc. Ğu yedike zı mek'varanang'a taq'atıkanang'a ıxha. Ğu gırgıng'ule xərna, qıvaats'ana vor.
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
Ğu xhyanık akar sa'as-qa'as əxə deş. Vak'le man ats'axhxhe, ğu yik' hı'ı yizde tyuleeqa k'iç'uva, yizde xhunaşşeeşine sang'ıka g'alirxhuva, vake xərna ixhes deş!
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Şimoniy Levi çocar vob, Manbışe qəlasın ha'asva g'ılınc xılyaqa alyaata.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Manbı qəlakanang'a adamer gyabat'a, Yik'es ıkkanang'ad manbışin həyvanar kara idyaalesın xhinne qaa'a. Manbışe ək'elee aqqıyn karbı zı ha'as deş, Zı manbışika sarçes deş.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Fiğan haa'ane manbışde qəlbışisiy Xıl ts'ıts'dya'ane bahaliyvalis bed-düə vuxhena. Zı manbışike g'abıynbı sacigeeqa savaales havaasaras deş, İzrailvolle oot'alasınbı.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
Yahud, yiğne çocaaşe ğu axtı qa'as, Duşmanaaşina gardan yiğne xıle vuxhes, dekkın dixbıb vas k'yoozaras.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Yizda dix, Yahud, ğu k'on qoodu-soodu qööne mek'vne aslanık akar. Ğu manzil haa'ane şirık akar, horku-qorku ç'iyel g'ılexha, Şavusse şir g'udokana'as əxəyee?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Paççahiyvalla Yahudne xıleençe mısacab əlyhəəs deş. Gırgıne gahbışil vuk'lek vukkiy mang'unee nasılınbışisse mebınbışilqa ılğeeç'es deş. Nimeeletteyiy gırgın milletbı k'yozarasda vake paççah g'idyarı.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
Yahudıqa manimee xətta t'ımılen tayangbı eyxhe, mang'us manbı qidiykkın cuna əməleb çik avt'alas vəəxəna, Çike hı'iyne çaxıree tanalinbıd hoğalas əxənbı.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Mang'unee uleppışin adın ciga çaxırıle k'ışşeyda, Silibıd niknele cagvarada ixhes.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
Zevulunun cigad deryahne mıglek ixhes, Maa'ad gamıbı ileezaras, Mang'un ciga Sidonnee şaharılqa hixharas.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
Xurcunbı mıgal alixhxhı manzil haa'ana İssaxar taq'atıkane əməleyk akar.
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
Mang'us vuc manzilis ulyorzulin ciga yugda qadı, maana nyaq'v cus vukkanəxüb g'avcu, mang'vee yı'q' k'yozarı'ı mebbınbışis iş haa'ana.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Danir İzrailyne nasılbışda sa vob, Mang'vee cune milletıs məhkama haa'as.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Dani yəqqı'ne mıglekna xoçe xhinne ixhes. Balkanne guvuyk üvxü Çilyna yı'qı'hina g'ı'xə'əne.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
Rəbb, zı gozet ha'an Ğu mısayiy zı duşmanaaşike g'attixhan ha'as!
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
Mebınbı Qadın cigabı q'əra qa'as ables, Mang'veeyib manbı g'e'ebaşeng'a q'əra qaa'as.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
Aşerne cigabışee otxhuniy barakayka ixhes, Mang'vee paççahaaşisıd otxhuniy alles.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
Naftali g'avkkune maralık akar, Mang'uke g'abıynbı geeb micagınbı vuxhes.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
Yusufmee, xhyan ı'lqəəne cigaysneene, bıtağbıd cabırıle g'alysikkıyne tayangık akar.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Duşmanar mang'ulqa qəlıka vukaaşika kyoohar,
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
Mang'un xıleppı gucuka vodva mang'vee vuk xıle it'umda aqqaqqa. Mang'us guc hoole vuxha Yaaq'ubee ı'bəədat ha'ane Allahee. Allah İzrailiqa çoban cune syuriyqa ilyakkan xhinne ilyakka. Mana manbışda Suva vobna.
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
Yiğne dekkee ı'bəədat ha'ana Allah hasre vas kumagxhecen, Hasre Mang'vee vas xayir-düə hevlecen, Xəəne-ç'iyeyne xhyanbışike ğu g'ıts'mayk'vancen, Vas geeb uşaxaariy çavra-vəq'ə helecen.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Yiğne dekkına xayir-düə barakatnane çolbışileb geeb vob, Ğu manisa çocaaşile qıvaats'anava, Hasre man gırgın xayir-düəbı yiğınbı ixhecen.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
Benyamin bahalne ümulyuk akar, Miç'eeb k'on givku opxhan, Exhalid ing'uke-şeng'uke g'ayşuyn bit'al ha'a.
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
İna ələpqı'na yits'ıq'öble nasıl İzrailyna vobna. Dekkee dixbışde gırgıng'us, cus sik'ına inəxübna xayir-düə huvu.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
Qiyğa Yaaq'ubee dixbışilqa əmr haa'a: – Zı sık'ınne gahıle qik'asda, zas yizde xizanısqa, zale ögee hapt'iynbışide k'anyaqa əlyhəəs ıkkan. Zı Q'etbışda eyxhene Efronne çoleene mağaree k'eyxhe.
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
Mana mağara Kana'anne ölkeene Mamrе eyhene cigays k'anene Maxpelayne çolee vobna. İbrahimee mana mağara nyaq'v haa'asdemee Efronusse çoluka sacigeeniy alivşu.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
Maa'abniy İbrahimiy cuna xhunaşşe Sarra, I'saq'iy cuna xhunaşşe Rivq'a k'evxhu. Zı Leayer maa'ar k'eyxhı.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Man çolud, maana mağarab Q'etbışisseniy alivşu.
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
Yaaq'ubee dixbışis əmr hav'u g'attirxhınmee, g'elybı tyuleeqa sı'ı qek'ana.

< Genesis 49 >