< Genesis 49 >

1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
Jakob je svojim sinovom zaklical in rekel: »Zberite se skupaj, da vam bom lahko povedal to, kar vas bo doletelo v poslednjih dneh.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
Zberite se skupaj in poslušajte, vi, Jakobovi sinovi in prisluhnite Izraelu, svojemu očetu.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Ruben, ti si moj prvorojenec, moja mogočnost in začetek moje moči, odličnost dostojanstva in odličnost moči,
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
nestabilen kakor voda, ti se ne boš odlikoval. Ker si odšel k postelji svojega očeta, takrat si jo omadeževal. Dvignil se je k mojemu ležišču.
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Simeon in Lévi sta brata, sredstva krutosti so v njunih prebivališčih.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Oh moja duša, ne pridi v njuno skrivnost, v njun zbor, moja čast, ne bodi združena, kajti v svoji jezi sta usmrtila človeka in v svoji svojevoljnosti sta spodkopala zid.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Prekleta bodi njuna jeza, kajti bila je kruta in njun srd, kajti bil je neizprosen. Razdelil ju bom v Jakobu in razkropil v Izraelu.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
Juda, ti si ta, ki ga bodo tvoji bratje hvalili. Tvoja roka bo na vratu tvojih sovražnikov, otroci tvojega očeta se bodo priklanjali pred teboj.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Juda je levji mladič. Od plena, moj sin, si se dvignil. Sklonil se je, ležal kakor lev in kakor star lev; kdo ga bo prebudil?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Žezlo ne bo odšlo od Juda niti palica zakona izmed njegovih stopal, dokler ne pride Šilo in k njemu bo zbiranje ljudstva.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
Privezujoč svojega oslička k trti in svojega osličjega žrebeta k izbrani trti, je svoje obleke opral v vinu in svoja oblačila v krvi grozdnih jagod.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Njegove oči bodo rdeče od vina in njegovi zobje beli od mleka.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
Zábulon bo prebival pri morskem zavetju in bo za zavetje ladjam in njegova meja bo do Sidóna.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
Isahár je močan osel, počivajoč med dvema bremenoma.
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
Videl je, da je bil počitek dober in da je bila dežela prijetna in sklonil svojo ramo, da prenaša in postal služabnik davku.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Dan bo sodil svoje ljudstvo kakor enega izmed Izraelovih rodov.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Dan bo kača ob poti, gad na stezi, ki piči konjska kopita, tako da bo njegov jezdec padel vznak.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
Pričakoval sem tvojo rešitev duše, oh Gospod.
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
Gad, krdelo ga bo premagalo, toda nazadnje bo on premagal.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
Iz Aserja bo njegov kruh zajeten in oskrboval bo kraljeve slaščice.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
Neftáli je spuščena košuta. On daje ljubke besede.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
Jožef je rodovitna veja, rodovitna veja pri vodnjaku, čigar mladike segajo preko zidu.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Lokostrelci so ga boleče užalostili, streljali nanj in ga sovražili.
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
Toda njegov lok je ostal v moči in lakti njegovih rok so bili okrepljeni z rokami mogočnega Jakobovega Boga (od tam je pastir, Izraelov kamen),
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
celó z Bogom svojih očetov, ki ti bo pomagal in z Vsemogočnim, ki te bo blagoslovil z blagoslovi z neba od zgoraj, blagoslovi iz globine, ki leži spodaj, blagoslovi prsi in maternice.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Blagoslovi tvojega očeta so prevladali nad blagoslovi mojih prednikov do skrajne meje večnih hribov. Ti bodo na Jožefovi glavi in na têmenu tistega, ki je bil ločen od svojih bratov.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
Benjamin bo ropal kakor volk. Zjutraj bo požrl plen, ponoči pa bo razdelil ukradeno blago.«
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
Vsi ti so dvanajsteri Izraelovi rodovi in to je to, kar jim je njihov oče govoril in jih blagoslovil; vsakega glede na svoj blagoslov jih je blagoslovil.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
Zapovedal jim je in jim rekel: »Jaz bom zbran k svojemu ljudstvu. Pokopljite me z mojimi očeti v votlini, ki je na polju Hetejca Efróna,
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
v votlini, ki je na polju Mahpéli, ki je pred Mamrejem, v kánaanski deželi, ki jo je Abraham kupil s poljem Hetejca Efróna za posest in grobišče.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
Tam so pokopali Abrahama in njegovo ženo Saro, tam so pokopali Izaka in njegovo ženo Rebeko, in tam sem pokopal Leo.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Nakup polja in votline, ki je na njem, je bil od Hetovih otrok.«
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ko je Jakob naredil konec zapovedovanju svojim sinovom, je svoja stopala dvignil v posteljo, izročil duha in bil zbran k svojemu ljudstvu.

< Genesis 49 >