< Genesis 49 >
1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
És szólítá Jákób az ő fiait, és monda: Gyűljetek egybe, hadd jelentsem meg néktek, a mi rátok következik a messze jövőben.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
Gyűljetek össze s hallgassatok Jákóbnak fiai! hallgassatok Izráelre, a ti atyátokra.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Rúben, te elsőszülöttem, erőm, tehetségem zsengéje, első a méltóságban, első a hatalomban.
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
Állhatatlan, mint a víz, nem leszesz első, mivel atyád ágyába léptél fel: akkor megfertőztetted! Nyoszolyámba lépett ő.
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Simeon és Lévi atyafiak, erőszak eszközei az ő fegyverök.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Tanácsukban ne légyen részes lelkem, gyűlésükkel ne egyesűljön dicsőségem, mert haragjokban férfit öltek, s kedvök telve inát szegték az ökörnek.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Átkozott haragjok, mert erőszakos, és dühök, mivel kegyetlen; eloszlatom őket Jákóbban, és elszélesztem Izráelben.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
Júda! téged magasztalnak atyádfiai, kezed ellenségeidnek nyakán lesz s meghajolnak előtted atyáidnak fiai.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Oroszlánkölyök Júda; zsákmányt ejtvén, felmentél, fiam! Lehevert, lenyúgodott, mint a hím oroszlán, és mint nőstény oroszlán; ki veri őt fel?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Nem múlik el Júdától a fejedelmi bot, sem a vezéri pálcza térdei közűl; míg eljő Siló, és a népek néki engednek.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
Szőlőtőhöz köti szamarát, és nemes venyigéhez szamara vemhét, ruháját borban mossa, felöltőjét a szőlő vérében.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Bortól veresek szemei, tejtől fehérek fogai.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
Zebulon a tenger partjáig lakozik, azaz a hajók kikötőjéig s határának széle Czídonig ér.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
Izsakhár erős csontú szamár, a karámok közt heverész.
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
S látja, hogy jó a nyugalom és hogy a föld mily kies: teher alá hajtja hátát, s robotoló szolgává lesz.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Dán ítéli az ő népét, mint Izráel akármelyik nemzetsége.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Dán kígyó lesz az úton, szarvaskígyó az ösvényen, mely a ló körmébe harap, hogy lovagja hanyatt esik.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
Szabadításodra várok Uram!
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
Gád! had háborgatja; majd ő hág annak sarkába.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
Ásernek kenyere kövér, királyi csemegét szolgáltat.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
Nafthali, gyorslábú szarvas, az ő beszéde kedves.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
Termékeny fa József, termő ág a forrás mellett, ágazata meghaladja a kőfalat.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Keserítik, lövöldözik és üldözik a nyilazók:
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
De mereven marad kézíve, feszülten keze karjai, Jákób Hatalmasának kezétől, onnan, Izráel pásztorától, kősziklájától.
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
Atyád Istenétől, a ki segéljen; a mindenhatótól, a ki megáldjon, az ég áldásaival, onnan felülről, a mélység áldásaival, mely alant terül, az emlők és anyaméh áldásaival.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Atyád áldásai meghaladják az ős hegyek áldásait, az örök halmok kiességeit. Szálljanak József fejére, a testvérek közűl kiválasztatottnak koponyájára.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
Benjámin ragadozó farkas: reggel ragadományt eszik, este pedig zsákmányt oszt.
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
Mind ezek Izráel nemzetségei, tizenketten, és ez az a mit mondott nékik az ő atyjok, mikor őket megáldá; mindeniket tulajdon áldásával áldá meg.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
És parancsola nékik és monda: Én az én népemhez takaríttatom, temessetek engem az én atyáimhoz, ama barlangba, mely a Khitteus Efron mezején van.
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
Abba a barlangba, mely Kanaán földén Mamré átellenében Makpelahnak mezején van, melyet megvett Ábrahám a mezővel együtt a Khitteus Efrontól, temetésre való örökségül.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
Oda temették el Ábrahámot és Sárát az ő feleségét; oda temették Izsákot és Rebekát az ő feleségét; s oda temettem el Leát is.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Szerzemény e mező és a barlang, mely abban van, a Khéth fiaitól.
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
És elvégezé Jákób a mit fiainak parancsolt és fölszedé lábait az ágyra, és kimúlék és az ő népéhez takaríttaték.