< Genesis 49 >

1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
És szólította Jákob az ő fiait és mondta: Gyűljetek egybe, hadd adom tudtotokra, mi ér benneteket a késő jövőben.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
Gyülekezzetek és halljátok Jákob fiai, hallgassatok Izraelre, a ti atyátokra.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Rúbén, elsőszülöttem vagy te, erőm és tehetségem zsengéje, első méltóságra, első hatalomra!
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
De túláradtál, mint a víz, ne légy első, mert fölszálltál atyád fekvőhelyére, akkor szentségtörő voltál bizony ágyamra szállt föl.
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Simon és Lévi testvérek, erőszakosság eszközei az ő fegyvereik.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Tanácsukba ne jusson lelkem, gyülekezetükkel ne egyesüljön becsületem; mert haragjukban embert öltek és önkényükben ökröt bénítottak.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Átkozott az ő haragjuk, mert hatalmas és fölgerjedésük, mert kegyetlen! Elosztom őket Jákobban és elszórom őket Izraelben.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
Júda te, téged dicsőítenek testvéreid – kezed ellenségeid nyakán! Előtted leborulnak atyád fiai.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Fiatal oroszlán Júda; zsákmánylásból jöttél fel fiam! Lehever, leterül, mint oroszlán és nőstény-oroszlán, ki kelti föl őt!
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Nem távozik a jogar Júdából és a törvény pálca lábai közül, míg nem eljön Silóba és az övé a népek hódolata.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
Odaköti a szőlőtőhöz csikaját, a venyigéhez szamarának vemhét; borban mossa öltözetét és szőlővérben ruháját.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Piros szemű a bortól, fehér fogú a tejtől.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
Zebúlun tengerek partján lakik, ő a hajók vénénél és oldala Cidónnál.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
Isszáchár csontos szamár, hever a cserények; között;
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
látta a nyugalmat, hogy jó és a földet, hogy kellemes, vállát hajtotta a teherhordásra és lett adófizető szolgává.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Dán ítél majd népe fölött, mint bármelyike Izrael törzseinek.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Dán kígyó lesz az úton, vipera az ösvényen, megmarja a ló sarkát, hogy hátrabukik lovasa.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
Segítségedet remélem; Örökkévaló.
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
Gád csapat csődül ellene, de ő sarkába csap.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
Asérnek kövér a kenyere és ő ad királyi csemegéket.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
Náftáli szabadjára eresztett szarvasünő; ő ad szép szózatokat.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
Termő sarjadék József, termő sarjadék a forrás mellett; sarjai felkúsztak a falra.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Azért keserítették, lövöldözték és gyűlölték a nyilasok,
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
de megmaradt mereven az íjja, megizmosodtak kezeinek karjai, Jákob hatalmasának kezétől, onnan, Izrael pásztorától, szirtjétől;
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
atyád Istenétől, aki megsegít téged, a Mindenhatótól, aki megáld téged, az egek áldásával felülről, a mélység áldásával, mely alant honol, az emlők és az anyaméh áldásával.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Atyád áldásai meghaladták az én szüleim áldásait, egész az örök halmok határáig, szálljanak József fejére, feje tetejére testvérei koszorúzottjának.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
Benjámin farkas, mely széjjelszaggat; reggel fölemészti a ragadmányt és este oszt zsákmányt.
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
Mindezek Izrael törzsei, tizenkettő és ez az, amit szólt hozzájuk atyjuk, midőn megáldotta őket; mindegyiket a maga áldása szerint áldotta meg.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
És megparancsolta nekik és mondta nekik: Én eltakaríttatom népemhez, temessetek el engem atyáim mellé a barlangba, mely Efrónnak, a chittinek mezejében van;
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
a barlangba, – mely Máchpéla mezejében, mely Mámré előtt van Kánaán országában – a melyet megvett Ábrahám mezőstül Efróntól, a chittitől sírnak való birtokul.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
Ott temették el Ábrahámot és Sárát, az ő feleségét, ott temették el Izsákot és Rebekát, az ő feleségét és oda temettem el Léát.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Megvett birtok a mező és a barlang, mely benne van, Chész fiaitól.
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
Midőn végzett Jákob azzal, hogy parancsot adjon fiainak, fölszedte lábait az ágyra; kimúlt és eltakaríttatott népéhez.

< Genesis 49 >