< Genesis 49 >
1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
Ningĩ Jakubu agĩtũmanĩra ariũ ake, akĩmeera atĩrĩ: “Cookanĩrĩrai haha nĩgeetha ndĩmwĩre ũrĩa gũgekĩka kũrĩ inyuĩ matukũ-inĩ marĩa magooka.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
“Ũnganai na mũthikĩrĩrie, inyuĩ ariũ a Jakubu; thikĩrĩriai Isiraeli ithe wanyu.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
“Rubeni, ũrĩ irigithathi rĩakwa, ũhoti wakwa, kĩonithania kĩa mbere kĩa hinya wakwa; ũkĩrĩte arĩa angĩ na gũtĩĩka, ũkamakĩra na hinya.
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
Wagagĩte ta maaĩ, na nĩ ũndũ ũcio ndũgũcooka gũkĩra arĩa angĩ, tondũ nĩwahaicire ũrĩrĩ wa thoguo, ũgĩthaahia ũrĩrĩ wakwa.
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
“Simeoni na Lawi nĩ a nyina ũmwe, hiũ ciao cia njora nĩ indo cia mbaara cia ũhinya.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Ngoro yakwa ndũkanatoonye ndundu-inĩ yao, ndũkananyiitane na kĩũngano kĩao, nĩgũkorwo nĩmooragĩte andũ marakarĩte, na magatemanga ndegwa magũrũ macithuithie o ũrĩa mangĩendire.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Marakara mao mahiũ mũno, na mangʼũrĩ mao matarĩ tha, maronyiitwo nĩ kĩrumi. Ngaamaharagania thĩinĩ wa Jakubu na ndĩmahurunjĩre thĩinĩ wa Isiraeli.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
“Juda, ariũ a thoguo nĩmagagũkumia; nakuo guoko gwaku nĩgũgatooria thũ ciaku; ariũ a thoguo nĩmagakũinamĩrĩra.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Juda, we ũrĩ kĩana kĩa mũrũũthi, mũrũ wakwa; we ũcookaga kuuma ũguĩmi-inĩ ũhũũnĩte ũguĩmi waku. O ta mũrũũthi-rĩ, ethunaga na agakoma thĩ, o ta mũrũũthi wa mũgoma-rĩ, nũũ ũngĩthĩgĩrĩria kũmwarahũra?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Rũthanju rwa ũthamaki rũtikoima harĩ Juda, o na kana rũthanju rwa ũnene rũthenge gatagatĩ-inĩ ka magũrũ make, o nginya agooka ũrĩa mwene ruo, o we ũrĩa ũgaathĩkagĩrwo nĩ thĩ.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
Akoohagĩrĩra ndigiri yake mũthabibũ-inĩ, nayo njaũ yake ya ndigiri amĩohagĩrĩre rũhonge-inĩ rũrĩa rwega mũno. Agaathambagia nguo ciake na ndibei, na kanjũ ciake na ũtune wa thabibũ.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Maitho make makaira gũkĩra ndibei, namo magego make merũhe gũkĩra iria.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
“Zebuluni agaatũũra hũgũrũrũ-inĩ cia iria, na atuĩke handũ hega ha gũikaragwo nĩ marikabu; mĩhaka yake ĩgaakinya o Sidoni.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
“Isakaru nĩ ndigiri ĩrĩa ĩrĩ hinya ĩkomete gatagatĩ ka mĩrigo ĩĩrĩ.
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
Rĩrĩa akoona ũrĩa ũhurũko wake ũrĩ mwega, na ũrĩa bũrũri wake wagĩrĩte-rĩ, no rĩo akainamĩrĩria kĩande gĩake akuue mĩrigo, na etĩkĩre kũruta wĩra ũtarĩ mũcaara.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
“Dani agaaciirĩrĩra andũ ake na kĩhooto, arĩ ta mũhĩrĩga ũmwe wa Isiraeli.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Dani agaatuĩka ta nyoka ĩrĩ mũkĩra-inĩ wa njĩra, atuĩke ta nduĩra ĩrĩ gacĩra-inĩ, ĩrĩa ĩrũmaga ndiira cia mbarathi, na tondũ ũcio mũmĩtwarithia akagũa na ngara.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
“Wee Jehova-rĩ, njetereire kũhonokania gwaku.
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
“Gadi nĩagatharĩkĩrwo nĩ ikundi cia atunyani, nowe nĩagacitharĩkĩra aciingatithie.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
“Irio cia Asheri nĩ cia kũguna mwĩrĩ; na akaaheanaga irio njega ingĩkenia mũthamaki.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
“Nafitali nĩ ta thiiya ya mũgoma ĩrekereirio, ĩrĩa ĩciaraga tũthiiya tũthaka.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
“Jusufu nĩ mũthabibũ ũrĩa ũciaraga, mũthabibũ ũrĩa ũciaraga ũrĩ hakuhĩ na gĩthima, ũrĩa honge ciaguo itambagĩrĩra rũthingo.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Aikia a mĩguĩ nĩmamũtharĩkĩire marĩ na marũrũ; makĩmũikĩria mĩguĩ marĩ na ũũru mũingĩ.
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
No ũta wake ndwenyenyekire, moko make marĩ hinya magĩikara merũmĩtie nĩ ũndũ wa guoko kwa Mwene-Hinya wa Jakubu, na nĩ ũndũ wa Mũrĩithi, o we Ihiga rĩa Isiraeli,
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
nĩ ũndũ wa Ngai wa thoguo, ũrĩa ũgũteithagia, na tondũ wa Mwene-Hinya-Wothe, ũrĩa ũkũrathimaga na irathimo cia igũrũ, na irathimo cia kũrĩa kũriku mũhuro wa thĩ, o na irathimo cia nyondo na cia nda.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Irathimo cia thoguo nĩ makĩria ma irathimo cia irĩma iria cia tene, na nĩ makĩria ma ũtonga wa tũrĩma tũrĩa tũkũrũ. Ici ciothe nĩirekwo ihurũke mũtwe-inĩ wa Jusufu, o thiithi-inĩ wa ũcio ũhaana ta mwana wa mũthamaki harĩ ariũ a ithe.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
“Benjamini ahaana ta njũũi ĩrĩa ngoroku; kĩroko-inĩ atambuuraga kĩrĩa aguĩmĩte, hwaĩ-inĩ akagayania kĩrĩa atahĩte.”
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
Ĩyo yothe nĩyo mĩhĩrĩga ĩrĩa ikũmi na ĩĩrĩ ya Isiraeli, na ũguo nĩguo ithe wao aameerire rĩrĩa aamarathimaga, akĩhe o mũndũ kĩrathimo kĩrĩa kĩamwagĩrĩire.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
Ningĩ Jakubu akĩmahe mawatho maya: “Ndĩ hakuhĩ gũkua. Mũgaathika harĩa maithe makwa mathikĩtwo, ngurunga-inĩ ĩrĩa ĩrĩ gĩthaka-inĩ kĩa Efironi ũrĩa Mũhiti,
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
ngurunga ĩrĩa ĩrĩ gĩthaka-inĩ kĩa Makipela hakuhĩ na Mamure kũu Kaanani, ĩrĩa Iburahĩmu aagũranĩirie na gĩthaka kĩu, ĩrĩ handũ ha gũthikana, kuuma kũrĩ Efironi ũrĩa Mũhiti.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
Hau nĩho Iburahĩmu na mũtumia wake Sara maathikirwo, na no ho Isaaka na Rebeka mũtumia wake maathikirwo, na no ho ndaathikire Lea.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Gĩthaka kĩu na ngurunga ĩyo ciagũrirwo kuuma kũrĩ Ahethi.”
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
Nake Jakubu aarĩkia kũhe ariũ ake ũhoro ũcio-rĩ, agĩthuna magũrũ make arĩ o gĩtanda-inĩ, agĩtuĩkana, agĩcookanĩrĩrio kũrĩ andũ ao arĩa maakuĩte.