< Genesis 49 >

1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
Jacob summoned all his sons, and said to them,
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
“Gather around me in order that I can tell you what will happen in the future. My sons, come and listen to me. I am your father, [Jacob, whom God named] Israel.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Reuben, you are my oldest son. You were born when I was young and energetic/strong. You are prouder and stronger than all the rest of my sons.
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
But you were as uncontrollable as a flood [SIM]. So now you will not be my most important son, because you climbed up onto my bed, and had sex with [MTY] my (concubine/slave who had become one of my wives). Your doing that caused me, your father, to have great shame.
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Simeon and Levi, you have both acted like criminals. You use your swords to act violently.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
I do not want to be with you when you make evil plans [DOU]. I do not want to join you in your meetings, because you killed people when you became very angry, and you (hamstrung/cut the tendons in the legs of) oxen just to (have fun/see them suffer).
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
God says, ‘I will (curse/cause bad things to happen to) them for being very angry, for acting very cruelly when they were very furious. I will scatter their descendants [MTY] throughout Israel land.’
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
Judah, your [older and younger] brothers will praise you. They will bow down before you, because you will thoroughly defeat [MTY] your enemies.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Judah is like a young lion [SIM] that has returned to its den satisfied after eating the animals that it has killed. He is like a lion that lies down and stretches out after eating; no one would dare to disturb it [RHQ].
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
There will always be a ruler [MTY] from the descendants of Judah [MTY]. Each one will hold a scepter/staff to show that he has authority as a king. He will do that until the one to whom the scepter belongs comes, the one to whom the nations will bring tribute and show that they will obey him.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
The grapevines of Judah’s descendants will produce grapes very abundantly. As a result, they will not object to tying their young donkeys to the grapevines in order that the donkeys can eat the leaves of the grapevines. [Wine will be very plentiful, with the result that] they could wash their cloaks in wine that is as red as blood [MET].
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Their eyes will be red because of [drinking too much] wine, but their teeth will be very white because of drinking much milk [from the cows].
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
Zebulun, your descendants will live by the seashore where there will be a safe harbor for ships. Their land will extend north as far as Sidon [city].
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
Issachar, your descendants will be like strong donkeys that are lying down on the ground between their loads, [so tired that they cannot get up]!
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
They will see that their resting place is good, and that the land pleases them very much. But they will bend their backs to carry heavy loads and be forced to work for others.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Dan, although your tribe will be small, their leaders will rule their people just like the leaders of other tribes of Israel will rule their people.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Your descendants will be like snakes at the side of a road, like poisonous snakes lying beside a path. They will strike the heels of horses that pass by, causing the riders to fall backwards [as the horses rear up on their hind legs].”
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
Then Jacob prayed, “Yahweh, I am waiting for you to rescue me [from my enemies].”
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
[Then Jacob continued telling his sons what would happen in the future. He said], “Gad, your tribe/descendants will be attacked by a group of bandits, but your tribe/descendants will pursue and attack them [MTY].
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
Asher, your descendants will eat good-tasting food; they will produce food that is delicious enough for kings to eat.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
Naphtali, your descendants will be like deer [MET] that are (free to/not tied down and can) run wherever they wish. They will give birth to children who are good-looking like (fawns/baby deer) [MET].
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
Joseph, you will have many descendants [MET]. Their children will be as many as the fruit on a vine near a spring of water, whose branches extend over a wall.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Their enemies will attack them fiercely, and shoot at them with bows and arrows and pursue them.
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
But they will hold their bows steady and their arms will remain strong, because of the power [MTY] of my mighty God, because of Yahweh who guides and provides for me [MET] like a shepherd guides and provides for his sheep. The people of Israel will [ask Yahweh to protect them], [like people hide under] a huge [overhanging] to be protected.
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
God, the one whom I worship, will help your descendants. God Almighty will bless them by sending them rain from the sky and by giving them water from deep/far below the ground. He will give them many cattle and children [MET] (OR, and their cattle will have many offspring).
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
The blessings that I want God to give you are great ones. They are greater than the blessings that come from the eternal mountains, greater than the ones that come from the everlasting hills. Joseph, I pray that these blessings will (be given to you/come upon your head), because you are the leader of your [older] brothers [and younger brother].
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
Benjamin, your descendants will be like [MET] vicious/fierce wolves: In the morning they will kill their enemies like a wolf devours (its prey/the animals that it has killed), and in the evening they will divide among their warriors the spoils that they seized from their enemies.”
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
Those twelve sons are the ancestors of the twelve tribes of Israel. That is what their father said to them as he blessed them, telling to each one words that were appropriate for him.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
Then Jacob said to his sons, “I will soon die. Bury my body where some of my ancestors are buried, in the cave that is in the field that was bought from Ephron, who belonged to the Heth people-group.
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
That field is in the Machpelah area, east of Mamre [town], in Canaan. My grandfather Abraham bought it from Ephron to use as a burial place.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
That is where they buried him and his wife Sarah. That is where they buried my father Isaac and his wife Rebekah. And that is where I buried my wife Leah.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
That field and the cave in it were bought from the Heth people-group; so that is where I want you to bury me.”
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
When Jacob finished giving those instructions to his sons, he lay down on his bed again. Then he died [IDM].

< Genesis 49 >