< Genesis 48 >

1 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ si, a wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ ń ṣàìsàn,” nítorí náà, ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì, Manase àti Efraimu lọ́wọ́ lọ pẹ̀lú rẹ̀.
Şi s-a întâmplat, după aceste lucruri, că i s-a spus lui Iosif: Iată, tatăl tău este bolnav; iar el a luat cu el pe cei doi fii ai săi, Manase şi Efraim.
2 Nígbà tí a sọ fún Jakọbu pé, “Josẹfu ọmọ rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,” Israẹli rọ́jú dìde jókòó lórí ibùsùn rẹ̀.
Şi i s-a spus lui Iacob, zicând: Iată, fiul tău, Iosif, vine la tine; şi Israel s-a întărit şi a şezut pe pat.
3 Jakọbu wí fún Josẹfu pé, “El-Ṣaddai, fi ara hàn mí ní Lusi ní ilẹ̀ Kenaani, níbẹ̀ ni ó sì ti súre fún mi.
Şi Iacob i-a spus lui Iosif: Dumnezeu cel Atotputernic mi s-a arătat la Luz, în ţara lui Canaan, şi m-a binecuvântat.
4 Ó sì wí fún mi pé, ‘Èmi yóò mú kí o bí sí i, ìwọ yóò sì pọ̀ sí i, èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ ní ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ohun ìní ayérayé.’
Şi mi-a spus: Iată, te voi face roditor şi te voi înmulţi şi voi face din tine o mulţime de popoare; şi voi da această ţară seminţei tale după tine ca stăpânire veşnică.
5 “Nítorí náà báyìí, àwọn ọmọ rẹ méjèèjì tí a bí fún ọ ní ilẹ̀ Ejibiti, kí èmi kí ó tó tọ̀ ọ́ wá ní ìhín, ni mo sọ di ọmọ mi fúnra mi. Manase àti Efraimu yóò jẹ́ tèmi gẹ́gẹ́ bí Reubeni àti Simeoni ti jẹ́ tèmi.
Şi acum cei doi fii ai tăi, Efraim şi Manase, care ţi s-au născut în ţara Egiptului înainte să vin la tine în Egipt, sunt ai mei; ca Ruben şi Simeon, vor fi ai mei.
6 Àwọn ọmọ mìíràn tí ìwọ bá bí lẹ́yìn wọn yóò jẹ́ ọmọ rẹ. Ní ilẹ̀ tí wọn yóò jogún, orúkọ arákùnrin wọn ni a ó máa fi pè wọ́n.
Şi urmaşii tăi, pe care îi naşti după ei, vor fi ai tăi şi vor fi chemaţi după numele fraţilor lor în moştenirea lor.
7 Bí mo ti ń padà láti Padani, Rakeli kú ní ọ̀nà nígbà tí ó ṣì wà ní ilẹ̀ Kenaani, èyí tó mú ìbànújẹ́ bá mi, níbi tí kò jìnnà sí Efrata. Nítorí náà èmí sì sin ín sí ẹ̀bá ọ̀nà tí ó lọ sí Efrata” (tí ṣe Bẹtilẹhẹmu).
Şi cât despre mine, când eu am venit din Padan, Rahela a murit lângă mine în ţara lui Canaan, pe cale, pe când nu era decât o bucată de drum până să ajungem la Efrata; şi eu am îngropat-o acolo, pe calea Efratei, care este Betleem.
8 Nígbà tí Israẹli rí àwọn ọmọ Josẹfu, ó béèrè wí pé, “Àwọn wo nìyí?”
Şi Israel a privit pe fiii lui Iosif şi a spus: Cine sunt aceştia?
9 Josẹfu fún baba rẹ̀ lésì pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi fún mi ní ìhín.” Nígbà náà ni Israẹli wí pé, “Kó wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi kí èmi kí ó ba à le súre fún wọn.”
Şi Iosif a spus tatălui său: Ei sunt fiii mei, pe care Dumnezeu mi i-a dat în acest loc. Iar el a spus: Adu-i la mine, te rog şi îi voi binecuvânta.
10 Báyìí, ojú Israẹli ti ń di bàìbàì nítorí ogbó, agbára káká sì ni ó fi ń ríran. Josẹfu sì kó àwọn ọmọ rẹ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, baba rẹ̀ fẹnukò wọ́n ni ẹnu, ó sì dì mọ́ wọn.
Acum ochii lui Israel erau slabi din cauza vârstei, aşa că nu putea vedea. Şi i-a adus aproape de el; şi i-a sărutat şi i-a îmbrăţişat.
11 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Èmi kò lérò rárá pé, mo tún le rí ojú rẹ mọ́ láéláé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tún fún mi ní àǹfààní, mo sì tún rí àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú.”
Şi Israel i-a spus lui Iosif: Nu mă gândisem să văd faţa ta; şi, iată, Dumnezeu mi-a arătat de asemenea sămânţa ta.
12 Nígbà náà ni Josẹfu kó àwọn ọmọ náà kúrò ní orí eékún baba rẹ̀, ó wólẹ̀, ó sì tẹríba.
Şi Iosif i-a scos dintre genunchii săi şi s-a prosternat el însuşi cu faţa lui la pământ.
13 Josẹfu sì mú àwọn méjèèjì, Efraimu ni o fi sí ọwọ́ ọ̀tún òun tìkára rẹ̀, èyí tí í ṣe ọwọ́ òsì fún Israẹli, ó sì fi Manase sí ọwọ́ òsì ara rẹ̀, èyí tí ó bọ́ sí ọwọ́ ọ̀tún Israẹli.
Şi Iosif i-a luat pe amândoi, pe Efraim în mâna sa dreaptă, spre mâna stângă a lui Israel, şi pe Manase în mâna sa stângă, spre mâna dreaptă a lui Israel, şi i-a apropiat de el.
14 Israẹli sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Efraimu lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàsé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Manase lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Manase ni àkọ́bí.
Şi Israel a întins mâna sa dreaptă şi a pus-o pe capul lui Efraim, care era mai tânăr, şi mâna sa stângă peste capul lui Manase, punând mâinile sale în mod voit astfel; fiindcă Manase era întâiul născut.
15 Nígbà náà ni ó súre fún Josẹfu wí pé, “Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba mi Abrahamu àti Isaaki rìn níwájú rẹ̀, Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbò mi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,
Şi a binecuvântat pe Iosif şi a spus: Dumnezeu, înaintea căruia părinţii mei, Avraam şi Isaac, au umblat, Dumnezeul care m-a hrănit cât a fost viaţa mea de lungă până în această zi,
16 Angẹli tí ó dá mi ní ìdè kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu, kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí. Kí a máa fi orúkọ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba mi Abrahamu àti Isaaki, kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ilẹ̀ ayé.”
Îngerul care m-a răscumpărat din tot răul, să binecuvânteze băieţii; şi numele meu să fie chemat peste ei şi numele părinţilor mei, Avraam şi Isaac; şi ei să devină o mulţime în mijlocul pământului.
17 Nígbà tí Josẹfu rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Efraimu lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Efraimu lọ sí orí Manase.
Şi când Iosif a văzut că tatăl său a pus mâna sa dreaptă peste capul lui Efraim, aceasta nu i-a plăcut; şi a apucat mâna tatălui său, să o mute de pe capul lui Efraim pe capul lui Manase.
18 Josẹfu wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”
Şi Iosif a spus tatălui său: Nu aşa tată, fiindcă acesta este întâiul născut; pune-ţi mâna dreaptă pe capul lui.
19 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú-ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.”
Dar tatăl său a refuzat şi a spus: Ştiu aceasta fiul meu, o ştiu, el de asemenea va deveni un popor şi el de asemenea va fi mare; dar cu adevărat, fratele lui mai tânăr va fi mai mare decât el şi sămânţa lui va deveni o mulţime de naţiuni.
20 Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé, “Ní orúkọ yín ni Israẹli yóò máa súre yìí pé, ‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Efraimu àti Manase.’” Ó sì gbé Efraimu gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ́n sí Manase.
Şi i-a binecuvântat în acea zi, spunând: În tine Israel va binecuvânta, zicând: Dumnezeu să te facă pe tine ca pe Efraim şi ca pe Manase; şi a aşezat pe Efraim înaintea lui Manase.
21 Nígbà náà ni Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Ọjọ́ ikú mi súnmọ́ etílé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò wà pẹ̀lú yín, yóò sì mú un yín padà sí ilẹ̀ àwọn baba yín.
Şi Israel i-a spus lui Iosif: Iată, eu mor; dar Dumnezeu va fi cu tine şi te va aduce din nou în ţara părinţilor tăi.
22 Pẹ̀lúpẹ̀lú èmi yóò fún ọ ní ìpín kan ju ti àwọn arákùnrin rẹ lọ. Ilẹ̀ tí mo fi idà àti ọ̀kọ̀ mi gbà lọ́wọ́ àwọn ará Amori.”
Mai mult, ţi-am dat o porţie mai mult decât fraţilor tăi, pe care i-am scos din mâna amoritului cu sabia mea şi cu arcul meu.

< Genesis 48 >