< Genesis 48 >

1 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ si, a wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ ń ṣàìsàn,” nítorí náà, ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì, Manase àti Efraimu lọ́wọ́ lọ pẹ̀lú rẹ̀.
És lőn ezek után, megmondák Józsefnek: Ímé a te atyád beteg; és elvivé magával az ő két fiát Manassét és Efraimot.
2 Nígbà tí a sọ fún Jakọbu pé, “Josẹfu ọmọ rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,” Israẹli rọ́jú dìde jókòó lórí ibùsùn rẹ̀.
És tudtára adák Jákóbnak, mondván: Ímé a te fiad József hozzád jő; és összeszedé erejét Izráel, s felüle az ágyon.
3 Jakọbu wí fún Josẹfu pé, “El-Ṣaddai, fi ara hàn mí ní Lusi ní ilẹ̀ Kenaani, níbẹ̀ ni ó sì ti súre fún mi.
És monda Jákób Józsefnek: A mindenható Isten megjelenék nékem Lúzban, a Kanaán földén, és megálda engem.
4 Ó sì wí fún mi pé, ‘Èmi yóò mú kí o bí sí i, ìwọ yóò sì pọ̀ sí i, èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ ní ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ohun ìní ayérayé.’
És monda nékem: Ímé én megszaporítlak és megsokasítlak és népek sokaságává teszlek téged, s ezt a földet te utánnad a te magodnak adom örök birtokul.
5 “Nítorí náà báyìí, àwọn ọmọ rẹ méjèèjì tí a bí fún ọ ní ilẹ̀ Ejibiti, kí èmi kí ó tó tọ̀ ọ́ wá ní ìhín, ni mo sọ di ọmọ mi fúnra mi. Manase àti Efraimu yóò jẹ́ tèmi gẹ́gẹ́ bí Reubeni àti Simeoni ti jẹ́ tèmi.
Most tehát a te két fiad, a kik néked Égyiptom földén annakelőtte születtek, hogy én hozzád jöttem vala Égyiptomba, az enyéim; Efraim és Manasse, akár csak Rúben és Simeon, az enyéim lesznek.
6 Àwọn ọmọ mìíràn tí ìwọ bá bí lẹ́yìn wọn yóò jẹ́ ọmọ rẹ. Ní ilẹ̀ tí wọn yóò jogún, orúkọ arákùnrin wọn ni a ó máa fi pè wọ́n.
Ama szülötteid pedig, kiket ő utánok nemzettél, tiéid lésznek, és az ő bátyjaik nevéről neveztessenek az ő örökségökben.
7 Bí mo ti ń padà láti Padani, Rakeli kú ní ọ̀nà nígbà tí ó ṣì wà ní ilẹ̀ Kenaani, èyí tó mú ìbànújẹ́ bá mi, níbi tí kò jìnnà sí Efrata. Nítorí náà èmí sì sin ín sí ẹ̀bá ọ̀nà tí ó lọ sí Efrata” (tí ṣe Bẹtilẹhẹmu).
Mert mikor Mésopotámiából jövék, meghala mellettem Rákhel Kanaán földén az úton, mikor még egy dűlőföldre valék Efratától, és eltemetém őt ott az Efratába (azaz Bethlehembe) vezető úton.
8 Nígbà tí Israẹli rí àwọn ọmọ Josẹfu, ó béèrè wí pé, “Àwọn wo nìyí?”
És meglátá Izráel a József fiait és monda: Kicsodák ezek?
9 Josẹfu fún baba rẹ̀ lésì pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi fún mi ní ìhín.” Nígbà náà ni Israẹli wí pé, “Kó wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi kí èmi kí ó ba à le súre fún wọn.”
József pedig monda az ő atyjának: Az én fiaim, kiket Isten itt adott nékem. És monda: Hozd ide őket hozzám, hadd áldjam meg.
10 Báyìí, ojú Israẹli ti ń di bàìbàì nítorí ogbó, agbára káká sì ni ó fi ń ríran. Josẹfu sì kó àwọn ọmọ rẹ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, baba rẹ̀ fẹnukò wọ́n ni ẹnu, ó sì dì mọ́ wọn.
Mert Izráelnek szemei meghomályosodának a vénség miatt, és nem láthat vala. Közel vivé tehát őket hozzá, ő pedig megcsókolgatá és megölelgeté őket.
11 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Èmi kò lérò rárá pé, mo tún le rí ojú rẹ mọ́ láéláé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tún fún mi ní àǹfààní, mo sì tún rí àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú.”
És monda Izráel Józsefnek: Nem gondoltam, hogy orczádat megláthassam, és íme az Isten megengedte látnom magodat is.
12 Nígbà náà ni Josẹfu kó àwọn ọmọ náà kúrò ní orí eékún baba rẹ̀, ó wólẹ̀, ó sì tẹríba.
Akkor kivevé József azokat az ő atyjának térdei közül, és leborula arczczal a földre.
13 Josẹfu sì mú àwọn méjèèjì, Efraimu ni o fi sí ọwọ́ ọ̀tún òun tìkára rẹ̀, èyí tí í ṣe ọwọ́ òsì fún Israẹli, ó sì fi Manase sí ọwọ́ òsì ara rẹ̀, èyí tí ó bọ́ sí ọwọ́ ọ̀tún Israẹli.
És fogá József mindkettejöket, Efraimot jobbkezével Izráel balkeze felől; Manassét pedig balkezével Izráelnek jobbkeze felől és közel vivé őket hozzá.
14 Israẹli sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Efraimu lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàsé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Manase lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Manase ni àkọ́bí.
Izráel pedig kinyujtá az ő jobbkezét és rátevé Efraim fejére, pedig ő a kisebbik vala, az ő balkezét pedig Manasse fejére. Tudva tevé így kezeit, mert az elsőszülött Manasse vala.
15 Nígbà náà ni ó súre fún Josẹfu wí pé, “Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba mi Abrahamu àti Isaaki rìn níwájú rẹ̀, Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbò mi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,
És megáldá Józsefet s monda: Az Isten, a kinek előtte jártak az én atyáim Ábrahám és Izsák; az Isten a ki gondomat viselte, a mióta vagyok, mind e napig:
16 Angẹli tí ó dá mi ní ìdè kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu, kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí. Kí a máa fi orúkọ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba mi Abrahamu àti Isaaki, kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ilẹ̀ ayé.”
Amaz Angyal, ki megszabadított engem minden gonosztól, áldja meg e gyermekeket, és viseljék az én nevemet és az én atyáimnak Ábrahámnak és Izsáknak nevét, és mint a halak szaporodjanak e földön.
17 Nígbà tí Josẹfu rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Efraimu lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Efraimu lọ sí orí Manase.
Látván pedig József, hogy az ő atyja jobbkezét Efraim fejére tevé, nem tetszék néki, és megfogá atyja kezét, hogy Efraim fejéről Manasse fejére tegye át.
18 Josẹfu wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”
És monda József az ő atyjának: Nem úgy atyám; mert ez az elsőszülött, ennek fejére tedd jobb kezedet.
19 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú-ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.”
Nem akará pedig az atyja és monda: Tudom fiam, tudom, ő is néppé lesz, ő is megnevekedik; de az ő öccse nálánál inkább megnevekedik, és az ő magja népek sokaságává lesz.
20 Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé, “Ní orúkọ yín ni Israẹli yóò máa súre yìí pé, ‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Efraimu àti Manase.’” Ó sì gbé Efraimu gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ́n sí Manase.
És megáldá őket azon a napon, mondván: Ha áld, téged említsen Izráel, mondván: Az Isten téged olyanná tégyen mint Efraimot s Manassét. És Efraimot eleibe tevé Manassénak.
21 Nígbà náà ni Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Ọjọ́ ikú mi súnmọ́ etílé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò wà pẹ̀lú yín, yóò sì mú un yín padà sí ilẹ̀ àwọn baba yín.
És mondá Izráel Józsefnek: Ímé én meghalok, de az Isten veletek lesz és vissza visz titeket a ti atyáitok földére.
22 Pẹ̀lúpẹ̀lú èmi yóò fún ọ ní ìpín kan ju ti àwọn arákùnrin rẹ lọ. Ilẹ̀ tí mo fi idà àti ọ̀kọ̀ mi gbà lọ́wọ́ àwọn ará Amori.”
Én pedig adok néked egy osztályrészt a te atyádfiainak része felett, melyet az Emoreustól vettem fegyveremmel és kézívemmel.

< Genesis 48 >