< Genesis 47 >

1 Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.”
Пришед же Иосиф, поведа фараону глаголя: отец мой и братия моя, и скоти и волове их, и вся сущая их приидоша из земли Ханаани: и се, суть в земли Гесем.
2 Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.
От братий же своих поя пять мужей и постави их пред фараоном.
3 Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?” Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran.”
И рече фараон к братиям Иосифовым: что дело ваше? Они же реша фараону: пастуси овчии, раби твои, и мы и отцы наши отдетска и доселе.
4 Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”
Рекоша же фараону: обитати в земли приидохом, несть бо пажити скотом раб твоих: одоле бо глад на земли Ханаани: ныне убо да вселимся раби твои в земли Гесем.
5 Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,
И рече фараон Иосифу, глаголя: отец твой и братия твоя приидоша к тебе:
6 ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ, mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”
се, земля Египетская пред тобою есть: на лучшей земли посели отца твоего и братию твою, да вселятся в земли Гесем: аще же веси, яко суть в них мужие сильнии, постави их старейшины скотом моим. (приидоша же во Египет ко Иосифу Иаков и сынове его: и услыша фараон царь Египетский).
7 Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán.
Введе же Иосиф Иакова отца своего и постави его пред фараоном, и благослови Иаков фараона.
8 Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”
Рече же фараон ко Иакову: колико лет дний жития твоего?
9 Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje, ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”
И рече Иаков фараону: дние лет жития моего, яже обитаю, сто тридесять лет: малы и злы быша дние лет жития моего: не достигоша во дни лет жития отец моих, яже дни обиташа.
10 Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.
И благословив Иаков фараона, отиде от него.
11 Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ.
И всели Иосиф отца своего и братию свою, и даде им обдержание в земли Египетстей, на лучшей земли, в земли Рамессийстей, якоже повеле фараон.
12 Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.
И деляше Иосиф пшеницу отцу своему и братии своей и всему дому отца своего по числу лиц.
13 Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà.
Пшеницы же не бяше во всей земли, одоле бо глад зело: скончавашеся же земля Египетская и земля Ханааня от глада.
14 Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao.
Собра же Иосиф все сребро обретшееся в земли Египетстей и в земли Ханаани, за пшеницу, юже куповаху, и размеряше им пшеницу, и внесе Иосиф все сребро в дом фараонов.
15 Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”
И оскуде все сребро от земли Египетския и от земли Ханаанския: приидоша же вси Египтяне ко Иосифу, глаголюще: даждь нам хлебы, и вскую умираем пред тобою? Скончася бо сребро наше.
16 Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”
Рече же им Иосиф: пригоните скоты вашя, и дам вам хлебы за скоты вашя, аще скончася сребро ваше.
17 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.
Пригнаша же скоты своя ко Иосифу, и даде им Иосиф хлебы за кони и за овцы, и за волы и за ослы, и прекорми их хлебами за вся скоты их в том лете.
18 Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa.
Прейде же то лето, и приидоша к нему во второе лето и рекоша ему: да не како погибнем от господина нашего? Аще бо скончася сребро наше, и имение и скоты пред тобою, господине, и не остася нам пред господином нашим, точию едино тело и земля наша:
19 Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”
да не умрем убо пред тобою, и земля опустеет, купи нас и землю нашу хлебами: и будем мы и земля наша раби фараону: даждь семя, да посеем и живи будем, и не умрем, и земля не опустеет.
20 Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao,
И купи Иосиф всю землю Египетскую фараону: продаша бо Египтяне землю свою фараону, ибо одоле им глад: и бысть земля фараону.
21 Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì.
И люди поработи ему в рабы, от края предел Египетских даже до краев,
22 Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.
кроме земли жреческия токмо, тоя бо не купи Иосиф: даянием бо даде в дар жерцем фараон, и ядяху даяние, еже даде им фараон: сего ради не продаша земли своея.
23 Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà.
Рече же Иосиф всем Египтяном: се, купих вас и землю вашу днесь фараону: возмите себе семена и сейте на земли:
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”
и будут плоды ея, и да дасте пятую часть фараону, четыри же части будут вам самем в семена земли и на препитание вам и всем сущым в домех ваших.
25 Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”
И рекоша: оживил ны еси, обретохом благодать пред господином нашим, и будем раби фараону.
26 Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.
И устави им Иосиф заповедь даже до сего дне на земли Египетстей пятую часть даяти фараону, кроме земли жреческия: та точию не бяше фараоня.
27 Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.
Вселися же Израиль в земли Египетстей, на земли Гесем, и наследствоваше ю: и возрастоша, и умножишася зело.
28 Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tàdínlógún iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹẹ́tàdínlàádọ́jọ.
Поживе же Иаков в земли Египетстей седмьнадесять лет: и быша дние Иаковли лет жизни его, сто четыредесять седмь лет.
29 Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti.
Приближишася же дние Израилю еже умрети, и призва сына своего Иосифа и рече ему: аще обретох благодать пред тобою, подложи руку твою под стегно мое и сотвориши надо мною милость и истину, еже не погребсти мене во Египте,
30 Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.” Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”
но да почию со отцы моими: и изнесеши мя из Египта, и погребеши мя во гробе их. Он же рече: аз сотворю по словеси твоему.
31 Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.
Рече же: кленися мне. И клятся ему. И поклонися Израиль на конец жезла его.

< Genesis 47 >