< Genesis 47 >

1 Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.”
Atunci Iosif a venit şi i-a povestit lui Faraon şi a spus: Tatăl meu şi fraţii mei şi turmele lor şi cirezile lor şi tot ce au ei, au ieşit din ţara lui Canaan; şi, iată, ei sunt în ţinutul Gosen.
2 Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.
Şi a luat pe câţiva dintre fraţii săi, cinci bărbaţi, şi i-a prezentat înaintea lui Faraon.
3 Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?” Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran.”
Şi Faraon a spus fraţilor lui: Care este ocupaţia voastră? Iar ei i-au spus lui Faraon: Servitorii tăi sunt păstori, deopotrivă noi şi părinţii noştri.
4 Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”
Ei i-au mai spus lui Faraon: Noi am venit pentru a locui temporar în ţară; fiindcă servitorii tăi nu au păşune pentru turmele lor, pentru că foametea este aspră în ţara lui Canaan; acum de aceea, te rugăm, lasă pe servitorii tăi să locuiască în ţinutul Gosen.
5 Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,
Şi Faraon i-a vorbit lui Iosif, spunând: Tatăl tău şi fraţii tăi au venit la tine;
6 ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ, mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”
Ţara Egiptului este înaintea ta; în cea mai bună parte a ţării aşază pe tatăl tău şi pe fraţii tăi să locuiască; în ţinutul Gosen să locuiască; şi dacă tu cunoşti pe unii bărbaţi capabili printre ei, atunci pune-i conducători peste vitele mele.
7 Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán.
Şi Iosif a adus pe Iacob, tatăl său, şi l-a pus înaintea lui Faraon; şi Iacob a binecuvântat pe Faraon.
8 Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”
Şi Faraon i-a spus lui Iacob: Câte sunt zilele anilor vieţii tale?
9 Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje, ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”
Şi Iacob i-a spus lui Faraon: Zilele anilor călătoriei mele sunt o sută treizeci de ani; puţine şi rele au fost zilele anilor vieţii mele şi nu au ajuns la zilele anilor vieţii părinţilor mei în zilele călătoriei lor.
10 Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.
Şi Iacob a binecuvântat pe Faraon şi a ieşit dinaintea lui Faraon.
11 Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ.
Şi Iosif a aşezat pe tatăl său şi pe fraţii săi şi le-a dat o stăpânire în ţara Egiptului, în cea mai bună parte a ţării, în ţinutul Ramses, aşa cum Faraon poruncise.
12 Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.
Şi Iosif a hrănit pe tatăl său şi pe fraţii săi şi toată casa tatălui său, cu pâine, conform cu familiile lor.
13 Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà.
Şi nu era pâine în toată ţara, pentru că foametea era foarte aspră, aşa că toată ţara Egiptului şi toată ţara lui Canaan leşina din cauza foametei.
14 Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao.
Şi Iosif a adunat toţi banii care s-au găsit în ţara Egiptului şi în ţara lui Canaan, pentru grânele pe care le-au cumpărat; şi Iosif a adus banii în casa lui Faraon.
15 Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”
Şi când s-au terminat banii din ţara Egiptului şi din ţara lui Canaan, toţi egiptenii au venit la Iosif şi au spus: Dă-ne pâine, pentru ce să murim în faţa ta? Pentru că banii s-au terminat.
16 Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”
Şi Iosif a spus: Daţi vitele voastre; şi vă voi da pentru vitele voastre, dacă banii s-au terminat.
17 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.
Şi au adus vitele lor la Iosif; şi Iosif le-a dat pâine în schimb pentru cai şi pentru turme şi pentru vitele cirezilor şi pentru măgari; şi i-a hrănit pe ei cu pâine pentru toate vitele lor în acel an.
18 Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa.
Când acel an s-a terminat, ei au venit la el în al doilea an şi i-au spus: Noi nu vom ascunde aceasta faţă de domnul nostru, cum că banii noştri s-au terminat; domnul nostru are de asemenea cirezile noastre de vite; nu este nimic rămas înaintea domnului nostru decât trupurile noastre şi pământurile noastre;
19 Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”
Pentru ce să murim înaintea ochilor tăi, deopotrivă noi şi ţara noastră? Cumpără-ne pe noi şi pământul nostru pentru pâine şi noi şi pământul nostru vom fi servitori lui Faraon; şi dă-ne sămânţă, ca noi să trăim şi să nu murim, ca ţara să nu fie pustiită.
20 Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao,
Şi Iosif a cumpărat toată ţara Egiptului pentru Faraon; fiindcă egiptenii au vândut, fiecare bărbat câmpul său, pentru că îi cuprinsese foametea; aşa că ţara a devenit a lui Faraon.
21 Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì.
Şi cât despre popor, i-a mutat în cetăţi de la un capăt al graniţelor Egiptului chiar până la celălalt capăt al lui.
22 Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.
Numai pământul preoţilor nu l-a cumpărat; fiindcă preoţii aveau o porţie atribuită lor de Faraon şi mâncau porţia lor pe care Faraon le-a dat-o; din această cauză nu şi-au vândut pământurile.
23 Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà.
Atunci Iosif a spus poporului: Iată, v-am cumpărat astăzi pe voi şi pământul vostru pentru Faraon; iată, aici este sămânţă pentru voi şi veţi semăna pământul.
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”
Şi se va întâmpla la timpul roadelor, că voi veţi da a cincea parte lui Faraon şi patru părţi vor fi ale voastre, pentru sămânţa câmpului şi pentru mâncarea voastră şi pentru cei ai caselor voastre şi pentru mâncare pentru micuţii voştri.
25 Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”
Iar ei au spus: Tu ai salvat vieţile noastre; să găsim har înaintea ochilor domnului meu şi vom fi servitorii lui Faraon.
26 Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.
Şi Iosif a făcut aceasta o lege peste ţara Egiptului până în această zi, că Faraon va avea a cincea parte; cu excepţia numai a pământului preoţilor, care nu a devenit al lui Faraon.
27 Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.
Şi Israel a locuit în ţara Egiptului, în ţinutul Gosen; şi aveau stăpâniri acolo şi au crescut şi s-au înmulţit peste măsură.
28 Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tàdínlógún iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹẹ́tàdínlàádọ́jọ.
Şi Iacob a trăit în ţara Egiptului şaptesprezece ani, aşa că toate zilele vieţii lui Iacob au fost o sută patruzeci şi şapte de ani.
29 Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti.
Şi s-au apropiat zilele lui Israel ca să moară; şi a chemat pe fiul său, Iosif, şi i-a spus: Dacă eu acum am găsit har înaintea ochilor tăi, pune-ţi, te rog, mâna sub coapsa mea şi lucrează cu bunăvoinţă şi credincioşie faţă de mine; nu mă îngropa, te rog, în Egipt,
30 Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.” Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”
Ci mă voi culca cu părinţii mei şi tu mă vei duce din Egipt şi mă vei îngropa în locul lor de îngropare. Iar el a spus: Voi face precum ai spus.
31 Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.
Iar el a spus: Jură-mi. Şi el i-a jurat. Şi Israel s-a aplecat pe capul patului.

< Genesis 47 >