< Genesis 47 >
1 Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.”
Józef więc przyszedł i powiedział faraonowi: Mój ojciec i moi bracia ze swymi owcami, wołami i ze wszystkim, co mają, przybyli z ziemi Kanaan; oto są w ziemi Goszen.
2 Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.
A spośród swych braci wziął pięciu mężczyzn i przedstawił ich faraonowi.
3 Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?” Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran.”
I faraon zapytał jego braci: Czym się zajmujecie? A [oni] odpowiedzieli faraonowi: Twoi słudzy [są] pasterzami, my i nasi ojcowie.
4 Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”
Powiedzieli jeszcze do faraona: Przyszliśmy, aby przebywać w tej ziemi, bo nie ma paszy dla stad, które [mają] twoi słudzy, gdyż ciężki głód [panuje] w ziemi Kanaan. Teraz prosimy, pozwól, aby twoi słudzy mieszkali w ziemi Goszen.
5 Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,
Wtedy faraon powiedział do Józefa: Twój ojciec i twoi bracia przybyli do ciebie.
6 ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ, mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”
Ziemia Egiptu jest przed tobą. W najlepszym [miejscu] tej ziemi osadź twego ojca i twoich braci, niech mieszkają w ziemi Goszen. A jeśli wiesz, że są wśród nich dzielni ludzie, uczyń ich przełożonymi nad moimi stadami.
7 Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán.
I Józef przyprowadził swego ojca Jakuba, i postawił go przed faraonem. A Jakub błogosławił faraona.
8 Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”
Faraon zapytał Jakuba: Ile lat życia sobie liczysz?
9 Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje, ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”
Jakub odpowiedział faraonowi: Liczba lat mego pielgrzymowania to sto trzydzieści. Krótkie i złe były lata mego życia i nie osiągnąłem wieku moich ojców podczas ich pielgrzymowania.
10 Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.
Potem Jakub pobłogosławił faraona i odszedł sprzed jego oblicza.
11 Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ.
Wtedy Józef osiedlił swego ojca i swoich braci i dał im posiadłość w ziemi Egiptu, w najlepszym [miejscu] tej krainy, w ziemi Ramses, jak rozkazał faraon.
12 Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.
I Józef żywił chlebem swego ojca i swoich braci, i cały dom swego ojca, aż do najmniejszego.
13 Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà.
A w całej ziemi nie [było] chleba, bo panował bardzo ciężki głód i była utrapiona przez głód ziemia Egiptu i ziemia Kanaan.
14 Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao.
Józef zebrał więc wszystkie pieniądze, które znajdowały się w ziemi Egiptu i w ziemi Kanaan, za żywność, którą kupowano. I Józef wniósł te pieniądze do skarbu faraona.
15 Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”
A gdy zabrakło pieniędzy w ziemi Egiptu i w ziemi Kanaan, wszyscy Egipcjanie przyszli do Józefa i powiedzieli: Daj nam chleba. Dlaczego mamy umierać na twoich oczach? Gdyż nam już zabrakło pieniędzy.
16 Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”
Józef na to odpowiedział: Dajcie wasze bydła, a dam wam [żywność] za wasze bydła, skoro zabrakło [wam] pieniędzy.
17 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.
Przyprowadzili więc swoje bydła do Józefa; i Józef dał im chleb za konie, za trzody owiec, za stada wołów i za osły. W tym roku zaopatrywał ich w żywność w zamian za wszelkie ich bydło.
18 Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa.
A gdy minął ten rok, przyszli do niego w następnym roku i powiedzieli: Nie ukryjemy przed naszym panem, że już skończyły się nam pieniądze, a stada bydła [należą] do naszego pana. Nie zostaje [nam] nic przed naszym panem jak tylko nasze ciała i nasze pole.
19 Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”
Dlaczego mamy umierać na twoich oczach, zarówno my, jak i nasza ziemia? Kupuj za chleb nas i nasze pole, a my i nasza ziemia będziemy w niewoli u faraona. Daj [nam] tylko ziarno, abyśmy żyli, a nie pomarli, i by ziemia nie opustoszała.
20 Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao,
I tak kupił Józef [całą] ziemię Egiptu dla faraona, bo każdy Egipcjanin sprzedał swoje pole, gdyż wzmógł się wśród nich głód. I cała ziemia stała się [własnością] faraona.
21 Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì.
I przeniósł lud do miast, od jednego krańca Egiptu do drugiego.
22 Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.
Nie kupił tylko ziemi kapłanów, bo kapłani mieli [żywność] przydzieloną im przez faraona i żywili się swoją żywnością, którą dał im faraon. Dlatego nie sprzedali swej ziemi.
23 Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà.
Potem Józef powiedział do ludu: Oto teraz kupiłem was i waszą ziemię dla faraona. Macie tu ziarno, obsiejcie nim pola.
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”
A piątą część [waszych] plonów oddacie faraonowi, cztery zaś części będą wasze – na obsianie pól i na żywność dla tych, którzy są w waszych domach, i na żywność [dla] waszych dzieci.
25 Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”
Wtedy odpowiedzieli: Uratowałeś nam życie! Obyśmy znaleźli łaskę w oczach swego pana, a będziemy niewolnikami faraona.
26 Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.
I Józef ustanowił to jako prawo aż do dziś w ziemi Egiptu, aby faraonowi [oddawano] piątą część [plonów]. Tylko ziemia samych kapłanów nie stała się [własnością] faraona.
27 Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.
Izrael mieszkał w ziemi Egiptu, w ziemi Goszen. Nabywali w niej posiadłości na własność, byli płodni i bardzo się rozmnożyli.
28 Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tàdínlógún iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹẹ́tàdínlàádọ́jọ.
I Jakub żył w ziemi Egiptu siedemnaście lat. A w sumie Jakub przeżył sto czterdzieści siedem lat.
29 Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti.
I zbliżył się czas śmierci Izraela. Wezwał więc swego syna Józefa i powiedział do niego: Jeśli teraz znalazłem łaskę w twoich oczach, połóż, proszę, twoją rękę pod moje biodro, a wyświadcz mi tę łaskę i wierność: Proszę, nie chowaj mnie w Egipcie;
30 Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.” Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”
Ale [gdy] zasnę z moimi ojcami, wywieziesz mnie z Egiptu i pochowasz mnie w ich grobie. A on powiedział: Uczynię według twego słowa.
31 Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.
A [Jakub] powiedział: Przysięgnij mi. I przysiągł mu. Potem Izrael pokłonił się na wezgłowie łoża.