< Genesis 47 >

1 Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.”
Na ka haere a Hohepa, ka korero ki a Parao, ka mea, Kua tae mai toku papa me oku tuakana, me a ratou kahui, a ratou kau, a ratou mea katoa, i te whenua o Kanaana; na, kei te whenua ratou o Kohena.
2 Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.
Na ka tango ia i etahi o ona tuakana, tokorima, a whakaturia ana ratou e ia ki te aroaro o Parao.
3 Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?” Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran.”
A ka mea a Parao ki ona tuakana, He aha ta koutou na mahi? A ka mea ratou ki a Parao, He hepara au pononga, matou me o matou matua.
4 Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”
I mea ano ratou ki a Parao, He noho ki tenei whenua i haere mai ai matou; no te mea kahore he kai ma nga hipi a au pononga; he nui hoki te matekai o te whenua o Kanaana: koia ra kia noho au pononga ki te whenua o Kohena.
5 Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,
Na ka korero a Parao ki a Hohepa, ka mea, Kua tae mai nei tou papa me ou tuakana ki a koe:
6 ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ, mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”
Kei tou aroaro te whenua o Ihipa; whakanohoia e koe tou papa me ou tuakana ki te wahi pai o te whenua; kia noho ratou ki te whenua o Kohena: ki te mea hoki e mohiotia ana e koe etahi tangata pakari i roto i a ratou, meinga ratou hei rangatira mo aku kararehe.
7 Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán.
Na ka kawea mai a Hakopa, tona papa, e Hohepa, ka whakaturia ki te aroaro o Parao; a ka manaaki a Hakopa i a Parao.
8 Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”
A ka mea a Parao ki a Hakopa, Ka hia ou tau?
9 Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje, ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”
Ka mea a Hakopa ki a Parao, Ka kotahi rau e toru tekau tau nga ra o nga tau o toku noho manene: he torutoru, a he kino nga ra o nga tau o toku ora, kihai ano hoki i rite ki nga ra o nga tau o te ora o oku matua, i nga ra i noho manene ai ratou.
10 Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.
Na ka manaaki a Hakopa i a Parao, a puta atu ana i te aroaro o Parao.
11 Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ.
Na ka whakanohoia e Hohepa tona papa me ona tuakana, a hoatu ana e ia ki a ratou he kainga i te whenua o Ihipa, i te wahi pai rawa o te whenua, i te whenua o Ramehehe, pera me ta Parao i whakahau ai.
12 Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.
Na ka atawhai a Hohepa i tona papa, ratou ko ona tuakana, ko te whare katoa ano hoki o tona papa ki te taro, he mea whakarite tonu ki o ratou hapu.
13 Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà.
A kahore he taro o te whenua katoa; he nui rawa hoki te matekai; a hemo noa iho te whenua o Ihipa i te matekai, me te whenua hoki o Kanaana.
14 Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao.
A kohia ana e Hohepa te moni katoa i kitea ki te whenua o Ihipa, ki te whenua hoki o Kanaana, mo te witi i hokona e ratou: a kawea ana e Hohepa te moni ki te whare o Parao.
15 Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”
A, no te potonga o te moni o te whenua o Ihipa, o te whenua hoki o Kanaana, na ka haere nga Ihipiana katoa ki a Hohepa, ka mea, Homai he taro ki a matou: kia mate hoki matou ki tou aroaro hei aha? kua poto nei hoki te moni.
16 Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”
Na ka mea a Hohepa, Homai a koutou kararehe; a ka hoatu e ahau hei utu mo a koutou kararehe, i te mea kua poto te moni.
17 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.
Na ka kawea mai e ratou a ratou kararehe ki a Hohepa: a hoatu ana e Hohepa he taro ki a ratou hei utu mo nga hoiho, mo nga kahui hipi, mo nga kahui kau, mo nga kaihe: a whangaia ana ratou e ia ki te taro i taua tau, hei utu mo a ratou kararehe k atoa.
18 Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa.
A, no te takanga o taua tau, ka haere mai ratou ki a ia i te rua o nga tau, ka mea ki a ia, E kore e huna e matou i toku ariki, kua poto te moni; kei toku ariki hoki a matou kahui kararehe; kahore he mea e toe ana hei tirohanga ma toku ariki, ko o matou tinana anake, me o matou oneone:
19 Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”
Kia mate matou ki tou aroaro hei aha? matou tahi hoki me to matou oneone? hokona matou me to matou oneone ki te taro, a ka riro matou me to matou oneone hei pononga ma Parao: homai ano hoki he purapura, a ka ora matou, a e kore e mate, e kore an o hoki e ururuatia te whenua.
20 Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao,
Na ka hokona e Hohepa te oneone katoa o Ihipa mo Parao: i hokona hoki e nga Ihipiana tana mara, tana mara; he pehi rawa hoki na te matekai i a ratou: a riro ana te whenua i a Parao.
21 Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì.
Tena ko nga tangata, i whakawhitiwhitia e ia ki nga pa, i tetahi pito o nga rohe o Ihipa a puta noa ki tetahi pito o reira.
22 Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.
Ko te oneone anake ia o nga tohunga kihai i hokona e ia; i whakaritea hoki tetahi wahi e Parao ma nga tohunga, a i kai ratou i ta ratou wahi i homai e Parao ma ratou: koia te hokona ai e ratou o ratou oneone.
23 Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà.
A ka mea a Hohepa ki te iwi, Nana, kua hokona nei koutou e ahau inaianei, me to koutou oneone, ma Parao: na, he purapura ma koutou, ruia te whenua.
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”
A, ka whai hua a mua, me homai e koutou te rima o nga wahi ki a Parao, a ma koutou nga wahi e wha, hei purapura mo te mara, hei kai hoki ma koutou, ma te hunga hoki i roto i o koutou whare, hei kai ano hoki ma a koutou tamariki.
25 Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”
A ka mea ratou, Ka ora matou i a koe: kia manakohia matou e toku ariki, hei pononga matou ma Parao.
26 Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.
Na ka whakatakotoria te tikanga e Hohepa mo te oneone o Ihipa a tae noa mai ki tenei ra, ma Parao te rima o nga wahi; haunga ia te oneone o nga tohunga, kihai hoki tena i riro i a Parao.
27 Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.
Na ka noho a Iharaira ki te whenua o Ihipa, ki te whenua o Kohena; ka whai kainga ratou ki reira, ka hua, ka nui whakaharahara.
28 Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tàdínlógún iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹẹ́tàdínlàádọ́jọ.
A kotahi tekau ma whitu nga tau i ora ai a Hakopa ki te whenua o Ihipa: a kotahi rau e wha tekau ma whitu nga tau o te oranga o Hakopa.
29 Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti.
Na ka whakatata nga ra o Iharaira e mate ai ia: a ka karanga i tana tama, i a Hohepa, ka mea ki a ia, Na, ki te mea ka manakohia ahau e koe, tena, whakapakia mai tou ringa ki raro i toku huha, a whakaputaina mai he aroha, he pono ki ahau; kaua r a ahau e tanumia ki Ihipa:
30 Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.” Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”
Engari kia takoto ahau ki oku matua, me kawe atu ahau e koe i Ihipa, me tanu hoki ki to ratou urupa. A ka mea ia, Ka rite i ahau tau kupu.
31 Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.
A ka mea ia ki a ia, Oati mai ki ahau. A oati ana ia ki a ia. A ka pike a Iharaira ki runga ki te urunga o te moenga.

< Genesis 47 >