< Genesis 47 >
1 Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.”
Elméne azért József és tudtára adá a Faraónak, és monda: Az én atyám és atyámfiai, juhaikkal, barmaikkal és mindenökkel valamijök volt, ide jöttek Kanaán földéről; és most Gósen földén vannak.
2 Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.
És vőn ötöt az ő testvérei közűl, és állítá őket a Faraó elé.
3 Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?” Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran.”
És monda a Faraó a József testvéreinek: Mi a ti életmódotok? És mondának a Faraónak: Juhpásztorok a te szolgáid, mi is, mint a mi atyáink.
4 Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”
És mondának a Faraónak: Azért jöttünk, hogy e földön tartózkodjunk, mert a te szolgáid barmainak nincs legelője, mivelhogy elhatalmazott az éhség Kanaán földén: hadd lakjanak azért most a te szolgáid Gósen földén.
5 Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,
És szóla a Faraó Józsefnek, mondván: A te atyád és a te atyádfiai jöttek te hozzád.
6 ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ, mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”
Égyiptom földe ímé előtted van; e föld legjobb részében telepítsd le a te atyádat és atyádfiait, lakozzanak a Gósen földén: ha pedig tudod, hogy vannak közöttök arra termett emberek, tedd azokat az én barmaim gondviselőivé.
7 Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán.
Bevivé József Jákóbot is az ő atyját, és állítá őt a Faraó elé. És köszönté Jákób a Faraót.
8 Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”
És monda a Faraó Jákóbnak: Hány esztendős vagy?
9 Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje, ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”
Monda pedig Jákób a Faraónak: Az én bujdosásom esztendeinek napjai száz harmincz esztendő; kevesek és nyomorúságosak voltak az én életem esztendeinek napjai, és nem érték el az én atyáim élete esztendeinek napjait, a meddig ők bujdostak.
10 Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.
És megáldá Jákób a Faraót, és kiméne a Faraó elől.
11 Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ.
Megtelepíté tehát József az ő atyját és atyjafiait, és ada nékik birtokot Égyiptom földén, annak a földnek legjobb részében a Rameszesz földén; a mint megparancsolta vala a Faraó.
12 Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.
És ellátja vala József az ő atyját és atyjafiait, és az ő atyjának egész házanépét kenyérrel, gyermekeik számához képest.
13 Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà.
És kenyér nem vala az egész föld kerekségén, mert igen nagy vala az éhség, és elalélt vala Égyiptom földe, és a Kanaán földe az éhség miatt.
14 Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao.
József pedig mind összeszedé a pénzt, a mi találtatik vala Égyiptomnak és Kanaánnak földén a gabonáért, a melyet azok vesznek vala; és bévivé József a pénzt a Faraó házába.
15 Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”
És mikor elfogyott a pénz Égyiptom földéről is, Kanaán földéről is, egész Égyiptom Józsefhez méne, mondván: Adj nékünk kenyeret, miért haljunk meg szemed láttára, azért hogy nincs pénz?
16 Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”
És monda József: Hozzátok ide barmaitokat, és adok néktek a ti barmaitokért, ha nincs pénz.
17 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.
És elvivék barmaikat Józsefhez, és ada nékik József kenyeret lovakért, juhokért, ökrökért és szamarakért: és eltartá őket abban az esztendőben kenyérrel az ő barmaik összeségéért.
18 Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa.
Mikor pedig elmúlék az esztendő, menének hozzá a második esztendőben, és mondának néki: Nem titkolhatjuk el uramtól, hogy bizony elfogyott a pénz, és a barom-nyájak mind uramnál vannak, a mint látja az én uram semmi sem maradt, csak testünk és földünk.
19 Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”
Miért veszszünk el szemed láttára mind magunk, mind földünk? végy meg minket és földünket kenyéren, és mi és a mi földünk szolgái leszünk a Faraónak; csak adj magot, hogy éljünk s ne haljunk meg, és a föld ne pusztuljon el.
20 Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao,
Megvevé azért József egész Égyiptom földét a Faraó részére, mert az Égyiptombeliek mind eladák az ő földjöket, mivelhogy erőt vett vala rajtok az éhség. És a föld a Faraóé lőn.
21 Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì.
A népet pedig egyik városból a másikba telepíté Égyiptom egyik határszélétől másik széléig.
22 Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.
Csak a papok földét nem vevé meg, mert a papoknak szabott részök vala a Faraótól és abból a szabott részből élnek vala, a mit nékik a Faraó ád vala; annak okáért, nem adák el az ő földjöket.
23 Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà.
És monda József a népnek: Ímé megvettelek titeket a mai napon, és a ti földeteket a Faraónak. Ímhol számotokra a mag, vessétek be a földet.
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”
És takaráskor adjatok a Faraónak egy ötödrészt; négy rész pedig legyen a tiétek, a mező bevetésére és éléstekre, mind magatoknak, mind házatok népének, és gyermekeiteknek eledelül.
25 Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”
És mondának: Életünket megtartottad; hadd találjunk kegyelmet uram szemei előtt, és szolgái leszünk a Faraónak.
26 Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.
És törvénynyé tevé azt József mind e mai napig Égyiptom földén, hogy a Faraóé az ötödrész, csak a papok földe, egyedűl az nem volt a Faraóé.
27 Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.
Lakozék azért Izráel Égyiptom földében a Gósen földén, és ott megöröködének, s megszaporodának és megsokasodának felette igen.
28 Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tàdínlógún iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹẹ́tàdínlàádọ́jọ.
Jákób pedig tizenhét esztendeig él vala Égyiptom földén, és Jákób élete esztendeinek napjai száz negyvenhét esztendő.
29 Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti.
És elközelgetének Izráel halálának napjai, és hívatá az ő fiát Józsefet, s monda néki: Ha én te előtted kedves vagyok, kérlek tedd a kezedet tomporom alá, és légy hozzám szeretettel és hűséggel: Kérlek ne temess el engem Égyiptomban.
30 Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.” Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”
Midőn elaluszom az én atyáimmal, vígy ki engem Égyiptomból és temess el az ő sírjokba. És monda: Én a te beszéded szerint cselekszem.
31 Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.
És monda: Esküdjél meg nékem! és megesküvék néki. És leborula Izráel az ágy fejére.