< Genesis 46 >
1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
Востав же Израиль сам и вся сущая его, прииде ко кладязю Клятвенному и пожре жертву Богу отца своего Исаака.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Рече же Бог ко Израилю в видении нощию, глаголя: Иакове, Иакове. Он же рече: что есть?
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
Он же рече ему: Аз есмь Бог отцев твоих, не убойся изыти во Египет: в язык бо велий сотворю тя тамо:
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
и Аз сниду с тобою во Египет, и Аз возведу тя до конца: и Иосиф возложит руки своя на очи твои.
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
Воста же Иаков от кладязя Клятвеннаго, и взяша сынове Израиля отца своего, и стяжание, и жены своя на колесницы, яже посла Иосиф, взяти его:
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
и вземше имения своя и все стяжание, еже стяжаша в земли Ханаанстей, внидоша во Египет Иаков и все семя его с ним:
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
сынове и сынове сынов его с ним, дщери и дщери дщерей его, и все семя свое введе во Египет.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
Сия же имена сынов Израилевых вшедших во Египет купно со Иаковом отцем своим: Иаков и сынове его: первенец Иаковль Рувим.
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
Сынове же Рувимли: Енох и Фаллос, Асрон и Харми.
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
Сынове же Симеони: Иемуил и Иамин, и Аод и Ахин, и Саар и Саул, сын Хананитидин.
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Сынове же Левиини: Гирсон, Кааф и Мерарий.
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Сынове же Иудины: Ир и Авнан, и Силом и Фарес и Зара: умроша же Ир и Авнан в земли Ханаани. Быша же сынове Фаресу: Есром и Иемуил.
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
Сынове же Иссахаровы: Фола и Фуа, и Асум и Самвран.
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
Сынове же Завулони: Серед и Аллон и Ахоил.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
Сии сынове Лиини, ихже роди Иакову в Месопотамии Сирстей, и Дину дщерь его: всех душ сынов и дщерей тридесять три.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
Сынове же Гадовы: Сафон и Ангис, и Саннис и Фасован, и Аидис и Ароидис и Ареилис.
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
Сынове же Асировы: Иемна и Ессуа, и Иеул и Вариа, и Сара сестра их. Сынове же Вариины: Ховор и Мелхиил.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
Сии сынове Зелфины, юже даде Лаван Лии, дщери своей, яже роди сих Иакову, шестьнадесять душ.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
Сынове же Рахили, жены Иаковли: Иосиф и Вениамин.
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
Быша же сынове Иосифу в земли Египетстей, ихже роди ему Асенефа, дщи Петефриа жреца Илиопольска, Манассию и Ефрема. Быша же сынове Манассиины, ихже роди ему наложница Сира, Махира. Махир же роди Галаада. Сынове же Ефраима, брата Манассиина: Суталаам и Таам. Сынове же Суталаамли, Едом.
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
Сынове же Вениамини: Вала и Ховор и Асфил. Быша же сынове Валовы: Гира и Ноеман, и Анхис и Рос, и Мамфим и Офимим. Гира же роди Арада.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
Сии сынове Рахилины, ихже роди Иакову, всех душ осмьнадесять.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
Сынове же Дановы: Асом.
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
Сынове же Неффалимли: Асиил и Гони, и Иссаар и Селлим.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
Сии сынове Валлины, юже даде Лаван Рахили дщери своей, яже роди сих Иакову: всех душ седмь.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
Всех же душ вшедших со Иаковом во Египет, яже изыдоша из чресл его, кроме жен сынов Иаковлих, всех душ шестьдесят шесть.
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
Сынове же Иосифовы, иже быша ему в земли Египетстей, душ девять: всех душ дому Иаковля, яже приидоша со Иаковом во Египет, душ седмьдесят пять.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
Иуду же посла пред собою ко Иосифу срести его у Иройска града в земли Рамессийстей.
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
Впряг же Иосиф колесницы своя, изыде во сретение Израилю, отцу своему, ко Ироону граду: и явився ему, нападе на выю его и плакася плачем великим.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
И рече Израиль ко Иосифу: да умру отныне, понеже видех лице твое: еще бо ты еси жив.
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
Рече же Иосиф ко братии своей: шед повем фараону и реку ему: братия моя и дом отца моего, иже быша в земли Ханаани, приидоша ко мне:
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
они же суть мужие пастуси, мужие бо скотопитателие быша: и скоты, и волы, и вся своя приведоша:
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
аще убо призовет вас фараон и речет вам: что дело ваше есть?
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
Рцыте: мужие скотопитателие есмы, раби твои, издетска даже до ныне, и мы и отцы наши: да вселитеся в земли Гесем аравийстей: мерзость бо есть Египтяном всяк пастух овчий.