< Genesis 46 >

1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
Şi Israel a plecat în călătoria sa cu tot ce avea şi a venit la Beer-Şeba şi a oferit sacrificii Dumnezeului tatălui său Isaac.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Şi Dumnezeu i-a vorbit lui Israel în viziunile nopţii şi a spus: Iacob, Iacob. Iar el a spus: Iată-mă.
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
Şi a spus: Eu sunt Dumnezeu, Dumnezeul tatălui tău; nu te teme să cobori în Egipt, fiindcă acolo voi face din tine o mare naţiune;
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
Voi coborî cu tine în Egipt; şi de asemenea cu adevărat te voi urca înapoi, şi Iosif îşi va pune mâna peste ochii tăi.
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
Şi Iacob s-a ridicat din Beer-Şeba; şi fiii lui Israel l-au dus pe Iacob, tatăl lor, şi pe micuţii lor şi pe soţiile lor în carele pe care Faraon le-a trimis să îl ducă.
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Şi au luat vitele lor şi bunurile lor, pe care le dobândiseră în ţara lui Canaan, şi au venit în Egipt, deopotrivă Iacob şi toată sămânţa lui cu el;
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Fiii săi şi fiii fiilor săi cu el, fiicele sale şi fiicele fiilor săi şi toată sămânţa sa el a adus-o cu el în Egipt.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
Şi acestea sunt numele copiilor lui Israel, care au venit în Egipt, Iacob şi fiii săi: Ruben, întâiul născut al lui Iacob.
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
Şi fiii lui Ruben: Hanoc şi Falu şi Heţron şi Carmi.
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
Şi fiii lui Simeon: Iemuel şi Iamin şi Ohad şi Iachin şi Ţohar şi Şaul, fiul unei femei canaanite.
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Şi fiii lui Levi: Gherşon, Chehat şi Merari.
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Şi fiii lui Iuda: Er şi Onan şi Şela şi Pereţ şi Zerah; dar Er şi Onan au murit în ţara lui Canaan. Şi fiii lui Pereţ au fost: Heţron şi Hamul.
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
Şi fiii lui Isahar: Tola şi Pua şi Iov şi Şimron.
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
Şi fiii lui Zabulon: Sered şi Elon şi Iahleel.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
Aceştia sunt fiii Leei, cu fiica sa Dina, pe care ea i-a născut lui Iacob în Padanaram; toate sufletele fiilor săi şi a fiicelor sale au fost treizeci şi trei.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
Şi fiii lui Gad: Ţifion şi Hagi, Şuni şi Eţbon, Eri şi Arodi şi Areli.
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
Şi fiii lui Aşer: Imna şi Işva şi Işvi şi Beria şi Serah, sora lor; şi fiii lui Beria: Heber şi Malchiel.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
Aceştia sunt fiii Zilpei, pe care Laban a dat-o Leei, fiica sa, şi pe aceştia i-a născut ea lui Iacob, şaisprezece suflete.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
Fiii Rahelei, soţia lui Iacob: Iosif şi Beniamin.
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
Şi lui Iosif în ţara Egiptului i s-au născut Manase şi Efraim, pe care Asenat, fiica lui Potifera, preot din On, i-a născut lui.
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
Şi fiii lui Beniamin au fost Bela şi Becher şi Aşbel, Ghera şi Naaman, Ehi şi Roş, Mupim şi Hupim şi Ard.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
Aceştia sunt fiii Rahelei, care au fost născuţi lui Iacob; toate sufletele au fost paisprezece.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
Şi fiii lui Dan: Huşim.
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
Şi fiii lui Neftali: Iahzeel şi Guni şi Ieţer şi Şilem.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
Aceştia sunt fiii Bilhei, pe care Laban a dat-o Rahelei, fiica sa, şi ea i-a născut pe aceştia lui Iacob; toate sufletele au fost şapte.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
Toate sufletele care au venit cu Iacob în Egipt, care au ieşit din coapsele lui, pe lângă soţiile fiilor lui Iacob, toate sufletele au fost şaizeci şi şase.
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
Şi fiii lui Iosif, care i s-au născut în Egipt, au fost două suflete; toate sufletele din casa lui Iacob, care au venit în Egipt, au fost şaptezeci.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
Şi a trimis pe Iuda înaintea lui la Iosif, să îndrepte faţa sa spre Gosen; şi au venit în ţinutul Gosen.
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
Şi Iosif şi-a pregătit carul şi s-a urcat să întâmpine pe Israel, tatăl său, la Gosen; şi i s-a înfăţişat; şi a căzut pe gâtul lui şi a plâns pe gâtul lui mult timp.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
Şi Israel i-a spus lui Iosif: Acum pot muri pentru că am văzut faţa ta şi încă trăieşti.
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
Şi Iosif a spus fraţilor săi şi casei tatălui său: Voi urca şi îl voi anunţa pe Faraon şi îi voi spune: Fraţii mei şi casa tatălui meu, care au fost în ţara lui Canaan, au venit la mine;
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
Şi bărbaţii sunt păstori, pentru că meseria lor era să pască vitele; şi au adus turmele lor şi cirezile lor şi tot ceea ce au.
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
Şi se va întâmpla, când Faraon vă va chema şi va spune: Care este ocupaţia voastră?
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
Că voi să spuneți: Meseria servitorilor tăi a fost la vite din tinereţea noastră chiar până acum, deopotrivă noi şi părinţii noştri; ca să locuiţi în ţinutul Gosen; căci fiecare păstor este o urâciune înaintea Egiptenilor.

< Genesis 46 >