< Genesis 46 >
1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
Tak więc Izrael wyruszył [w drogę] ze wszystkim, co miał; a gdy przybył do Beer-Szeby, złożył ofiary Bogu swego ojca Izaaka.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Wtedy Bóg powiedział do Izraela w nocnym widzeniu: Jakubie, Jakubie! A on odpowiedział: Oto jestem.
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
I powiedział: Ja [jestem] Bogiem, Bogiem twego ojca. Nie bój się zejść do Egiptu, bo tam cię rozmnożę w wielki naród.
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
Pójdę z tobą do Egiptu i wyprowadzę cię stamtąd [z powrotem], a Józef położy swoją rękę na twoje oczy.
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
I Jakub wyruszył z Beer-Szeby. I synowie Izraela wzięli swego ojca Jakuba, swoje dzieci i swe żony na wozy, które faraon posłał, aby go przywieziono.
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Zebrali też swe stada i swój dobytek, który zdobyli w ziemi Kanaan, i przyjechali do Egiptu, Jakub i całe jego potomstwo razem z nim;
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Swych synów i synów swoich synów, swoje córki i córki swoich synów oraz całe swoje potomstwo prowadził ze sobą do Egiptu.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
A to [są] imiona synów Izraela, którzy weszli do Egiptu – Jakub i jego synowie: pierworodny Jakuba, Ruben.
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
Synowie Rubena: Henoch, Pallu, Chesron i Karmi.
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
Synowie Symeona: Jemuel, Jamin, Ohad, Jakin, Sochar i Szaul, syn [kobiety] Kananejki.
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Synowie Lewiego: Gerszon, Kehat i Merari.
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Synowie Judy: Er, Onan, Szela, Peres i Zerach. Lecz Er i Onan umarli w ziemi Kanaan. A synami Peresa byli: Chesron i Chamul.
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
Synowie Issachara: Tola, Puwwa, Job i Szimron.
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
Synowie Zebulona: Sered, Elon i Jachleel.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
A to są synowie Lei, których – jak i córkę Dinę, urodziła Jakubowi w Paddan-Aram. Wszystkich dusz jego synów i córek było trzydzieści trzy.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
Synowie Gada: Sifion, Chaggi, Szuni, Esbon, Eri, Arodi i Areli.
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
Synowie Aszera: Jimna, Jiszwa, Jiszwi, Beria i siostra ich Serach. A synowie Berii: Cheber i Malkiel.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
To [są] synowie Zilpy, którą Laban dał swej córce Lei, których ona urodziła Jakubowi – szesnaście dusz.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
Synowie Racheli, żony Jakuba: Józef i Beniamin.
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
Józefowi zaś urodzili się w ziemi Egiptu Manasses i Efraim, których urodziła Asenat, córka Poti-Fery, kapłana z On.
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
Synowie Beniamina: Bela, Beker, Aszbel, Gera, Naaman, Echi, Rosz, Muppim, Chuppim i Ard.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
To [są] synowie Racheli, którzy się urodzili Jakubowi. Wszystkich dusz – czternaście.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
Synowie Dana: Chuszim.
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
Synowie Neftalego: Jachseel, Guni, Jeser i Szillem.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
To [są] synowie Bilhy, którą Laban dał swej córce Racheli, i których urodziła Jakubowi. Wszystkich dusz – siedem.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
Wszystkich, którzy przyszli z Jakubem do Egiptu, pochodzących z jego lędźwi, oprócz żon synów Jakuba, wszystkich dusz było sześćdziesiąt sześć.
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
A synów Józefa, którzy mu się urodzili w Egipcie, były dwie dusze. [I tak] wszystkich dusz z domu Jakuba, które weszły do Egiptu, [było] siedemdziesiąt.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
I [Jakub] posłał przed sobą Judę do Józefa, aby go uprzedził, zanim przybędzie do Goszen. I przybyli do ziemi Goszen.
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
I Józef zaprzągł swój wóz, i wyjechał naprzeciw swemu ojcu Izraelowi do Goszen. A gdy go zobaczył, rzucił mu się na szyję i długo płakał na jego szyi.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
Wtedy Izrael powiedział do Józefa: Mogę już umrzeć, skoro ujrzałem twoją twarz, że jeszcze żyjesz.
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
Józef powiedział do swoich braci i do domu swego ojca: Pójdę zawiadomić faraona i powiem mu: Moi bracia i dom mego ojca, którzy byli w ziemi Kanaan, przyjechali do mnie;
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
A [ci] mężczyźni [są] pasterzami, bo zajmowali się hodowlą bydła. Przyprowadzili więc swoje owce i woły, i wszystko, co mieli.
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
A gdy wezwie was faraon i zapyta: Czym się zajmujecie?
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
Odpowiecie: Twoi słudzy od swego dzieciństwa aż do dziś są pasterzami, my i nasi ojcowie. [W ten sposób] będziecie mogli mieszkać w ziemi Goszen, bo Egipcjanie brzydzą się każdym pasterzem.