< Genesis 46 >
1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
Elindula azért Izráel minden hozzá tartozóival és méne Beérsebába; és áldozék áldozatokat az ő atyja Izsák Istenének.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
És szóla Isten Izráelnek éjjeli látomásban, és monda: Jákób, Jákób. Ő pedig monda: Ímhol vagyok.
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
És monda: Én vagyok az Isten, a te atyádnak Istene: Ne félj lemenni Égyiptomba: mert nagy néppé teszlek ott téged.
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
Én lemegyek veled Égyiptomba, és én bizonynyal fel is hozlak; és József fogja bé a te szemeidet.
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
Felkerekedék azért Jákób Beérsebából, és elvivék Izráel fiai Jákóbot az ő atyjokat, és gyermekeiket és feleségeiket a szekereken, melyeket a Faraó küldött vala érette.
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
És elvivék nyájaikat és szerzeményeiket, melyeket Kanaán földén szereztek vala, és jutának Égyiptomba Jákób és minden vele levő magva.
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Az ő fiait és fiainak fiait, az ő leányait, és fiainak leányait és minden vele levő magvát elvivé magával Égyiptomba.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
Ezek pedig az Izráel fiainak nevei, kik bementek Égyiptomba: Jákób és az ő fiai: Jákóbnak elsőszülötte Rúben.
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
Rúben fiai pedig: Khánokh, Pallu, Kheczrón, Khármi.
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
Simeon fiai pedig: Jemúel, Jámin, Ohad, Jákhin, Czóhár és Saul a kanaáni asszonynak fia.
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Lévi fiai pedig: Gerson, Kehát, Mérári.
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Júda fiai pedig: Hér, Ónán, Séla, Perecz, Zerákh; de megholt vala Hér és Ónán a Kanaán földén. Perecznek fiai pedig: Kheczrón és Khámul.
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
Izsakhár fiai pedig: Thóla, Puvah, Jób és Simrón.
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
Zebulon fiai pedig: Szered, Élon, Jákhleél.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
Ezek Lea fiai, a kiket szűlt vala Jákóbnak Mésopotámiában, Dínával az ő leányával együtt. Fiainak és leányainak összes száma: harminczhárom lélek.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
Gád fiai pedig: Czifjon, Khaggi, Súni, Eczbón, Héri, Aródi és Areéli.
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
Áser fiai pedig: Jimnáh, Jisváh, Jisvi, Beriha és Szerakh az ő húgok; Berihának fiai pedig: Khéber és Málkhiel.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
Ezek Zilpa fiai, kit Lábán adott vala Leának az ő leányának; és ő szűlé ezt a tizenhat lelket Jákóbnak.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
Rákhelnek, Jákób feleségének fiai: József és Benjámin.
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
És születének Józsefnek Égyiptom földén Manasse és Efráim, a kiket Asznáth, Potiferának, On papjának leánya szűlt néki.
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
Benjámin fiai pedig: Bela, Bekher, Asbél, Géra, Nahamán, Ekhi, Rós, Muppim, Khuppim és Ard.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
Ezek Rákhel fiai, kik születtek Jákóbnak, mindössze tizennégy lélek.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
Dán fia pedig: Khusim.
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
Nafthali fiai pedig: Jakhczeél, Gúni, Jéczer és Sillém.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
Ezek Bilha fiai, kit adott vala Lábán Rákhelnek az ő leányának; és ezeket szűlte Jákóbnak, mindössze hét lelket.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
Valamennyi Jákóbbal Égyiptomba jött lélek, kik az ő ágyékából származtak, a Jákób fiainak feleségeit nem számítva, mindössze hatvanhat lélek.
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
József fiai pedig, kik Égyiptomban születtek, két lélek. Jákób egész házanépe, mely Égyiptomba ment vala, hetven lélek.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
Júdát pedig elküldé maga előtt Józsefhez, hogy útmutatója legyen Gósen felé. És eljutának Gósen földére.
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
És befogata József az ő szekerébe, és eleibe méne Izráelnek az ő atyjának Gósenbe; s a mint maga előtt látá, nyakába borula, és síra az ő nyakán sok ideig.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
És monda Izráel Józsefnek: Immár örömest meghalok, minekutána láttam a te orczádat, hogy még élsz.
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
József pedig monda az ő testvéreinek, és az ő atyja házanépének: Felmegyek és tudtára adom a Faraónak, és ezt mondom néki: Az én testvéreim és atyám háznépe, kik Kanaán földén valának, eljöttek én hozzám.
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
Azok az emberek pedig juhpásztorok, mert baromtartó nép valának, és juhaikat, barmaikat, és mindenöket valamijök van, elhozták.
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
S ha majd a Faraó hivat titeket és azt kérdi: Mi a ti életmódotok?
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
Azt mondjátok: Baromtartó emberek voltak a te szolgáid gyermekségünktől fogva mind ez ideig, mi is, mint a mi atyáink, hogy lakhassatok Gósen földén; mert minden juhpásztor utálatos az Égyiptombeliek előtt.