< Genesis 46 >

1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Isiraeli akiumagara na indo ciothe iria aarĩ nacio, na aakinya Birishiba-rĩ, akĩrutĩra Ngai wa ithe Isaaka magongona.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Nake Ngai akĩarĩria Isiraeli na kĩoneki ũtukũ, akĩmwĩra atĩrĩ, “Jakubu! Jakubu!” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ũyũ haha.”
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
Ngai akiuga atĩrĩ, “Nĩ niĩ Ngai, Ngai wa thoguo. Ndũgetigĩre gũikũrũka ũthiĩ Misiri, tondũ nĩngagũtua rũrĩrĩ rũnene mũno kũu.
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
O na nĩngũikũrũkania nawe kũu Misiri, na ti-itherũ nĩ ngagũcookia gũkũ rĩngĩ. Nakuo guoko kwa Jusufu kuo kwene nĩkuo gũgaakũhinga maitho wakua.”
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
Hĩndĩ ĩyo Jakubu akiuma Birishiba, nao ariũ a Isiraeli magĩkuua ithe wao Jakubu na ciana ciao na atumia ao na makaari marĩa Firaũni aatũmĩte ma kũmũkuua.
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
O na ningĩ magĩthiĩ na mahiũ mao na indo iria ciothe maagĩĩte nacio marĩ kũu Kaanani, na Jakubu na rũciaro rwake ruothe magĩthiĩ Misiri.
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Aathiire Misiri na ariũ ake na tũmwana twa ariũ ake, agĩthiĩ na airĩtu ake na tũirĩtu twa airĩtu ake, ũguo nĩ kuuga rũciaro rwake ruothe.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
Maya nĩmo marĩĩtwa ma ariũ a Isiraeli (Jakubu na njiaro ciake) arĩa maathiire Misiri: Rubeni irigithathi rĩa Jakubu.
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
Ariũ a Rubeni maarĩ: Hanoku, na Palu, na Hezironi, na Karimi.
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
Ariũ a Simeoni maarĩ: Jemueli, na Jamini, na Ohadi, na Jakini, na Zoharu, na Shauli mũrũ wa mũtumia ũrĩa Mũkaanani.
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Ariũ a Lawi maarĩ: Gerishoni, na Kohathu, na Merari.
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Ariũ a Juda maarĩ: Eri, na Onani, na Shela, na Perezu, na Zera (no Eri na Onani nĩmakuĩrĩire bũrũri wa Kaanani.) Nao ariũ a Perezu maarĩ: Hezironi na Hamuli.
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
Ariũ a Isakaru maarĩ: Tola, na Puya, na Jashubu, na Shimuroni.
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
Ariũ a Zebuluni maarĩ: Seredi, na Eloni, na Jahaleeli.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
Acio nĩo ariũ arĩa Lea aaciarĩire Jakubu kũu Padani-Aramu, hamwe na mwarĩ Dina. Ariũ acio na airĩtu ake othe maarĩ mĩrongo ĩtatũ na atatũ.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
Ariũ a Gadi maarĩ: Zifioni, na Hagi, na Shuni, na Eziboni, na Eri, na Arodi, na Areli.
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
Nao Ariũ a Asheri maarĩ: Imuna, na Ishiva, na Ishivi, na Beria. Mwarĩ wa nyina aarĩ Sera. Ariũ a Beria maarĩ: Heberi na Malikieli.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
Icio nĩcio ciana iria ciaciarĩirwo Jakubu nĩ Zilipa, ũrĩa Labani aaheete mwarĩ Lea; ciothe ciarĩ ciana ikũmi na ithathatũ.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
Ariũ a Rakeli mũtumia wa Jakubu maarĩ: Jusufu na Benjamini.
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
Nake Jusufu arĩ kũu Misiri, nĩaciarĩirwo Manase na Efiraimu nĩ Asenathu mwarĩ wa Potifera, mũthĩnjĩri-ngai wa Onu.
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
Nao ariũ a Benjamini maarĩ: Bela, na Bekeri, na Ashibeli, na Gera, na Naamani, na Ehi, na Roshu, na Mupimu, na Hupimu, na Aradi.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
Acio nĩo ariũ a Rakeli arĩa maaciarĩirwo Jakubu othe maarĩ andũ ikũmi na ana.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
Mũriũ wa Dani aarĩ: Hushimu.
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
Nao Ariũ a Nafitali maarĩ: Jahazeeli, na Guni, na Jezeri, na Shilemu.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
Acio nĩo ariũ arĩa maaciarĩirwo Jakubu nĩ Biliha ũrĩa Labani aaheete mwarĩ Rakeli, othe maarĩ mũgwanja.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
Andũ othe arĩa maathiire na Jakubu Misiri, arĩa maarĩ a njiaro ciake tũtegũtara atumia a ariũ ake, maarĩ andũ mĩrongo ĩtandatũ na atandatũ.
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
Hamwe na ariũ arĩa eerĩ a Jusufu arĩa aaciarĩire Misiri, andũ a nyũmba ya Jakubu arĩa maathiire Misiri maarĩ mĩrongo mũgwanja.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
Nake Jakubu agĩtũma Juda athiĩ mbere yake kũrĩ Jusufu nĩgeetha athĩrĩrwo njĩra ya gũthiĩ Gosheni. Rĩrĩa maakinyire bũrũri wa Gosheni,
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
Jusufu akĩhaarĩria ngaari yake ya mbarathi, na agĩthiĩ Gosheni gũtũnga ithe Isiraeli. Na Jusufu aakinya o ũguo harĩ ithe, akĩmũhĩmbĩria na akĩrĩra ihinda inene.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
Nake Isiraeli akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Rĩu no ngĩkue, kuona atĩ nĩndeyonera niĩ mwene atĩ ũrĩ o muoyo.”
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
Hĩndĩ ĩyo Jusufu akĩĩra ariũ a ithe na andũ a nyũmba ya ithe atĩrĩ, Nĩngwambata thiĩ njarie na Firaũni, ndĩmwĩre atĩrĩ, Ariũ a baba, na nyũmba ya baba, arĩa maratũũraga bũrũri wa Kaanani, nĩmokĩte kũrĩ niĩ.
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
Andũ acio nĩ arĩithi; marĩithagia mahiũ, na mokĩte na ndũũru ciao cia mbũri na cia ngʼombe, na indo ciothe ciao.
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
Na rĩrĩa Firaũni arĩmwĩta na amũũrie atĩrĩ, “Inyuĩ mũrutaga wĩra ũrĩkũ?”
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
mwagĩrĩirwo mũmũcookerie atĩrĩ, “Ithuĩ ndungata ciaku tũtũũraga tũrĩithagia mahiũ kuuma ũnini witũ, o ta ũrĩa maithe maitũ meekaga.” Hĩndĩ ĩyo nĩmũgetĩkĩrio mũtũũre mwena wa Gosheni, tondũ arĩithi othe moonagwo marĩ thaahu nĩ andũ a Misiri.

< Genesis 46 >