< Genesis 46 >

1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
Israël partit avec tout ce qu'il avait, arriva à Beer Schéba, et offrit des sacrifices au Dieu de son père Isaac.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Dieu parla à Israël dans les visions de la nuit, et dit: « Jacob, Jacob! » Il a dit: « Je suis là. »
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
Il dit: « Je suis Dieu, le Dieu de ton père. Ne crains pas de descendre en Égypte, car c'est là que je ferai de toi une grande nation.
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
Je descendrai avec toi en Égypte. Et je te ferai remonter. La main de Joseph fermera tes yeux. »
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
Jacob se leva de Beer Schéba, et les fils d'Israël portèrent Jacob, leur père, leurs petits enfants et leurs femmes, dans les chariots que Pharaon avait envoyés pour le transporter.
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Ils prirent leur bétail et leurs biens, qu'ils avaient acquis au pays de Canaan, et ils entrèrent en Égypte: Jacob, et toute sa descendance avec lui,
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
ses fils, et les fils de ses fils avec lui, ses filles, et les filles de ses fils, et il amena toute sa descendance avec lui en Égypte.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
Voici les noms des enfants d'Israël qui vinrent en Égypte, de Jacob et de ses fils: Ruben, premier-né de Jacob.
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
Fils de Ruben: Hanoch, Pallu, Hezron et Carmi.
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
Fils de Siméon: Jemuel, Jamin, Ohad, Jachin, Zohar et Shaoul, fils d'une Cananéenne.
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Fils de Lévi: Gershon, Kehath et Merari.
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Fils de Juda: Er, Onan, Shéla, Pérez et Zérach; mais Er et Onan moururent au pays de Canaan. Les fils de Pérez furent Hetsron et Hamul.
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
Fils d'Issacar: Tola, Puvah, Iob et Shimron.
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
Fils de Zabulon: Sered, Elon et Jahleel.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
Ce sont là les fils de Léa, qu'elle enfanta à Jacob à Paddan Aram, avec sa fille Dina. Le total des âmes de ses fils et de ses filles était de trente-trois.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
Fils de Gad: Ziphion, Haggi, Shuni, Ezbon, Eri, Arodi et Areli.
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
Fils d'Asher: Imna, Ishva, Ishvi, Beriah, et Serah, leur sœur. Fils de Beria: Héber et Malkiel.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
Voici les fils de Zilpa, que Laban donna à Léa, sa fille, et qu'elle enfanta à Jacob: seize âmes.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
Fils de Rachel, femme de Jacob: Joseph et Benjamin.
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
A Joseph naquirent, au pays d'Égypte, Manassé et Éphraïm, qu'Asenath, fille de Potiphéra, prêtre d'On, lui enfanta.
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
Fils de Benjamin: Bela, Becher, Ashbel, Gera, Naaman, Ehi, Rosh, Muppim, Huppim et Ard.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
Voici les fils de Rachel, qui naquirent à Jacob: tous avaient quatorze âmes.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
Fils de Dan: Huschim.
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
Fils de Nephtali: Jahzeel, Guni, Jezer et Shillem.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
Voici les fils de Bilha, que Laban donna à Rachel, sa fille, et qu'elle enfanta à Jacob: tous ceux-là étaient sept.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
Toutes les âmes qui vinrent avec Jacob en Égypte, qui étaient sa descendance directe, en plus des femmes des fils de Jacob, toutes les âmes étaient soixante-six.
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
Les fils de Joseph, qui lui étaient nés en Égypte, étaient au nombre de deux. Toutes les âmes de la maison de Jacob, qui vinrent en Égypte, étaient au nombre de soixante-dix.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
Jacob envoya Juda devant lui à Joseph, pour lui montrer le chemin de Gosen, et ils arrivèrent dans le pays de Gosen.
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
Joseph prépara son char, et monta à la rencontre d'Israël, son père, en Gosen. Il se présenta à lui, se jeta à son cou, et pleura longtemps sur son cou.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
Israël dit à Joseph: « Maintenant, laisse-moi mourir, puisque j'ai vu ton visage et que tu vis encore. »
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
Joseph dit à ses frères et à la maison de son père: « Je vais monter et parler à Pharaon, et je lui dirai: « Mes frères et la maison de mon père, qui étaient au pays de Canaan, sont venus vers moi.
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
Ces hommes sont des bergers, car ils ont gardé du bétail, et ils ont amené leurs troupeaux, leurs bêtes, et tout ce qu'ils ont.
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
Lorsque Pharaon vous convoquera et dira: « Quelle est votre profession?
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
vous répondrez: « Tes serviteurs ont gardé le bétail depuis notre jeunesse jusqu'à ce jour, nous et nos pères, et vous pourrez habiter dans le pays de Gosen, car tout berger est en abomination aux Égyptiens ».

< Genesis 46 >