< Genesis 46 >
1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
So Jacob left [Canaan], taking with him all his family and possessions. When they arrived at Beersheba, he offered sacrifices to God, the one whom his father Isaac worshiped.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
That night, God called to Jacob in a vision, saying, “Jacob! Jacob!” He replied, “I am here!”
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
God said, “I am God, the one your father worshiped. Do not be afraid to go down to Egypt, because I will give you many descendants, and they will become a great nation there.
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
I will go down to Egypt with you, and later I will bring [your descendants] back to Canaan again. And Joseph will be with you [MTY] when you die.” [IDM]
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
Jacob left Beersheba, and his sons took their father, their wives, and their children, in the carts that the king had sent for them to travel in.
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
So Jacob and all his family went to Egypt. They took with them the livestock and all the other possessions that they had acquired in Canaan.
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Jacob went to Egypt with all his sons and his daughters and grandsons and granddaughters—his whole family.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
(Here is/I will now give you) a list of the names of the members of Jacob’s family who went with him to Egypt: Reuben, Jacob’s oldest son; Reuben’s sons Hanoch, Pallu, Hezron, and Carmi; Simeon and his sons Jemuel, Jamin, Ohad, Jakin, Zohar, and Shaul, who was the son of a Canaan people-group woman; Levi and his sons Gershon, Kohath, and Merari; Judah and his sons, Shelah, Perez, and Zerah (his other sons, Er, and Onan, had died in Canaan); Perez and his two sons Hezron and Hamul; Issachar and his sons Tola, Puah, Jashub, and Shimron; Zebulon and his sons Sered, Elon, and Jahleel; (Those were the sons of Jacob and Leah, and their daughter Dinah, who were born in Paddan-Aram/Mesopotamia: There were 33 of them, altogether.) They had Gad and his sons Zephon, Haggi, Shuni, Ezbon, Eri, Arodi, and Areli; Asher and his sons Imnah, Ishvah, Ishvi, and Beriah; and their sister Serah; Beriah’s sons Heber and Malkiel; (Those were the children and grandchildren of Jacob and Zilpah, the slave girl whom Laban gave to his daughter Leah: There were 16 of them, altogether.) Joseph and Benjamin, the sons of Jacob’s wife Rachel; (Ephraim and Manasseh were Joseph’s two sons. [They did not go down to Egypt] because they were already in Egypt. They were sons of Asenath, the daughter of On, who was the priest in the temple in On [city].) Benjamin and his sons Bela, Beker, Ashbel, Gera, Naaman, Ehi, Rosh, Muppim, Huppim, and Ard; (Those were the sons and grandsons of Rachel and Jacob: There were 14 people altogether.) Dan and his son Hushim; Naphtali and his sons Jahziel, Guni, Jezer, and Shillem. (Those were the sons and grandsons of Jacob and Bilhah, the slave girl whom Laban gave to his daughter Rachel: There were seven people altogether.)
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
Altogether there were 66 people who were Jacob’s descendants who went to Egypt with him. That number does not include his sons’ wives.
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
Including Jacob and Joseph and Joseph’s two sons who were born in Egypt, there were 70 members of Jacob’s family when they were all there in Egypt.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
Jacob sent Judah to go ahead of the rest of them to talk with Joseph and ask for directions on how to travel to Goshen. Then [Judah returned to the rest of his family and] they all traveled to the Goshen region. When they arrived there,
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
Joseph got his chariot ready and went to Goshen to meet his father. When Joseph arrived, he threw his arms around his father’s neck and cried a long time.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
Jacob said to Joseph, “I have seen you and I know that you are still alive! So now I am ready to die.”
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
Then Joseph said to his [older] brothers [and younger brother] and to the rest of his father’s family, “I will go to the king and say to him, ‘My [older] brothers [and younger brother] and my father and the rest of his family, who were living in Canaan land, have all come to me.
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
The men are all shepherds. They take care of their livestock, and they have brought with them their sheep and goats and cattle, and everything else that they own.’
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
When the king summons you and asks, ‘What work do you do?’
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
answer him by saying, ‘From the time when we were young, we have taken care of livestock, just as our ancestors did.’ If you tell him that, he will let you live in the Goshen region.” Joseph told them to say that because the people of Egypt despised all shepherds.