< Genesis 46 >

1 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
So Israel brake up, with all that he had, and came in to Beer-sheba, —and offered sacrifices to the God of his father Isaac.
2 Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
And God said to Israel in the visions of the night, and he said—Jacob! Jacob! And he said—Behold me!
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
And he said: I, am GOD himself, the God of thy father, —Be not afraid of going down to Egypt, seeing that for a great nation, will I plant thee there.
4 Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
I will go down with thee to Egypt, and I will bring thee up, yea wholly up, —and, Joseph, shall lay his own hand upon thine eyes.
5 Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
So Jacob rose up from Beer-sheba, —and the sons of Israel brought Jacob their father, and their little ones, and their wives, in the waggons which Pharaoh had sent to bring him;
6 Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
and they took their cattle and the gains which they had gained in the land of Canaan, and came into Egypt, —Jacob and all his seed with him:
7 Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
his sons, and his sons’ sons with him, his daughters, and his sons’ daughters, and all his seed, brought he with him into Egypt.
8 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
Now, these, are the names of the sons of Israel who came into Egypt—Jacob and his sons, —the firstborn of Jacob, Reuben:
9 Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
And, the sons of Reuben, —Hanoch and Pallu, and Hezron and Carmi;
10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
And, the sons of Simeon, —Jemuel and Jamin and Ohad and Jachin and Zohar, —and Shaul, son of the Canaanitess;
11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
And the sons of Levi, —Gershon, Kohath and Merari;
12 Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
And the sons of Judah, —Er and Onan and Shelah, and Perez and Zerah, —but Er and Onan died in the land of Canaan, and the sons of Perez were Hezron and Hamul;
13 Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
And, the sons of Issachar, —Tola and Puvah, and Iob and Shimron;
14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
And the sons of Zebulon, —Sered and Elon, and Jahleel.
15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
These, are the sons of Leah whom she bare to Jacob in Padan-aram, with Dinah also his daughter, —All the souls of his sons and of his daughters, were thirty-three.
16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
And, the sons of Gad, —Zaphon and Haggi, Shuni and Ezbon, —Eri and Arodi and Areli;
17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
And, the sons of Asher, —Imnah and Ishvah and Ishvi and Beriah, and Serah their sister, —and the sons of Beriah, Heber and Malchiel.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
These, are the sons of Zilpah, whom Laban gave to Leah his daughter, —so she bare these to Jacob, —sixteen souls.
19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
The sons of Rachel, Jacob’s wife, —Joseph and Benjamin;
20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
And there were born to Joseph in the land of Egypt, whom Asenath daughter of Poti-phera, priest of On, bare to him: Manasseh and Ephraim;
21 Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
And the sons of Benjamin—Bela and Becher, and Ashbel, Gera and Naaman, Ehi and Rosh, —Muppim and Huppim, and Ard.
22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
These, are the sons of Rachel, who were born to Jacob, —all the souls, were fourteen.
23 Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
And, the sons of Dan, —Hushim;
24 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
And the sons of Naphtali, —Jahzeel and Guni, and Jezer and Shillem.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
These, are the sons of Bilhah, whom Laban gave to Rachel his daughter, —so she bare these to Jacob, —all the souls, were seven.
26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
All the souls that came in with Jacob to Egypt that had come forth of his loins, besides Jacob’s sons’ wives, —all the souls, were sixty-six;
27 Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
and, the sons of Joseph who were born to him in Egypt, were two souls: All the souls of the house of Jacob that came into Egypt, were seventy.
28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
And he sent, Judah, before him unto Joseph, to direct his face to Goshen, —so they came in towards the land of Goshen.
29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
Then yoked Joseph his chariot, and went up to meet Israel his father towards Goshen, —and he appeared unto him, and fell upon his neck, and wept upon his neck a good while.
30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
Then said Israel unto Joseph I am ready to die at last, —now that I have seen thy face, in that thou art, yet alive.
31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
Then said Joseph unto his brethren and unto the house of his father, I must go up, and must tell Pharaoh—and must say unto him, My brethren, and the house of my father, who were in the land of Canaan, have come in unto me.
32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
Now, the men, are feeders of flocks, for men of cattle, they are, —and their flocks and their herds and all that they have, have they brought in.
33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
So shall it come to pass, when Pharaoh shall call for you, —and shall say—What is your occupation?
34 ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”
Then shall ye say—Men of cattle, have thy servants been from our youth even until now, both we and our fathers, —To the end ye may dwell in the land of Goshen, for an abomination to Egyptians, is every feeder of a flock,

< Genesis 46 >